< Joshua 8 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù, kí àyà kí ó má ṣe fò ọ́. Kó gbogbo àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ, kí ẹ gòkè lọ gbógun ti Ai. Nítorí mo ti fi ọba Ai, àwọn ènìyàn rẹ̀, ìlú u rẹ̀ àti ilẹ̀ ẹ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
Ningĩ Jehova akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ndũgetigĩre na ndũgakue ngoro. Thiĩ na mbũtũ yothe ya ita, mwambate mũgatharĩkĩre itũũra rĩa Ai. Nĩgũkorwo nĩneanĩte mũthamaki wa Ai moko-inĩ manyu, hamwe na andũ ake, na itũũra rĩake rĩu inene na bũrũri wake.
2 Ìwọ yóò sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, ohun ìkógun wọn àti ohun ọ̀sìn wọn ni kí ẹ̀yin mú fún ara yín. Rán ènìyàn kí wọ́n ba sí ẹ̀yìn ìlú náà.”
Ĩkai itũũra rĩa Ai na mũthamaki warĩo o ta ũrĩa mwekire itũũra rĩa Jeriko na mũthamaki warĩo, o tiga atĩrĩ, no muoye indo iria mũgũtaha, o na mahiũ matuĩke manyu. Oheriai andũ a itũũra rĩu inene na mwena wa na thuutha.”
3 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun jáde lọ láti dojúkọ Ai. Ó sì yan ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ogun rẹ̀ ti ó yakin, ó sì rán wọn lọ ní òru.
Nĩ ũndũ ũcio Joshua na mbũtũ yothe ya ita makiumagara magatharĩkĩre Ai. Nake agĩthuura andũ 30,000 arĩa maarĩ njamba mũno akĩmatũma mathiĩ kũrĩ ũtukũ,
4 Pẹ̀lú àwọn àṣẹ wọ̀nyí: “Ẹ fi etí sílẹ̀ dáradára. Ẹ ba sí ẹ̀yìn ìlú náà. Ẹ má ṣe jìnnà sí i púpọ̀. Kí gbogbo yín wà ní ìmúrasílẹ̀.
akĩmeera atĩrĩ: “Ta thikĩrĩriai wega. Inyuĩ mũkuoheria andũ a itũũra rĩu inene na mwena warĩo wa na thuutha. Mũtigaikare haraaya narĩo. Inyuothe mũikare mwĩiguĩte.
5 Èmi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú mi yóò súnmọ́ ìlú náà, nígbà tí àwọn ọkùnrin náà bá jáde sí wa, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìṣáájú, àwa yóò sì sá kúrò níwájú u wọn.
Niĩ na arĩa othe tũrĩ nao tũgũthengerera itũũra rĩu inene kuuma na mbere na rĩrĩa andũ acio mariumagara gũtũhũũra o ta ũrĩa meekire hĩndĩ ya mbere-rĩ, tũmoorĩre.
6 Wọn yóò sì lépa wa títí àwa ó fi tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà, nítorí tí wọn yóò wí pé, wọ́n ń sálọ kúrò ní ọ̀dọ̀ wa gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ṣe ní ìṣáájú. Nítorí náà bí a bá sá kúrò fún wọn,
Nao matũingatithie o nginya tũmaguucĩrĩrie biũ moime itũũra rĩu inene, nĩgũkorwo mariuga atĩrĩ, ‘Nĩ ithuĩ maroorĩra ta ũrĩa meekire rĩa mbere.’ Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa tũrĩĩmoorĩra-rĩ,
7 ẹ̀yin yóò dìde kúrò ní ibùba, ẹ ó sì gba ìlú náà. Olúwa Ọlọ́run yín yóò sì fi lé e yín lọ́wọ́.
inyuĩ na inyuĩ mũkĩre muume kũrĩa mũmooheirie, mũtharĩkĩre itũũra rĩu inene na mũrĩtunyane. Jehova Ngai wanyu nĩekũrĩneana moko-inĩ manyu.
8 Nígbà tí ẹ bá ti gba ìlú náà, kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́. Kí ẹ ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ. Mo ti fi àṣẹ fún un yín ná.”
Na rĩrĩ, mwarĩkia kwĩgwatĩra itũũra rĩu inene-rĩ, mũrĩcine. Ĩkai o ta ũrĩa Jehova aathanĩte gwĩkwo. Mũtigĩrĩre nĩ mweka ũguo ndamwatha.”
9 Nígbà náà ni Joṣua rán wọn lọ. Wọ́n sì lọ sí ibùba, wọ́n sì sùn ní àárín Beteli àti Ai, ní ìwọ̀-oòrùn Ai. Ṣùgbọ́n Joṣua wá dúró pẹ̀lú àwọn ènìyàn ní òru ọjọ́ náà.
Nake Joshua akĩmeera moimagare, nao magĩthiĩ harĩa maathiiaga kuoheria andũ a itũũra rĩu, na makĩĩhitha metereire gatagatĩ ka Betheli na Ai, mwena wa ithũĩro wa Ai, no Joshua araaranirie na andũ arĩa angĩ ũtukũ ũcio.
10 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Joṣua kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, òun àti àwọn olórí Israẹli, wọ́n wọ́de ogun lọ sí Ai.
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene, Joshua agĩcookanĩrĩria andũ ake, nake we mwene hamwe na atongoria a Isiraeli makĩmatongoria marorete Ai.
11 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ sì gòkè lọ, wọ́n sì súnmọ́ tòsí ìlú náà, wọ́n sì dé iwájú u rẹ̀. Wọ́n sì pàgọ́ ní ìhà àríwá Ai. Àfonífojì sì wà ní agbede-méjì wọn àti ìlú náà.
Mbũtũ yothe ya ita ĩrĩa yarĩ hamwe nake ĩgĩthiĩ yambatĩte, ĩgĩkuhĩrĩria itũũra rĩu inene mariumĩte na mbere. Nao makĩamba hema mwena wa gathigathini wa Ai, na hagĩkorwo nĩ haarĩ gĩtuamba gatagatĩ kao na itũũra rĩu inene.
12 Joṣua sì ti fi bí ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọmọ-ogun pamọ́ sí àárín Beteli àti Ai, sí ìwọ̀-oòrùn ìlú náà.
Joshua nĩakoretwo oete andũ ta 5,000 na akamaiga moheirie andũ kũu gatagatĩ ka Betheli na Ai, mwena wa ithũĩro wa itũũra rĩu inene.
13 Wọ́n sì yan àwọn ọmọ-ogun sí ipò wọn, gbogbo àwọn tí ó wà ní ibùdó lọ sí àríwá ìlú náà àti àwọn tí ó sá pamọ́ sí ìwọ̀-oòrùn rẹ̀. Ní òru ọjọ́ náà Joṣua lọ sí àfonífojì.
Magĩgĩatha thigari ciikare ciĩhaarĩirie o andũ handũ hao, iria ciothe ciarĩ kambĩ igĩikara mwena wa gathigathini wa itũũra rĩu inene, na iria cioheirie andũ mwena wa ithũĩro warĩo. Naguo ũtukũ ũcio Joshua agĩthiĩ kũraara kũu gĩtuamba-inĩ.
14 Nígbà tí ọba Ai rí èyí, òun àti gbogbo ọkùnrin ìlú náà yára jáde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù láti pàdé ogun Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ aginjù. Ṣùgbọ́n kò mọ̀ pé àwọn kan wà ní ibùba ní ẹ̀yìn ìlú náà.
Rĩrĩa mũthamaki wa Ai onire ũndũ ũcio, agĩũkĩra na ihenya rũciinĩ tene, akiumagara na ihenya hamwe na andũ othe a itũũra rĩu inene nĩguo agacemanie na Isiraeli marũe mbaara handũ hana haangʼethanĩire na Araba. No rĩrĩ, ndaigana kũmenya atĩ nĩmehithĩirwo na mwena wa thuutha wa itũũra rĩu inene.
15 Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sì ṣe bí ẹni tí a lé padà níwájú wọn, wọ́n sì sá gba ọ̀nà aginjù.
Nake Joshua na andũ a Isiraeli othe magĩĩtua ta mahũũrĩtwo magatoorio, nao makĩũra marorete na werũ-inĩ.
16 A sì pe gbogbo àwọn ọkùnrin Ai jọ láti lépa wọn, wọ́n sì lépa Joṣua títí wọ́n fi tàn wọ́n jáde nínú ìlú náà.
Nao andũ othe a itũũra rĩa Ai magĩĩtwo nĩguo mamarũmĩrĩre, nao magĩtengʼeria Joshua makĩguucĩrĩrio makiuma itũũra rĩao.
17 Kò sì ku ọkùnrin kan ní Ai tàbí Beteli tí kò tẹ̀lé Israẹli. Wọ́n sì fi ìlẹ̀kùn ibodè ìlú náà sílẹ̀ ní ṣíṣí, wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli.
Gũtirĩ mũndũ mũrũme o na ũmwe wa Ai kana Betheli ũtoimire gũthiĩ gũkinyĩra andũ a Isiraeli. Magĩtiga itũũra rĩu rĩtaahingĩtwo magĩtengʼeria andũ a Isiraeli.
18 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé, “Na ọ̀kọ̀ tí ó wà lọ́wọ́ rẹ sí Ai, nítorí tí èmi yóò fi ìlú náà lé ọ ní ọwọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì na ọ̀kọ̀ ọwọ́ rẹ̀ sí Ai.
Nake Jehova akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ambararia itimũ rĩu ũnyiitĩte na guoko, ũrĩrorie mwena wa Ai, nĩgũkorwo nĩngũneana itũũra rĩu inene moko-inĩ manyu.” Nĩ ũndũ ũcio Joshua akĩambararia itimũ rĩake akĩrĩroria Ai.
19 Bí ó ti ṣe èyí tán, àwọn ọkùnrin tí ó ba sì dìde kánkán kúrò ní ipò wọn, wọ́n sáré síwájú. Wọn wọ ìlú náà, wọ́n gbà á, wọ́n sì yára ti iná bọ̀ ọ́.
Na rĩrĩ, Joshua aarĩkia gwĩka ũguo, arũme arĩa moohetie andũ magĩũkĩra narua, magĩtengʼera na ihenya, magĩtoonya itũũra rĩu na makĩrĩtunyana, ningĩ makĩrĩgwatia mwaki o narua.
20 Àwọn ọkùnrin Ai bojú wo ẹ̀yìn, wọ́n rí èéfín ìlú náà ń gòkè lọ sí ọ̀run, ṣùgbọ́n wọn kò rí, ààyè láti sá àsálà lọ sí ibìkan kan, nítorí tí àwọn ará Israẹli tí wọ́n tí ń sálọ sí aginjù ti yípadà sí àwọn tí ń lépa wọn.
Na rĩrĩa andũ acio a Ai maarorire na thuutha na makĩona ndogo yumĩte itũũra rĩu yambatĩte na igũrũ-rĩ, nao makĩaga mweke wa gwĩthara na mwena o na ũrĩkũ, nĩgũkorwo andũ a Isiraeli arĩa morĩte marorete werũ-inĩ nĩmagarũrũkĩire acio maamatengʼeragia.
21 Nígbà tí Joṣua àti gbogbo àwọn ará Israẹli rí i pé àwọn tí ó bá ti gba ìlú náà, tí èéfín ìlú náà sì ń gòkè, wọ́n yí padà wọ́n sì kọlu àwọn ọkùnrin Ai.
Rĩrĩa Joshua na Isiraeli othe moonire atĩ andũ ao arĩa mooheirie andũ thuutha wa itũũra nĩmarĩtunyanĩte, na makĩona ndogo ĩgĩtoga kuuma itũũra, makĩgarũrũka na makĩũraga andũ acio a Ai.
22 Àwọn ọmọ-ogun tí ó ba náà sì yípadà sí wọn láti inú ìlú náà, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wà ní agbede-méjì àwọn ará Israẹli ní ìhà méjèèjì. Israẹli sì pa wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì jẹ́ kí ọ̀kan kí ó yè tàbí kí ó sálọ nínú wọn.
Nao andũ arĩa maamohetie makiuma itũũra rĩu inene matharĩkĩre. Andũ a Ai magĩgĩĩkĩrwo gatagatĩ ka andũ a Isiraeli, makĩmagĩa mbere na thuutha. Andũ a Isiraeli makĩmaniina, na matiatigirie mũndũ o na ũmwe arĩ muoyo, kana makĩreka o na ũmwe ahonoke.
23 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ọba Ai láààyè, wọ́n sì mu un tọ Joṣua wá.
No nĩmanyiitire mũthamaki wa Ai arĩ muoyo, makĩmũtwarĩra Joshua.
24 Nígbà tí Israẹli parí pípa gbogbo àwọn ìlú Ai ní pápá àti ní aginjù ní ibi tí wọ́n ti lépa wọn lọ, tí gbogbo wọ́n sì ti ojú idà ṣubú, tí a fi pa gbogbo wọn tan, gbogbo àwọn Israẹli sì padà sí Ai, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú.
Rĩrĩa andũ a Isiraeli maarĩkirie kũũraga andũ othe a Ai arĩa maarĩ gĩthaka-inĩ na kũu werũ-inĩ, kũrĩa maamatengʼereirie-rĩ, na rĩrĩa andũ acio othe maarĩkirie kũũragwo na rũhiũ rwa njora-rĩ, andũ a Isiraeli othe magĩcooka Ai na makĩũraga andũ arĩa othe maarĩ kuo.
25 Ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin àti obìnrin ni ó kú ní ọjọ́ náà—gbogbo wọn jẹ́ àwọn ènìyàn Ai.
Andũ arĩa mooragirwo mũthenya ũcio maarĩ andũ 12,000, arũme na andũ-a-nja; nao nĩo andũ othe a itũũra rĩa Ai.
26 Nítorí tí Joṣua kò fa ọwọ́ rẹ̀ tí ó di ọ̀kọ̀ mú sí ẹ̀yìn, títí ó fi pa gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú Ai run.
Nĩgũkorwo Joshua ndaigana gũthuna guoko kũrĩa kwambararĩtie itimũ rĩake nginya rĩrĩa aarĩkirie kũniina andũ arĩa othe maatũũraga Ai.
27 Ṣùgbọ́n Israẹli kó ẹran ọ̀sìn àti ìkógun ti ìlú yìí fún ara wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Joṣua.
Nao andũ a Isiraeli magĩkuuĩra ũhiũ na indo iria maatahĩte kuuma itũũra rĩu inene, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Joshua.
28 Joṣua sì jó Ai, ó sì sọ ọ́ di ààtàn, àní ahoro di òní yìí.
Nĩ ũndũ ũcio Joshua agĩcina Ai na akĩrĩtua hĩba ya mwanangĩko ya gũtũũra, gũgĩtuĩka kũndũ gũkirĩte ihooru nginya ũmũthĩ.
29 Ó sì gbé ọba Ai kọ́ orí igi, ó sì fi kalẹ̀ síbẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́. Bí oòrùn sì ti wọ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún wọn láti sọ òkú rẹ̀ kalẹ̀ kúrò ní orí igi, kí wọn sì wọ́ ọ jù sí àtiwọ ẹnu ibodè ìlú náà. Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé e ní orí, èyí tí ó wà títí di òní yìí.
Joshua agĩcooka agĩcuuria mũthamaki ũcio wa Ai mũtĩ igũrũ, akĩreka aikare ho o nginya hwaĩ-inĩ. Riũa rĩgĩthũa-rĩ, Joshua agĩathana atĩ mwĩrĩ ũcio ũrutwo mũtĩ igũrũ, ũikio hau itoonyero-inĩ rĩa kĩhingo gĩa itũũra rĩu, magĩcooka makĩũigĩrĩra hĩba nene ya mahiga, nayo ĩrĩ o ho nginya ũmũthĩ.
30 Nígbà náà ni Joṣua mọ pẹpẹ kan fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní òkè Ebali,
Thuutha wa ũguo Joshua agĩakĩra Jehova, o we Ngai wa Isiraeli, kĩgongona o kũu kĩrĩma-inĩ kĩa Ebali,
31 gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli. Ó sì kọ́ ọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé òfin Mose, pẹpẹ odindi òkúta, èyí tí ẹnìkan kò fi ohun èlò irin kàn rí. Wọ́n sì rú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà ní orí rẹ̀ sí Olúwa.
o ta ũrĩa Musa ndungata ya Jehova aathĩte andũ a Isiraeli. Aagĩakire o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo thĩinĩ wa Ibuku rĩa Watho wa Musa, kĩgongona kĩrĩ kĩa mahiga matarĩ maicũhie, hatarĩ indo cia wĩra cia kĩgera ikũhũthĩrwo ho. Igũrũ rĩakĩo makĩrutĩra Jehova maruta ma njino na magongona ma ũiguano.
32 Níbẹ̀, ní ojú àwọn ará Israẹli, Joṣua sì ṣe àdàkọ òfin Mose èyí tí ó ti kọ sí ara òkúta náà.
Nake Joshua akĩandĩka watho wa Musa igũrũ rĩa mahiga macio, aandĩkire andũ a Isiraeli marĩ ho makĩĩonagĩra.
33 Gbogbo Israẹli, àjèjì àti ọmọ ìlú, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà, olórí àti onídàájọ́ dúró ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àpótí ẹ̀rí Olúwa tí ó kọjú sí àwọn àlùfáà tí ó rù ú, tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi. Ìdajì àwọn ènìyàn náà dúró ní òkè Gerisimu, àwọn ìdajì si dúró ni òkè Ebali, gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ rí, pé kí wọn súre fún àwọn ènìyàn Israẹli.
Na rĩrĩ, andũ a Isiraeli othe, na andũ a kũngĩ na ene bũrũri o ũndũ ũmwe, hamwe na athuuri ao, na anene na atuithania ciira, makĩrũgama mĩena yeerĩ ya ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova mangʼetheire athĩnjĩri-Ngai, arĩa maarĩ Alawii na nĩo maarĩkuuaga. Nuthu ya andũ yarũgamĩte mbere ya kĩrĩma kĩa Gerizimu, na nuthu ĩyo ĩngĩ ĩkarũgama mbere ya kĩrĩma kĩa Ebali, o ta ũrĩa Musa ndungata ya Jehova aathanĩte mbere ĩyo rĩrĩa aarutanire ũhoro wa kũrathimaga andũ a Isiraeli.
34 Lẹ́yìn èyí, Joṣua sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin, ìbùkún àti ègún, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin.
Thuutha ũcio, Joshua agĩthoma ciugo ciothe cia Watho, agĩthoma irathimo o na agĩthoma irumi, o ta ũrĩa kwaandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩa Watho.
35 Kò sí ọ̀rọ̀ kan nínú gbogbo èyí tí Mose pàṣẹ tí Joṣua kò kà ní iwájú gbogbo àjọ Israẹli, títí fi kan àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn, àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn.
Gũtirĩ kiugo o na kĩmwe kĩa iria ciothe Musa aathanĩte Joshua ataathomeire kĩũngano kĩu gĩothe kĩa Isiraeli, o hamwe na andũ-a-nja na ciana na andũ o kũngĩ arĩa maatũũranagia nao.

< Joshua 8 >