< Joshua 8 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù, kí àyà kí ó má ṣe fò ọ́. Kó gbogbo àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú rẹ, kí ẹ gòkè lọ gbógun ti Ai. Nítorí mo ti fi ọba Ai, àwọn ènìyàn rẹ̀, ìlú u rẹ̀ àti ilẹ̀ ẹ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
L'Éternel dit ensuite à Josué: Ne crains point et ne t'effraie point; prends avec toi tous les gens de guerre, et lève-toi, monte à Aï. Regarde, j'ai livré entre tes mains le roi d'Aï, son peuple, sa ville et son pays.
2 Ìwọ yóò sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, ohun ìkógun wọn àti ohun ọ̀sìn wọn ni kí ẹ̀yin mú fún ara yín. Rán ènìyàn kí wọ́n ba sí ẹ̀yìn ìlú náà.”
Tu feras à Aï et à son roi, comme tu as fait à Jérico et à son roi; seulement vous en pillerez pour vous le butin et le bétail. Dresse une embuscade à la ville, par derrière.
3 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun jáde lọ láti dojúkọ Ai. Ó sì yan ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ogun rẹ̀ ti ó yakin, ó sì rán wọn lọ ní òru.
Josué se leva donc, avec tout le peuple propre à la guerre, pour monter à Aï; et Josué choisit trente mille hommes forts et vaillants, et il les envoya de nuit.
4 Pẹ̀lú àwọn àṣẹ wọ̀nyí: “Ẹ fi etí sílẹ̀ dáradára. Ẹ ba sí ẹ̀yìn ìlú náà. Ẹ má ṣe jìnnà sí i púpọ̀. Kí gbogbo yín wà ní ìmúrasílẹ̀.
Et il leur commanda, en disant: Voyez, vous serez en embuscade derrière la ville; ne vous éloignez pas beaucoup de la ville, et soyez tous prêts.
5 Èmi àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú mi yóò súnmọ́ ìlú náà, nígbà tí àwọn ọkùnrin náà bá jáde sí wa, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe ní ìṣáájú, àwa yóò sì sá kúrò níwájú u wọn.
Et moi, et tout le peuple qui est avec moi, nous nous approcherons de la ville. Et quand ils sortiront à notre rencontre, comme la première fois, nous fuirons devant eux,
6 Wọn yóò sì lépa wa títí àwa ó fi tàn wọ́n jáde kúrò ní ìlú náà, nítorí tí wọn yóò wí pé, wọ́n ń sálọ kúrò ní ọ̀dọ̀ wa gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ṣe ní ìṣáájú. Nítorí náà bí a bá sá kúrò fún wọn,
Et ils sortiront après nous, jusqu'à ce que nous les ayons attirés hors de la ville; car ils diront: Ils fuient devant nous comme la première fois. Et nous fuirons devant eux;
7 ẹ̀yin yóò dìde kúrò ní ibùba, ẹ ó sì gba ìlú náà. Olúwa Ọlọ́run yín yóò sì fi lé e yín lọ́wọ́.
Alors vous vous lèverez de l'embuscade, et vous vous emparerez de la ville; et l'Éternel votre Dieu la livrera entre vos mains.
8 Nígbà tí ẹ bá ti gba ìlú náà, kí ẹ sì ti iná bọ̀ ọ́. Kí ẹ ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ. Mo ti fi àṣẹ fún un yín ná.”
Or, quand vous aurez pris la ville, vous y mettrez le feu; vous ferez selon la parole de l'Éternel; voyez, je vous l'ai commandé.
9 Nígbà náà ni Joṣua rán wọn lọ. Wọ́n sì lọ sí ibùba, wọ́n sì sùn ní àárín Beteli àti Ai, ní ìwọ̀-oòrùn Ai. Ṣùgbọ́n Joṣua wá dúró pẹ̀lú àwọn ènìyàn ní òru ọjọ́ náà.
Josué les envoya donc, et ils allèrent se mettre en embuscade; et ils s'établirent entre Béthel et Aï, à l'occident d'Aï; mais Josué demeura cette nuit-là au milieu du peuple.
10 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Joṣua kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, òun àti àwọn olórí Israẹli, wọ́n wọ́de ogun lọ sí Ai.
Puis Josué se leva de bon matin et fit la revue du peuple; et il monta, lui et les anciens d'Israël, devant le peuple, vers Aï.
11 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ sì gòkè lọ, wọ́n sì súnmọ́ tòsí ìlú náà, wọ́n sì dé iwájú u rẹ̀. Wọ́n sì pàgọ́ ní ìhà àríwá Ai. Àfonífojì sì wà ní agbede-méjì wọn àti ìlú náà.
Tout le peuple propre à la guerre, qui était avec lui, monta et s'approcha; et ils vinrent vis-à-vis de la ville, et ils campèrent au nord d'Aï. La vallée était entre lui et Aï.
12 Joṣua sì ti fi bí ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọmọ-ogun pamọ́ sí àárín Beteli àti Ai, sí ìwọ̀-oòrùn ìlú náà.
Il prit alors environ cinq mille hommes, et les mit en embuscade entre Béthel et Aï, à l'occident de la ville.
13 Wọ́n sì yan àwọn ọmọ-ogun sí ipò wọn, gbogbo àwọn tí ó wà ní ibùdó lọ sí àríwá ìlú náà àti àwọn tí ó sá pamọ́ sí ìwọ̀-oòrùn rẹ̀. Ní òru ọjọ́ náà Joṣua lọ sí àfonífojì.
Ils disposèrent ainsi le peuple, tout le camp qui était au nord de la ville, et son arrière-garde à l'occident de la ville; puis Josué s'avança cette nuit-là au milieu de la vallée.
14 Nígbà tí ọba Ai rí èyí, òun àti gbogbo ọkùnrin ìlú náà yára jáde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù láti pàdé ogun Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ aginjù. Ṣùgbọ́n kò mọ̀ pé àwọn kan wà ní ibùba ní ẹ̀yìn ìlú náà.
Or, dès que le roi d'Aï vit cela, les hommes de la ville se hâtèrent, et se levèrent de bon matin. Le roi et tout son peuple sortirent pour la bataille, à la rencontre d'Israël, au lieu indiqué, du côté de la plaine; et il ne savait pas qu'il y avait une embuscade contre lui derrière la ville.
15 Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sì ṣe bí ẹni tí a lé padà níwájú wọn, wọ́n sì sá gba ọ̀nà aginjù.
Alors Josué et tout Israël, feignant d'être battus devant eux, s'enfuirent dans la direction du désert.
16 A sì pe gbogbo àwọn ọkùnrin Ai jọ láti lépa wọn, wọ́n sì lépa Joṣua títí wọ́n fi tàn wọ́n jáde nínú ìlú náà.
Et tout le peuple qui était dans la ville fut assemblé à grands cris pour les poursuivre. Ils poursuivirent Josué, et furent attirés hors de la ville;
17 Kò sì ku ọkùnrin kan ní Ai tàbí Beteli tí kò tẹ̀lé Israẹli. Wọ́n sì fi ìlẹ̀kùn ibodè ìlú náà sílẹ̀ ní ṣíṣí, wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli.
Et il ne resta pas un homme dans Aï ni dans Béthel, qui ne sortît à la poursuite d'Israël; et ils laissèrent la ville ouverte, et poursuivirent Israël.
18 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé, “Na ọ̀kọ̀ tí ó wà lọ́wọ́ rẹ sí Ai, nítorí tí èmi yóò fi ìlú náà lé ọ ní ọwọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì na ọ̀kọ̀ ọwọ́ rẹ̀ sí Ai.
Alors l'Éternel dit à Josué: Étends le javelot, qui est en ta main, vers Aï; car je la livrerai entre tes mains. Et Josué étendit vers la ville le javelot qui était en sa main.
19 Bí ó ti ṣe èyí tán, àwọn ọkùnrin tí ó ba sì dìde kánkán kúrò ní ipò wọn, wọ́n sáré síwájú. Wọn wọ ìlú náà, wọ́n gbà á, wọ́n sì yára ti iná bọ̀ ọ́.
Et ceux qui étaient en embuscade se levèrent promptement du lieu où ils étaient, et ils se mirent à courir, dès qu'il eut étendu sa main; et ils entrèrent dans la ville, s'en emparèrent, et se hâtèrent d'y mettre le feu.
20 Àwọn ọkùnrin Ai bojú wo ẹ̀yìn, wọ́n rí èéfín ìlú náà ń gòkè lọ sí ọ̀run, ṣùgbọ́n wọn kò rí, ààyè láti sá àsálà lọ sí ibìkan kan, nítorí tí àwọn ará Israẹli tí wọ́n tí ń sálọ sí aginjù ti yípadà sí àwọn tí ń lépa wọn.
Et les gens d'Aï, se tournant derrière eux, regardèrent, et voici, la fumée de la ville montait vers le ciel; et il n'y eut en eux aucune force pour fuir ici ou là. Et le peuple qui fuyait vers le désert, se retourna contre ceux qui le poursuivaient.
21 Nígbà tí Joṣua àti gbogbo àwọn ará Israẹli rí i pé àwọn tí ó bá ti gba ìlú náà, tí èéfín ìlú náà sì ń gòkè, wọ́n yí padà wọ́n sì kọlu àwọn ọkùnrin Ai.
Car Josué et tout Israël, voyant que ceux qui étaient en embuscade avaient pris la ville et que la fumée de la ville montait, retournèrent, et frappèrent les gens d'Aï.
22 Àwọn ọmọ-ogun tí ó ba náà sì yípadà sí wọn láti inú ìlú náà, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wà ní agbede-méjì àwọn ará Israẹli ní ìhà méjèèjì. Israẹli sì pa wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì jẹ́ kí ọ̀kan kí ó yè tàbí kí ó sálọ nínú wọn.
Les autres sortirent aussi de la ville à leur rencontre; ainsi ils furent enveloppés par les Israélites, ayant les uns d'un côté et les autres de l'autre. Et on les battit au point qu'il n'en resta aucun en vie ou qui s'échappât.
23 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ọba Ai láààyè, wọ́n sì mu un tọ Joṣua wá.
Et ils prirent vivant le roi d'Aï, et l'amenèrent à Josué.
24 Nígbà tí Israẹli parí pípa gbogbo àwọn ìlú Ai ní pápá àti ní aginjù ní ibi tí wọ́n ti lépa wọn lọ, tí gbogbo wọ́n sì ti ojú idà ṣubú, tí a fi pa gbogbo wọn tan, gbogbo àwọn Israẹli sì padà sí Ai, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú.
Et quand Israël eut achevé de tuer tous les habitants d'Aï dans les champs, dans le désert, où ils l'avaient poursuivi, et qu'ils furent tous tombés sous le tranchant de l'épée jusqu'au dernier, tous les Israélites retournèrent à Aï, et la firent passer au fil de l'épée.
25 Ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin àti obìnrin ni ó kú ní ọjọ́ náà—gbogbo wọn jẹ́ àwọn ènìyàn Ai.
Et tous ceux qui tombèrent, en ce jour-là, hommes et femmes, furent au nombre de douze mille, tous gens d'Aï.
26 Nítorí tí Joṣua kò fa ọwọ́ rẹ̀ tí ó di ọ̀kọ̀ mú sí ẹ̀yìn, títí ó fi pa gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú Ai run.
Et Josué ne retira point sa main, qu'il avait étendue avec le javelot, jusqu'à ce qu'on eût voué à l'interdit tous les habitants d'Aï.
27 Ṣùgbọ́n Israẹli kó ẹran ọ̀sìn àti ìkógun ti ìlú yìí fún ara wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Joṣua.
Seulement les Israélites pillèrent pour eux le bétail et le butin de cette ville-là, selon ce que l'Éternel avait commandé à Josué.
28 Joṣua sì jó Ai, ó sì sọ ọ́ di ààtàn, àní ahoro di òní yìí.
Josué brûla donc Aï, et la réduisit en un monceau perpétuel de ruines, jusqu'à ce jour.
29 Ó sì gbé ọba Ai kọ́ orí igi, ó sì fi kalẹ̀ síbẹ̀ títí di ìrọ̀lẹ́. Bí oòrùn sì ti wọ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún wọn láti sọ òkú rẹ̀ kalẹ̀ kúrò ní orí igi, kí wọn sì wọ́ ọ jù sí àtiwọ ẹnu ibodè ìlú náà. Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé e ní orí, èyí tí ó wà títí di òní yìí.
Il pendit au bois le roi d'Aï, jusqu'au soir; mais, au coucher du soleil, Josué commanda qu'on descendît son cadavre du bois; et on le jeta à l'entrée de la porte de la ville, et on éleva sur lui un grand monceau de pierres, qui est demeuré jusqu'à ce jour.
30 Nígbà náà ni Joṣua mọ pẹpẹ kan fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní òkè Ebali,
Alors Josué bâtit un autel à l'Éternel, le Dieu d'Israël, sur le mont Ébal,
31 gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli. Ó sì kọ́ ọ́ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé òfin Mose, pẹpẹ odindi òkúta, èyí tí ẹnìkan kò fi ohun èlò irin kàn rí. Wọ́n sì rú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà ní orí rẹ̀ sí Olúwa.
Comme Moïse, serviteur de l'Éternel, l'avait commandé aux enfants d'Israël, ainsi qu'il est écrit dans le livre de la loi de Moïse; un autel de pierres brutes, sur lesquelles on n'avait point levé le fer. Ils y offrirent des holocaustes à l'Éternel, et ils présentèrent des sacrifices de prospérités.
32 Níbẹ̀, ní ojú àwọn ará Israẹli, Joṣua sì ṣe àdàkọ òfin Mose èyí tí ó ti kọ sí ara òkúta náà.
Il écrivit aussi là, sur les pierres, une copie de la loi de Moïse, que celui-ci avait écrite devant les enfants d'Israël.
33 Gbogbo Israẹli, àjèjì àti ọmọ ìlú, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà, olórí àti onídàájọ́ dúró ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àpótí ẹ̀rí Olúwa tí ó kọjú sí àwọn àlùfáà tí ó rù ú, tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi. Ìdajì àwọn ènìyàn náà dúró ní òkè Gerisimu, àwọn ìdajì si dúró ni òkè Ebali, gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ rí, pé kí wọn súre fún àwọn ènìyàn Israẹli.
Et tout Israël, et ses anciens, et ses officiers, et ses juges, se tenaient des deux côtés de l'arche, devant les sacrificateurs, les Lévites, qui portaient l'arche de l'alliance de l'Éternel; les étrangers y étaient aussi bien que les Israélites, une moitié du côté du mont de Garizim, et l'autre moitié du côté du mont Ébal, comme Moïse, serviteur de l'Éternel, l'avait précédemment commandé, pour bénir le peuple d'Israël.
34 Lẹ́yìn èyí, Joṣua sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin, ìbùkún àti ègún, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin.
Après cela, Josué lut toutes les paroles de la loi, la bénédiction et la malédiction, selon tout ce qui est écrit dans le livre de la loi.
35 Kò sí ọ̀rọ̀ kan nínú gbogbo èyí tí Mose pàṣẹ tí Joṣua kò kà ní iwájú gbogbo àjọ Israẹli, títí fi kan àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wọn, àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn.
Il n'y eut rien de tout ce que Moïse avait commandé, que Josué ne lût en présence de toute l'assemblée d'Israël, des femmes, des petits enfants, et des étrangers qui marchaient au milieu d'eux.

< Joshua 8 >