< Joshua 7 >

1 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
Lékin Israil «haram» nersiler üstide itaetsizlik qildi; chünki Yehuda qebilisidin bolghan Zerahning ewrisi, Zabdining newrisi, Karmining oghli Aqan dégen kishi haram dep békitilgen nersilerdin alghanidi. Buning bilen Perwerdigarning ghezipi Israilgha qozghaldi.
2 Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
Yeshua Yérixodin Beyt-Elning sherq teripidiki Beyt-Awenning yénida bolghan Ayi shehirige birnechche adem ewetip ulargha: — U yerge chiqip u zéminni charlap kélinglar, dep buyrudi. Shuning bilen u ademler chiqip Ayi zéminini charlap keldi.
3 Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
Ular qaytip kélip, Yeshuagha: — Hemme xelqning u yerge bérishining hajiti yoq iken, ikki-üch mingche adem bolsila ayigha hujum qilip [uni igiliyeleydu; ] u yerde olturushluq kishiler az bolghachqa, pütkül xelqni aware qilip u yerge ewetmigin, — dédi.
4 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
Shuning bilen xelqtin üch mingche kishi u yerge chiqti; lékin bular Ayining ademliri aldidin qéchip kétishti.
5 Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
Ayining ademliri ulardin ottuz altiche kishini urup öltürdi; qalghanlarni sépil qowuqining aldidin Shébarimghiche qoghlap bérip, u yerdiki dawanda ularni urup meghlup qildi. Andin xelqning yüriki su bolup, qattiq sarasimge chüshti.
6 Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
Yeshua kiyimlirini yirtip, Israilning aqsaqalliri Perwerdigarning ehde sanduqining aldida yerge düm yiqilip, bashlirigha topilarni chéchip, u yerde kech kirgüche yétip qaldi.
7 Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
Yeshua: — Ah, Reb Perwerdigar, sen bizni Amoriylarning qoligha tapshurup halak qilish üchün, bu xelqni némishqa Iordan deryasining bu teripige ötküzgensen? Biz Iordan deryasining u teripide turuwergen bolsaq boptiken!
8 Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
Ey Rebbim! Israil öz düshmenlirining aldidin burulup qachqan yerde men némimu déyeleymen?
9 Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
Qanaaniylar, shundaqla zéminda barliq turuwatqanlar buni anglisa bizni qapsiwélip yer yüzidin namimizni üzüp tashlaydu; shu chaghda Sen ulugh nam-shöhriting üchün némilerni qilisen?! — dédi.
10 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
Lékin Perwerdigar Yeshuagha jawab bérip mundaq dédi: — «Ornungdin qop! Némishqa shundaq düm yatisen?
11 Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
Israil gunah qildi! Ular yene Men ulargha tapilighan ehdemge xilapliq qilip, haram dep békitilgen nersilerdin élip, oghriliq qilip, aldamchiliq qilip hem haram békitilgenni öz mallirining arisigha tiqip qoydi.
12 Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
Shunga Israillar düshmenlirining aldida tik turalmaydu; ular özlirini «haram» qilip békitip, mutleq yoqitilishqa yüzlen’gechke, düshmenlirining aldidin burulup arqisigha qachidu. Eger siler «haram» dep békitilgenni aranglardin tamamen yoq qilmisanglar, mundin kéyin men siler bilen bille bolmaymen.
13 “Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
Emdi sen turup xelqni pak-muqeddes qilip ulargha: — «Ete üchün özünglarni pak qilinglar; chünki Israilning Xudasi Perwerdigar shundaq deydu: — Ey Israil, sende «haram» dep békitilgen nerse bardur; bu haram nersini aranglardin yoq qilmighuchilik düshmenliringlarning aldida tik turalmaysiler.
14 “‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
Ete seherde siler qebile boyiche hazir qilinisiler; shundaq boliduki, Perwerdigar békitken qebile jemet-jemeti boyiche birdin-birdin aldigha kelsun; Perwerdigar békitken jemet aile-aile boyiche birdin-birdin hazir bolup aldigha kelsun; andin Perwerdigar békitken ailidiki erkekler birdin-birdin aldigha kélip hazir bolsun.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
Shundaq boliduki, haram dep békitilgen nersini öz yénida saqlighan kishi tépilghanda, Perwerdigarning ehdisige xilapliq qilghanliqi üchün hem shundaqla Israil ichide rezillik sadir qilghini üchün u we uninggha barliq tewe bolghanlar otta köydürülsun, — deydu», dep éytqin».
16 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
Yeshua etisi tang seherde turup Israilni aldigha yighip, qebile-qebilini hazir qiliwidi, Yehuda qebilisi békitildi;
17 Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
u Yehudaning jemetlirini hazir qiliwidi, Zarhiylar jemeti békitildi. U Zarhiylar jemetini aile-aile boyiche aldigha keltürüwidi, Zabdi dégen kishi békitildi.
18 Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
Zabdi öz ailisidiki erkeklerni birdin-birdin hazir qiliwidi, Yehuda qebilisidin Zerahning ewladi, Zabdining newrisi, Karmining oghli Aqan békitildi.
19 Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
Shuning bilen Yeshua Aqan’gha: — Ey oghlum, Israilning Xudasi Perwerdigargha shan-sherepni qayturup bérip, [Uning hörmiti üchün] qilghanliringni iqrar qilghin; mendin héchnémini yoshurmay, qilghiningning hemmisini manga éytqin, dédi.
20 Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
Aqan Yeshuagha jawab bérip: — Men derweqe Israilning Xudasi Perwerdigar aldida gunah qilip, mundaq-mundaq qildim:
21 nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
men oljining arisidin Shinarda chiqqan chirayliq bir ton’gha, ikki yüz shekel kümüsh, ellik shekel éghirliqtiki altun taxtigha közüm qizirip ularni éliwaldim. Mana, bu nersilerni chédirimning otturisidiki yerge kömüp qoydum, kümüsh ularning astida, — dédi.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
Shularni déwidi, Yeshua elchilerni ewetti, ular chédirgha yügürüp bardi we mana, nersiler derweqe chédirda yoshuruqluq bolup, kümüsh bularning astida idi.
23 Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
Ular bu nersilerni chédirdin élip chiqip Yeshuagha, shundaqla barliq Israillarning qéshigha keltürüp, Perwerdigarning aldigha qoydi.
24 Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
Andin Yeshua bilen pütkül Israil jamaiti qopup Zerahning oghli Aqanni, kümüsh, ton we altun taxta bilen qoshup, uning oghulliri bilen qizlirini, uyliri bilen éshekliri, qoyliri, chédiri bilen barliq teweliklirini élip Aqor jilghisigha keltürdi.
25 Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
Yeshua Aqan’gha: — Sen béshimizgha qanchilik apet keltürdüng! Mana, bügün Perwerdigar séning üstüngge apet keltüridu, — dédi. Andin pütkül Israil jamaiti uni chalma-kések qilip öltürdi. Ular ailisidikilernimu chalma-kések qilip öltürgendin kéyin, hemmini otta köydürüwetti.
26 Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.
Andin xalayiq bir chong döwe tashni uning üstige döwilep qoydi. Bügün’ge qeder u u yerde turmaqta. Buning bilen Perwerdigarning ghezipi yandi. Shuning bilen shu yerge «Apet jilghisi» [«(Aqor jilghisi)»] dep nam qoyuldi we bu kün’giche shundaq atalmaqta.

< Joshua 7 >