< Joshua 7 >

1 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
Și copiii lui Israel au făcut fărădelege în lucrul blestemat, căci Acan, fiul lui Carmi, fiul lui Zabdi, fiul lui Zerah, din tribul lui Iuda, a luat din ce era blestemat, și mânia DOMNULUI s-a aprins împotriva copiilor lui Israel.
2 Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
Și Iosua a trimis oameni din Ierihon la Ai, care este lângă Bet-Aven, în partea de est a Betelului și le-a vorbit, spunând: Urcați-vă și cercetați țara. Și oamenii s-au urcat și au cercetat cetatea Ai.
3 Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
Și s-au întors la Iosua și i-au spus: Să nu se urce tot poporul; cam două sau trei mii de oameni să se urce și să bată cetatea Ai; să nu faci ca tot poporul să ostenească acolo, fiindcă acei oameni sunt puțini.
4 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
Și s-au urcat din popor acolo aproape trei mii de bărbați, dar au fugit dinaintea bărbaților din Ai,
5 Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
Și bărbații din Ai au ucis dintre ei cam treizeci și șase de bărbați; și i-au urmărit dinaintea porții până la Șebarim și i-au bătut la coborâre; de aceea inima poporului s-a topit și s-a făcut ca apa.
6 Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
Și Iosua și-a sfâșiat hainele și a căzut cu fața la pământ înaintea chivotului DOMNULUI până seara, el și bătrânii lui Israel și și-au presărat țărână pe capete.
7 Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
Și Iosua a spus: Vai, Doamne DUMNEZEULE, pentru ce, oare, ai adus poporul acesta peste Iordan, ca să ne dai în mâna amoriților, pentru a ne nimici? De ne-am fi mulțumit și am fi rămas dincolo de Iordan!
8 Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
O, Doamne, ce voi spune când Israel va întoarce spatele înaintea dușmanilor săi?
9 Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
Deoarece canaaniții și toți locuitorii țării vor auzi și ne vor înconjura și ne vor stârpi numele de pe pământ; și ce vei face marelui tău nume?
10 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
Și DOMNUL i-a spus lui Iosua: Ridică-te! Pentru ce stai culcat astfel pe fața ta?
11 Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
Israel a păcătuit; și au încălcat de asemenea legământul meu, pe care li-l poruncisem; și chiar au luat din ce era blestemat și au și furat și s-au fățărnicit și au pus între lucrurile lor.
12 Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
De aceea copiii lui Israel nu au putut să stea înaintea dușmanilor lor, ci au întors spatele înaintea dușmanilor lor, căci copiii lui Israel au fost blestemați; nu voi mai fi cu voi dacă nu veți nimici pe cel blestemat din mijlocul vostru.
13 “Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
Ridică-te, sfințește poporul și spune: Sfințiți-vă pentru mâine, fiindcă astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Este un lucru blestemat în mijlocul tău, Israele; nu vei putea să stai înaintea dușmanilor tăi, până nu veți scoate ce este blestemat din mijlocul vostru.
14 “‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
De aceea să vă apropiați mâine dimineață după triburile voastre: și va fi așa că tribul pe care îl va arăta DOMNUL, să vină după familii; și familia pe care o va arăta DOMNUL, să vină după case; și casa pe care o va arăta DOMNUL, să vină bărbat cu bărbat.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
Și va fi că cel ce este arătat cu lucrul blestemat să fie ars în foc, el și tot ce are, pentru că a încălcat legământul DOMNULUI și pentru că a lucrat prostește în Israel.
16 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
Și Iosua s-a sculat dis-de-dimineață și a adus pe Israel după triburile sale; și a fost ales tribul lui Iuda.
17 Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
Și a adus familiile lui Iuda și a ales familia zerahiților; și a adus familia zerahiților, bărbat cu bărbat, și a fost ales Zabdi.
18 Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
Și a adus casa lui, bărbat cu bărbat, și a fost ales Acan, fiul lui Carmi, fiul lui Zabdi, fiul lui Zerah, din tribul lui Iuda.
19 Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
Și Iosua i-a spus lui Acan: Fiul meu, dă glorie DOMNULUI Dumnezeul lui Israel te rog și mărturisește înaintea lui și spune-mi acum ce ai făcut, nu-mi ascunde nimic.
20 Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
Și Acan a răspuns lui Iosua și a zis: Într-adevăr, am păcătuit împotriva DOMNULUI Dumnezeul lui Israel și așa am făcut:
21 nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
Când am văzut în pradă o manta frumoasă de Babilon și două sute de șekeli de argint și un lingou de aur, în greutate de cincizeci de șekeli, le-am poftit și le-am luat; și, iată, sunt ascunse în pământ în mijlocul cortului meu și argintul este dedesubt.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
Și Iosua a trimis mesageri și ei au alergat la cort; și, iată, era ascunsă în cortul lui și argintul dedesubt.
23 Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
Și le-au luat din mijlocul cortului și le-au adus la Iosua și la toți copiii lui Israel și le-au pus jos, înaintea DOMNULUI.
24 Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
Și Iosua și tot Israelul împreună cu el au luat pe Acan, fiul lui Zerah, și argintul și mantaua și lingoul de aur și pe fiii săi și pe fiicele sale și boii săi și măgarii săi și oile sale și cortul său și toate ale sale și le-au adus în Valea Acor.
25 Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
Și Iosua a spus: De ce ne-ai tulburat? DOMNUL te va tulbura în această zi. Și tot Israelul l-a ucis cu pietre și i-au ars în foc după ce i-au ucis cu pietre.
26 Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.
Și au ridicat deasupra lui o grămadă mare de pietre, care este până în această zi. Astfel DOMNUL s-a întors din înverșunarea mâniei sale. De aceea s-a pus numele locului aceluia Valea Acor, până în această zi.

< Joshua 7 >