< Joshua 7 >
1 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
De az Izráel fiai hűtlenül bántak vala a teljesen Istennek szentelt dolgokkal, mert elvőn a teljesen Istennek szentelt dolgokból Ákán, Kárminak fia (ki a Zabdi fia, ki a Zéra fia a Júda nemzetségéből); felgerjede azért az Úrnak haragja Izráel fiai ellen.
2 Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
Külde ugyanis Józsué férfiakat Jérikhóból, Aiba, a mely Bethaven mellett van, Bétheltől napkelet felé, és szóla nékik, mondván: Menjetek fel és kémleljétek ki azt a földet. És felmenének a férfiak és kikémlelék Ait.
3 Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
Majd visszatérének Józsuéhoz, és mondának néki: Ne menjen fel az egész nép; mintegy kétezer férfi, vagy mintegy háromezer férfi menjen fel, és megverik Ait. Ne fáraszd oda az egész népet, hiszen kevesen vannak azok!
4 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
Felméne azért oda a népből mintegy háromezer férfi; de elfutának Ai férfiai elől.
5 Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
És megölének közülök Ai férfiai mintegy harminczhat férfit, és üldözék őket a kaputól kezdve egész Sébarimig, és levágták őket a lejtőn. Azért megolvada a népnek szíve, és lőn olyanná, mint a víz.
6 Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
Józsué pedig megszaggatá az ő ruháit, és földre borula arczczal az Úrnak ládája előtt mind estvéig, ő és Izráel vénei, és port hintének a fejökre.
7 Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
És monda Józsué: Ah Uram Istenem! Miért is hozád által ezt a népet a Jordánon, hogyha az Emoreus kezébe adsz minket, hogy elveszítsen? Vajha úgy akartuk volna, hogy maradtunk volna túl a Jordánon!
8 Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
Óh Uram! mit mondjak, miután meghátrált Izráel az ő ellenségei előtt!
9 Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
Ha meghallják a Kananeusok és e földnek minden lakói, és ellenünk fordulnak, és kiirtják nevünket e földről: mit cselekszel majd a te nagy nevedért?
10 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
És monda az Úr Józsuénak: Kelj fel! Miért is borulsz te arczra?
11 Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
Vétkezett Izráel, és általhágták szövetségemet is, a melyet rendeltem nékik, mert elvettek a teljesen nékem szentelt dolgokból is, és loptak is és hazudtak is, és edényeik közé is dugdostak.
12 Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
Ezért nem bírtak megállni Izráel fiai az ő ellenségeik előtt, hátat fordítottak ellenségeiknek, mert átkozottakká lettek. Nem leszek többé veletek, ha ki nem vesztitek magatok közül azt a nékem szentelt dolgot.
13 “Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
Kelj fel, és tisztítsd meg a népet, és mondjad: Tisztítsátok meg magatokat holnapra, mert ezt mondá az Úr, Izráelnek Istene: Istennek szentelt dolog van közötted, Izráel! Nem állhatsz meg a te ellenségeid előtt, míg el nem távolítjátok közületek az Istennek szentelt dolgot.
14 “‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
Azért jőjjetek elő reggel nemzetségeitek szerint; a nemzetség pedig, a melyet bűnösnek jelent az Úr, jőjjön elő családonként; a család pedig, a melyet bűnösnek jelent az Úr, jőjjön elő házanként, a ház pedig, a melyet bűnösnek jelent az Úr, jőjjön elő férfianként.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
És lészen, hogy a ki az Istennek szentelt dologban bűnösnek találtatik, tűzzel égettessék meg, ő és mindene, a mije van, mivelhogy megszegte az Úrnak szövetségét, és mivel alávaló dolgot cselekedett Izráelben.
16 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
Felkele azért Józsué és jó reggel előállítá Izráelt az ő nemzetségei szerint, és bűnösnek jelenteték a Júda nemzetsége.
17 Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
Ekkor előállítá a Júda családjait, és bűnösnek jelenteték a Zéra családja; azután előállítá a Zéra családját férfianként, és bűnösnek jelenteték a Zabdi háza.
18 Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
És előállítá az ő házát férfianként, és bűnösnek találtaték Ákán, Kárminak fia, a ki Zabdi fia, a ki a Júda nemzetségéből való Zérának fia.
19 Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
Monda azért Józsué Ákánnak: Fiam, adj dicsőséget, kérlek, az Úrnak, Izráel Istenének, és tégy néki vallást, és add tudtomra, kérlek, nékem, mit cselekedtél, és el ne titkoljad tőlem!
20 Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
Ákán pedig felele Józsuénak, és monda: Bizony én vétkeztem az Úr ellen, Izráel Istene ellen, és ezt s ezt cselekedtem!
21 nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
Láték ugyanis a zsákmány közt egy jó babiloni köntöst, kétszáz siklus ezüstöt és egy arany vesszőt, a melynek súlya ötven siklus vala, és megkivántam ezeket, és elvevém ezeket, és ímé elrejtve vannak a földben, a sátoromnak közepében, az ezüst pedig alatta van.
22 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
Ekkor követeket külde Józsué s ezek a sátorba futának, és ímé, elrejtve vala az az ő sátorában, és az ezüst is alatta vala.
23 Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
Kivivék azért azokat a sátor közepéből, és vivék Józsuéhoz és Izráelnek minden fiához, és lerakák azokat az Úr előtt.
24 Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
Józsué pedig fogá Ákánt, a Zéra fiát, az ezüstöt, a köntöst és az aranyvesszőt, az ő fiait és leányait, az ő ökreit, szamarait és juhait, sátorát és mindent, a mije vala, és vele lévén az egész Izráel is, vivék azokat Akor völgyébe.
25 Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
És monda Józsué: Miért rontottál meg minket? Rontson meg téged e napon az Úr! És elborítá őt egész Izráel kövekkel, és megégeték őket tűzzel, miután megkövezték vala őket.
26 Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.
És nagy kőhalmot rakának feléje; megvan mind e napig. És megszűnék az Úr haragjának gerjedezése. Ezért nevezik ezt a helyet Akor völgyének mind e napig.