< Joshua 6 >

1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
Yeriho sepilining ⱪowuⱪ-dǝrwaziliri Israillarning sǝwǝbidin mǝⱨkǝm etilip, ⱨeqkim qiⱪalmaytti, ⱨeqkim kirǝlmǝytti.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
Pǝrwǝrdigar Yǝxuaƣa sɵz ⱪilip: — Mana, Mǝn Yeriho xǝⱨirini, padixaⱨini ⱨǝmdǝ batur jǝngqilirini ⱪolungƣa tapxurdum.
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Əmdi silǝr, yǝni barliⱪ jǝngqilǝr xǝⱨǝrni bir ⱪetim aylinip menginglar; altǝ küngiqǝ ⱨǝr küni xundaⱪ ⱪilinglar.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
Ⱨǝmdǝ yǝttǝ kaⱨin ǝⱨdǝ sanduⱪining aldida ⱪoqⱪar münggüzidin etilgǝn yǝttǝ burƣini kɵtürüp mangsun; yǝttinqi künigǝ kǝlgǝndǝ silǝr xǝⱨǝrni yǝttǝ ⱪetim aylinisilǝr; kaⱨinlar burƣilarni qalsun.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
Xundaⱪ boliduki, ular ⱪoqⱪar burƣiliri bilǝn sozup bir awaz qiⱪarƣinida, barliⱪ kixilǝr burƣining awazini anglap, ⱪattiⱪ tǝntǝnǝ ⱪilip towlisun; buning bilǝn xǝⱨǝrning sepilliri tegidin ɵrülüp qüxidu, ⱨǝrbir adǝm aldiƣa ⱪarap etilip kiridu, — dedi.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
Xuning bilǝn Nunning oƣli Yǝxua kaⱨinlarni qaⱪirip ularƣa: — Silǝr ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürüp menginglar; yǝttǝ kaⱨin Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪining aldida yǝttǝ ⱪoqⱪar burƣisini kɵtürüp mangsun, dedi
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
U hǝlⱪⱪǝ: — Qiⱪip xǝⱨǝrni aylininglar; ⱪoralliⱪ lǝxkǝrlǝr Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪining aldida mangsun, dedi.
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
Yǝxua buni hǝlⱪⱪǝ buyruƣandin keyin, Pǝrwǝrdigarning aldida yǝttǝ ⱪoqⱪar burƣisini kɵtürgǝn yǝttǝ kaⱨin aldiƣa mengip burƣilarni qaldi; Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪi bolsa ularning kǝynidin elip mengildi.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
Ⱪoralliⱪ lǝxkǝrlǝr burƣa qeliwatⱪan kaⱨinlarning aldida mangdi; ǝⱨdǝ sanduⱪining arⱪidin ⱪoƣdiƣuqi ⱪoxun ǝgixip mangdi. Kaⱨinlar mangƣaq burƣa qalatti.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
Yǝxua hǝlⱪⱪǝ buyrup: — Mǝn silǝrgǝ: «Towlanglar» demigüqǝ nǝ towlimanglar, nǝ awazinglarni qiⱪarmanglar, nǝ aƣzinglardin ⱨeqbir sɵzmu qiⱪmisun; lekin silǝrgǝ «Towlanglar» degǝn künidǝ, xu qaƣda towlanglar, — degǝnidi.
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
Xu tǝriⱪidǝ ular Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürüp xǝⱨǝrni bir aylandi. Halayiⱪ qedirgaⱨⱪa ⱪaytip kelip, qedirgaⱨda ⱪondi.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Ətisi Yǝxua tang sǝⱨǝrdǝ ⱪopti, kaⱨinlarmu Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪini yǝnǝ kɵtürdi;
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪining aldida yǝttǝ ⱪoqⱪar burƣisini kɵtürgǝn yǝttǝ kaⱨin aldiƣa mengip tohtimay qelip mangatti; [kaⱨinlar] mangƣaq burƣa qalƣanda, ⱪoralliⱪ lǝxkǝrlǝr ularning aldida mangdi, arⱪidin ⱪoƣdiƣuqi ⱪoxun ǝgixip mangdi.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Ikkinqi künimu ular xǝⱨǝrning ǝtrapini bir ⱪetim aylinip, yǝnǝ qedirgaⱨⱪa yenip kǝldi. Ular altǝ küngiqǝ xundaⱪ ⱪilip turdi.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
Yǝttinqi küni ular tang sǝⱨǝrdǝ ⱪopup, ohxax ⱨalǝttǝ yǝttǝ ⱪetim xǝⱨǝrning ǝtrapini aylandi; pǝⱪǝt xu künila ular xǝⱨǝrning ǝtrapini yǝttǝ ⱪetim aylandi.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
Yǝttinqi ⱪetim aylinip bolup, kaⱨinlar burƣa qalƣanda Yǝxua hǝlⱪⱪǝ: — Əmdi towlanglar! Qünki Pǝrwǝrdigar xǝⱨǝrni silǝrgǝ tapxurup bǝrdi!
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
Lekin xǝⱨǝr wǝ uning iqidiki barliⱪ nǝrsilǝr Pǝrwǝrdigarƣa mutlǝⱪ atalƣanliⱪi üqün [silǝrgǝ] «ⱨaram»dur; pǝⱪǝt paⱨixǝ ayal Raⱨab bilǝn uning pütün ɵyidikilǝrla aman ⱪalsun; qünki u biz ǝwǝtkǝn ǝlqilirimizni yoxurup ⱪoyƣanidi.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
Lekin silǝr ⱪandaⱪla bolmisun «ⱨaram» dǝp bekitilgǝn nǝrsilǝrdin ɵzünglarni tartinglar; bolmisa, «ⱨaram» ⱪilinƣan nǝrsilǝrdin elixinglar bilǝn ɵzünglarni ⱨaram ⱪilip, Israilning qedirgaⱨinimu ⱨaram ⱪilip uning üstigǝ apǝt qüxürisilǝr.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Əmma barliⱪ altun-kümüx, mis wǝ tɵmürdin bolƣan nǝrsilǝr bolsa Pǝrwǝrdigarƣa muⱪǝddǝs ⱪilinsun; ular Pǝrwǝrdigarning hǝzinisigǝ kirgüzulsun, — dedi.
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Xuning bilǝn hǝlⱪ towlixip, kaⱨinlar burƣa qaldi. Xundaⱪ boldiki, hǝlⱪ burƣa awazini angliƣinida intayin ⱪattiⱪ towliwidi, sepil tegidin ɵrülüp qüxti; hǝlⱪ uning üstidin ɵtüp, ⱨǝrbiri ɵz aldiƣa atlinip kirip, xǝⱨǝrni ixƣal ⱪildi.
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Ular ǝr-ayal bolsun, ⱪeri-yax bolsun, ⱪoy-kala wǝ exǝklǝr bolsun xǝⱨǝr iqidiki ⱨǝmmini ⱪiliqlap yoⱪatti.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
Yǝxua u zeminni qarlap kǝlgǝn ikki adǝmgǝ: — Silǝr u paⱨixǝ hotunning ɵyigǝ kirip, uningƣa bǝrgǝn ⱪǝsiminglar boyiqǝ uni wǝ uningƣa tǝwǝ bolƣanlarning ⱨǝmmisini elip qiⱪinglar, dedi.
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
Xuning bilǝn ikki qarliƣuqi yax yigit kirip, Raⱨabni ata-anisi bilǝn ⱪerindaxliriƣa ⱪoxup ⱨǝmmǝ nǝrsiliri bilǝn elip qiⱪti; ular uning barliⱪ uruⱪ-tuƣⱪanlirini elip kelip, ularni Israilning qedirgaⱨining sirtiƣa orunlaxturup ⱪoydi.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
Halayiⱪ xǝⱨǝrni wǝ xǝⱨǝr iqidiki ⱨǝmmǝ nǝrsilǝrni ot yeⱪip kɵydürüwǝtti. Pǝⱪǝt altun-kümüx, mis wǝ tɵmürdin bolƣan ⱪaqa-ⱪuqa ǝswablarni yiƣip, Pǝrwǝrdigarning ɵyining hǝzinisigǝ ǝkirip ⱪoydi.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
Lekin Yǝxua paⱨixǝ ayal Raⱨabni, ata jǝmǝtidikilǝrni wǝ uningƣa tǝwǝ bolƣanlirining ⱨǝmmisini tirik saⱪlap ⱪaldi; u bügüngiqǝ Israil arisida turuwatidu; qünki u Yǝxua Yerihoni qarlaxⱪa ǝwǝtkǝn ǝlqilǝrni yoxurup ⱪoyƣanidi.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
U qaƣda Yǝxua agaⱨ-bexarǝt berip: — Bu Yeriho xǝⱨirini ⱪaytidin yasaxⱪa ⱪopⱪan kixi Pǝrwǝrdigarning aldida ⱪarƣix astida bolidu; u xǝⱨǝrning ulini salƣanda tunji oƣlidin ayrilidu, xǝⱨǝrning ⱪowuⱪlirini orunlaxturidiƣan qaƣda kiqik oƣlidinmu ayrilidu, — dedi.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
Pǝrwǝrdigar Yǝxua bilǝn billǝ idi; uning nam-xɵⱨriti pütkül zeminƣa kǝng tarⱪaldi.

< Joshua 6 >