< Joshua 6 >
1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
Eriha Kenti'nin kapıları İsrailliler yüzünden sımsıkı kapatılmıştı. Ne giren vardı, ne de çıkan.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
RAB Yeşu'ya, “İşte Eriha'yı, kralını ve yiğit savaşçılarını senin eline teslim ediyorum” dedi,
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
“Siz savaşçılar, kentin çevresini günde bir kez olmak üzere altı gün dolanacaksınız.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
Koç boynuzundan yapılmış birer boru taşıyan yedi kâhin sandığın önünden gitsin. Yedinci gün kentin çevresini yedi kez dolanın; bu arada kâhinler borularını çalsınlar.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
Kâhinlerin koç boynuzu borularını uzun uzun çaldıklarını işittiğinizde, bütün halk yüksek sesle bağırsın. O zaman kentin surları çökecek ve herkes bulunduğu yerden dosdoğru kente girecek.”
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
Nun oğlu Yeşu kâhinleri çağırıp, “RAB'bin Antlaşma Sandığı'nı alın” dedi, “Yedi kâhin, ellerinde koç boynuzu borularla sandığın önünde yürüsün.”
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
Sonra halka, “Kalkın, kentin çevresini dolanmaya başlayın” dedi, “Silahlı öncüler RAB'bin Sandığı'nın önünden gitsin.”
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
Yeşu'nun bunları halka söylemesinden sonra, koç boynuzu birer boru taşıyan yedi kâhin borularını çalarak RAB'bin önünde ilerlemeye başladılar. Onları RAB'bin Antlaşma Sandığı izliyordu.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
Silahlı öncüler boru çalan kâhinlerin önünden, artçılar da sandığın arkasından ilerliyor, bu arada borular çalınıyordu.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
Yeşu halka şu buyruğu verdi: “Savaş naraları atmayın, sesinizi yükseltmeyin. ‘Bağırın’ diyeceğim güne dek ağzınızdan tek bir söz çıkmasın. Buyruğumu duyunca bağırın.”
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
Halk RAB'bin Sandığı'yla birlikte kentin çevresini bir kez dolandı, sonra ordugaha dönüp geceyi orada geçirdi.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Ertesi sabah Yeşu erkenden kalktı. Kâhinler de RAB'bin Sandığı'nı yüklendiler.
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
Koç boynuzu borular taşıyan yedi kâhin RAB'bin Sandığı'nın önünde ilerliyor, bir yandan da borularını çalıyorlardı. Silahlı öncüler onların önünden gidiyor, artçılar da RAB'bin Sandığı'nı izliyordu. Bu arada borular sürekli çalınıyordu.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Böylece ikinci gün de kentin çevresini bir kez dolanıp ordugaha döndüler. Aynı şeyi altı gün yinelediler.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
Yedinci gün erkenden, şafak sökerken kalkıp kentin çevresini aynı şekilde yedi kez dolandılar. Kentin çevresini yalnız o gün yedi kez dolandılar.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
Kâhinler yedinci turda borularını çalınca, Yeşu halka, “Bağırın! RAB kenti size verdi” dedi,
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
“Kent, içindeki her şeyle birlikte, RAB'be koşulsuz adanmıştır. Yalnız gönderdiğimiz ulakları saklamış olan fahişe Rahav'la evindekiler sağ bırakılacak.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
Sakın RAB'be adanan herhangi bir şeye el sürmeyin. Adadığınız şeyleri alırsanız İsrail'in ordugahını felakete ve yıkıma sürüklersiniz.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Bütün altınla gümüş, tunç ve demir eşya RAB'be ayrılmıştır. Bunlar RAB'bin hazinesine girecek.”
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Halk bağırmaya başladı, kâhinler de borularını çaldılar. Boru sesini işiten halk daha yüksek sesle bağırdı. Kentin surları çöktü. Herkes bulunduğu yerden dosdoğru kente girdi. Böylece kenti ele geçirdiler.
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Kadın erkek, genç yaşlı, küçük ve büyük baş hayvanlardan eşeklere dek, kentte ne kadar canlı varsa, hepsini kılıçtan geçirip yok ettiler.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
Yeşu ülkeye casus olarak gönderdiği iki adama, “O fahişenin evine gidin, ant içtiğiniz gibi, kadını ve bütün yakınlarını dışarı çıkarın” dedi.
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
Eve giren genç casuslar Rahav'ı, annesini, babasını, erkek kardeşleriyle bütün akrabalarını ve kendisine ait olan her şeyi alıp İsrail ordugahının yakınına getirdiler.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
Sonra kenti içindekilerle birlikte ateşe verdiler. Ancak altını ve gümüşü, tunç ve demir eşyayı RAB'bin Tapınağı'nın hazinesine koydular.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
Yeşu fahişe Rahav'a, babasının ev halkıyla yakınlarına dokunmadı. Yeşu'nun Eriha'yı araştırmak için gönderdiği ulakları saklayan Rahav, bugün de İsrailliler'in arasında yaşıyor.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
Bundan sonra Yeşu şöyle ant içti: “Bu kenti, Eriha'yı yeniden kurmaya kalkışan, RAB'bin lanetine uğrasın. Buna kalkışan kişi büyük oğlunu kaybetme pahasına temel atacak, en küçük oğlunu kaybetme pahasına da kentin kapılarını yerine takacak.”
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
RAB Yeşu'yla birlikteydi. Yeşu'nun ünü ülkenin her yanına yayıldı.