< Joshua 6 >

1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
A Jerycho było zamknione, i opatrzone przed synami Izraelskimi, i nikt z niego nie wychodził, ani do niego wchodził.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
Tedy rzekł Pan do Jozuego: Otom dał w ręce twoje Jerycho, i króla jego, i możne wojska jego.
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
A tak obchodzić będziecie miasto, wszyscy mężowie waleczni, około miasta chodząc raz na dzień; tak uczynicie po sześć dni.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
Przytem siedem kapłanów poniosą siedem trąb z rogów baranich, przed skrzynią; a dnia siódmego obejdziecie miasto siedem kroć, a kapłani trąbić będą w trąby.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
A gdy przewłocznie trąbić będą w trąby z rogów baranich, skoro usłyszycie głos trąby, wszystek lud uczyni okrzyk bardzo wielki, i upadnie mur miasta na miejscu swem, i wnijdzie lud do miasta, każdy przeciw miejscu, gdzie stał.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
Tedy wezwawszy Jozue, syn Nunów, kapłanów, rzekł do nich: weźmijcie skrzynię przymierza, a siedem kapłanów niech niosą siedem trąb z baranich rogów przed skrzynią Pańską.
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
Potem rzekł do ludu: Idźcie a obejdźcie miasto, a zbrojni niech idą przed skrzynią Pańską.
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
A gdy to Jozue ludowi powiedział, siedem kapłanów wziąwszy siedem trąb z rogów baranich, szli przed skrzynią Pańską, i trąbili w trąby, a skrzynia przymierza Pańskiego szła za nimi.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
A zbrojni szli przed kapłany trąbiącymi w trąby; ostatek też ludu pospolitego szedł za skrzynią, gdy idąc trąbiono w trąby.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
A ludowi przykazał Jozue, mówiąc: Nie będziecie wołać, ani będzie słyszan głos wasz, ani wynijdzie z ust waszych słowo, aż do dnia, którego wam rzekę: Wołajcie; i uczynicie okrzyk.
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
Tedy obeszła skrzynia Pańska miasto w około raz; i wrócili się do obozu, i zostali w obozie przez noc.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Wstał zasię Jozue rano, a kapłani wzięli skrzynię Pańską.
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
A siedem kapłanów wziąwszy siedem trąb z rogów baranich, przed skrzynią Pańską szli, idąc i trąbiąc w trąby; a zbrojni szli przed nimi, ostatek też ludu pospolitego szedł za skrzynią Pańską, gdy idąc trąbiono w trąby.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
A tak obeszli miasto drugi raz dnia wtórego, i wrócili się do obozu; i tak czynili po sześć dni.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
Ale dnia siódmego wstali rano na świtaniu, i obeszli miasto tymże sposobem siedem kroć; tylko dnia tego obeszli miasto siedem kroć.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
I stało się, gdy siódmy raz obchodzili, a kapłani trąbili w trąby, rzekł Jozue do ludu: Krzyczcież teraz; albowiem Pan podał wam miasto.
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
I niech będzie to miasto przeklęstwem Panu, ono, i wszystko co w niem jest; tylko Rachab wszetecznica żywo zostanie, ona i wszyscy, którzy z nią są w domu, gdyż utaiła posłów, któreśmy byli posłali.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
A wszakże się wy strzeżcie od rzeczy przeklętych, abyście się nie stali przeklęstwem, biorąc co z rzeczy przeklętych, abyście nie wprawili obozu Izraelskiego w przeklęstwo, i nie zamieszali go.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Ale wszystko srebro i złoto i naczynia miedziane i żelazne, święte będą Panu; do skarbu Pańskiego złożone będą.
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Tedy krzyczał lud, gdy zatrąbiono w trąby, albowiem gdy usłyszał lud głos trąb, krzyczał i lud wielkim głosem, i upadł mur na miejscu swem, i wszedł lud do miasta, każdy przeciw miejscu, gdzie stał, i wzięli miasto;
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
I wytracili wszystko, co było w mieście, męże i niewiasty, dzieci i starce; woły też i owce, i osły ostrzem miecza pobili.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
Ale dwom mężom, którzy szpiegowali onę ziemię, rzekł Jozue: Wnijdźcie do domu niewiasty wszetecznej, a wywiedźcie stamtąd niewiastę, i wszystko, co jej jest, jakoście jej przysięgli.
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
Tedy wszedłszy młodzieńcy oni, co byli wyszpiegowali ziemię, Rachabę, i ojca jej, matkę jej i bracią jej, i wszystko co było jej, i wszystkę rodzinę jej wywiedli, i zostawili je za obozem Izraelskim.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
Ale miasto spalili ogniem, i wszystko, co w niem było; tylko srebro i złoto, i naczynie miedziane, i żelazne, złożyli do skarbu domu Pańskiego.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
Rachabę także wszetecznicę, i dom ojca jej, i wszystko, co było jej, Jozue żywo zostawił, i mieszkała w pośrodku Izraela aż do teraźniejszego dnia, dla tego, iż utaiła posłów, które był posłał Jozue ku przeszpiegowaniu Jerycha.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
I wydał klątwę Jozue onego czasu, mówiąc: Przeklęty mąż przed Panem, któryby powstał a budował to miasto Jerycho; na pierworodnym swoim założy je, a na najmniejszym postawi bramy jego.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
I był Pan z Jozuem, a rozchodziła się sława jego po wszystkiej ziemi.

< Joshua 6 >