< Joshua 6 >

1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
Jérikhó pedig be- és elzárkózott vala az Izráel fiai miatt, se ki nem jöhetett, se be nem mehetett senki.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
És monda az Úr Józsuénak: Lásd! kezedbe adtam Jérikhót és királyát a sereg vitézeivel együtt.
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Azért járjátok körül a várost mind ti hadakozó emberek, megkerülvén egyszer a várost. Így cselekedjél hat napon át.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
És hét pap hordozzon hét kos-szarvból való kürtöt a láda előtt; a hetedik napon azonban hétszer kerüljétek meg a várost, a papok pedig kürtöljenek a kürtökkel.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
És ha majd belefúnak a kos-szarvba, mihelyt meghalljátok a kürtnek szavát, kiáltson fel az egész nép nagy kiáltással, és leszakad a város kőfala magától, és felmegy arra a nép, kiki az előtte való helyen.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
Előhívá azért Józsué, a Nún fia, a papokat és monda nékik: Vegyétek fel a frigyládát, hét pap pedig vigyen hét kos-szarvból való kürtöt az Úr ládája előtt.
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
A népnek pedig monda: Menjetek el, és kerüljétek meg a várost, a fegyveresek pedig menjenek az Úr ládája előtt.
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
És úgy lőn, a mint mondotta vala Józsué a népnek. A hét pap ugyanis, a kik a kos-szarvból való hét kürtöt vivék, az Úr előtt megy vala, és kürtölt vala a kürtökkel, az Úrnak frigyládája pedig utánok megy vala.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
A fegyveresek pedig előttök mennek vala a kürtölő papoknak, és a köznép követi vala a ládát, menvén és kürtölvén kürtökkel.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
A népnek pedig parancsolt vala Józsué, mondván: Ne kiáltsatok, hangotokat se hallassátok, és szó se jőjjön ki szátokból addig a napig, a míg azt mondom néktek: Kiáltsatok; és akkor kiáltsatok.
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
Körüljárák azért az Úrnak ládájával a várost, egyszer megkerülvén; azután visszatérének a táborba, és az éjszakát a táborban tölték.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Józsué pedig felkele jó reggel, és felvevék a papok az Úrnak ládáját.
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
És a hét pap, a kik a kos-szarvból való hét kürtöt vivék, az Úr ládája előtt megy vala folyton, és kürtöl vala a kürtökkel, a fegyveresek pedig előttök mennek vala, és a köznép követi az Úrnak ládáját, menvén és kürtökkel kürtölvén.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
A második napon is egyszer kerülék meg a várost, azután visszatérének a táborba. Így cselekedének hat napon át.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
És lőn a hetedik napon, hogy felkelének, mihelyt a hajnal feljöve, és megkerülék a várost a szokott módon hétszer; csak ezen a napon kerülék meg a várost hétszer.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
És lőn, hogy a hetedik forduláskor kürtölnek vala a papok a kürtökkel, Józsué pedig monda a népnek: Kiáltsatok, mert néktek adta az Úr a várost!
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
És legyen a város maga, és minden, a mi benne van, teljesen az Úrnak szentelve; csak a parázna Ráháb maradjon életben, ő és mindazok, a kik vele vannak a házban, mert elrejtette a követeket, a kiket küldöttünk volt.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
Mindazáltal ti óvjátok meg magatokat a teljesen Istennek szentelt dolgoktól, hogy miután néki szentelitek, el ne vegyetek a teljesen néki szentelt dolgokból, hogy Izráel táborát átkozottá ne tegyétek, és bajba ne keverjétek azt.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Hanem mivel minden ezüst- és arany-, meg réz- és vasedény az Úrnak van szentelve, az Úrnak kincse közé jusson.
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Kiálta azért a nép, mihelyt kürtölének a kürtökkel. Lőn ugyanis, a mint meghallá a nép a kürtnek szavát, kiálta a nép nagy kiáltással, és leszakada a kőfal magától, és felméne a nép a városba, kiki az előtte való helyen, és bevevék a várost.
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
És teljesen kipusztítának mindent, a mi csak vala a városban, a férfitól az asszonyig, a gyermektől az öregig, sőt az ökörig, juhig és a szamárig, fegyver élivel.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
A két férfiúnak pedig, a kik megkémlelték vala a földet, monda Józsué: Menjetek be a parázna asszonynak házába és hozzátok ki onnét az asszonyt és mindazt, a mije van, a miképen megesküdtetek néki.
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
Bemenének azért a kémlő ifjak, és kihozák Ráhábot, és az ő atyját, anyját és az ő atyjafiait, és mindazt, a mije vala, és minden cselédjét is kihozák, és helyezék őket Izráel táborán kivül.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
A várost pedig megégeték tűzzel, és mind azt, a mi benne vala; csakis az ezüstöt és aranyat és a réz- és vasedényeket rakták az Úr házának kincsei közé.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
A parázna Ráhábot pedig, és az ő atyjának háznépét és mindenét, a mije vala, élni hagyta vala Józsué, és ott lakik az Izráel között mind e mai napig; mert elrejtette vala a követeket, a kiket küldött volt Józsué, hogy kikémleljék Jérikhót.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
És átkot szóla Józsué azon a napon, mondván: Átkozott legyen az Úr előtt az a férfiú, a ki felkél, hogy megépítse e várost, Jérikhót! Az ő első szülöttjére rakja le annak alapját s legifjabb fiára állítsa fel annak kapuit!
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
És vala az Úr Józsuéval, és lőn híre az egész földön.

< Joshua 6 >