< Joshua 6 >
1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
Rĩu-rĩ, itũũra rĩu rĩa Jeriko rĩahingĩtwo biũ nĩ ũndũ wa andũ a Isiraeli. Gũtirĩ mũndũ woimaga nja kana agatoonya kuo.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
Nake Jehova akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Nĩneanĩte itũũra rĩĩrĩ rĩa Jeriko moko-inĩ maku, o hamwe na mũthamaki wakuo, o na njamba cia hinya ciakuo.
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Thiũrũrũkai itũũra rĩu inene hamwe na andũ anyu othe a ita riita rĩmwe. Mwĩke ũguo mĩthenya ĩtandatũ.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
Na athĩnjĩri-Ngai mũgwanja matongorie ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro, makuuĩte macoro mũgwanja mathondeketwo na hĩa cia ndũrũme. Mũthenya wa mũgwanja-rĩ, mũgaathiũrũrũka itũũra rĩu maita mũgwanja, nao athĩnjĩri-Ngai mathiĩ makĩhuhaga macoro.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
Rĩrĩa mũkaigua mahuha macoro na mũgambo mũnene, ĩra andũ othe makaanĩrĩra na rĩanĩrĩra inene mũno; naruo rũthingo rwa itũũra rĩu nĩrũkamomoka, nao andũ othe matoonye itũũra rĩu, o mũndũ athiĩte na mbere na kũrĩa arorete.”
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
Nĩ ũndũ ũcio, Joshua mũrũ wa Nuni agĩĩta athĩnjĩri-Ngai, akĩmeera atĩrĩ, “Oyai ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, na mũreke athĩnjĩri-Ngai mũgwanja thĩinĩ wanyu makuue macoro mũgwanja ma hĩa cia ndũrũme, matongorie ithandũkũ rĩu.”
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
Nake agĩatha andũ akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi mbere! Mũthiĩ mũthiũrũrũkĩirie itũũra, andũ arĩa meeohete indo cia mbaara matongorie ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova.”
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
Rĩrĩa Joshua aarĩkirie kwarĩria andũ, na athĩnjĩri-Ngai acio mũgwanja maakuuĩte macoro marĩa mũgwanja ma hĩa cia ndũrũme magĩthiĩ marĩ mbere ya Jehova, makĩhuhaga macoro mao, narĩo ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova rĩkĩmarũmĩrĩra.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
Nacio thigari iria ciarĩ na indo cia mbaara igĩthiĩ itongoretie athĩnjĩri-Ngai acio maahuhaga macoro, nacio thigari ingĩ ikĩrũmĩrĩra ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kuuma na thuutha. Hĩndĩ ĩyo yothe macoro no maahuhagwo.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
No rĩrĩ, Joshua nĩathĩte andũ akameera atĩrĩ, “Mũtikananĩrĩre na mũgambo wa mbaara, o na kana mũreke mĩgambo yanyu ĩiguo, o na mũtikoige ũndũ o na ũrĩkũ nginya mũthenya ũrĩa ngamwĩĩra mwanĩrĩre. Hĩndĩ ĩyo nĩguo mũkaanĩrĩra!”
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
Nĩ ũndũ ũcio akiuga ithandũkũ rĩu rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova rĩkuuo, rĩthiũrũrũkio itũũra-inĩ rĩu inene, riita rĩmwe. Andũ magĩcooka kambĩ na makĩraara kuo ũtukũ ũcio.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Rũciinĩ rũrũ rũngĩ, Joshua agĩũkĩra tene, nao athĩnjĩri-Ngai makĩoya ithandũkũ rĩu rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova.
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
Nao athĩnjĩri-Ngai arĩa mũgwanja makuuĩte macoro mũgwanja ma hĩa cia ndũrũme magĩthiĩ na mbere, makinyũkĩtie matongoretie ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova o makĩhuhaga macoro. Thigari iria ciarĩ na indo cia mbaara ikĩmatongoria, nacio thigari ingĩ ikĩrũmĩrĩra ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova kuuma na thuutha, o macoro makĩgambaga.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Nĩ ũndũ ũcio mũthenya wa keerĩ magĩthiũrũrũka itũũra rĩu inene riita rĩmwe, magĩcooka kambĩ. Meekire ũguo mĩthenya ĩtandatũ.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
Mũthenya wa mũgwanja-rĩ, magĩũkĩra ruoro rũgĩtema na magĩthiũrũrũka itũũra rĩu maita mũgwanja o ta ũrĩa meekaga mĩthenya ĩyo ĩngĩ, tiga atĩ mũthenya ũcio, maathiũrũrũkire itũũra rĩu inene maita mũgwanja.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
Nao makĩrĩthiũrũrũka riita rĩa mũgwanja-rĩ, rĩrĩa athĩnjĩri-Ngai maahuhire macoro, Joshua akĩĩra andũ atĩrĩ, “Anĩrĩrai mũno! Nĩgũkorwo Jehova nĩamũheete itũũra rĩĩrĩ!
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
Itũũra rĩĩrĩ inene na kĩndũ kĩrĩa gĩothe kĩrĩ thĩinĩ warĩo nĩikwamũrĩrwo Jehova, cianangwo. No Rahabu ũrĩa mũmaraya wiki, na andũ arĩa othe marĩ hamwe nake thĩinĩ wa nyũmba yake, mekũhonokio, tondũ nĩahithire athigaani arĩa twatũmĩte.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
Na rĩrĩ, mwĩmenyererei mũtikahutie indo icio ciamũrĩtwo cia kũniinwo, nĩgeetha mũtikerehere mwanangĩko nĩ ũndũ wa kuoya kĩndũ o na kĩrĩkũ gĩacio. Mũngĩcihutia nĩmũgatũma kambĩ ya Isiraeli ĩtuĩke ya kũniinwo, na mũmĩrehere thĩĩna.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Betha yothe na thahabu, na indo cia gĩcango na kĩgera, nĩ nyamũrĩre Jehova na no nginya ciigwo kĩgĩĩna-inĩ gĩake.”
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Rĩrĩa coro wahuhirwo, andũ makĩanĩrĩra, na rĩrĩa andũ maaiguire mũgambo wa coro, makĩanĩrĩra rĩanĩrĩra inene, naruo rũthingo rũkĩmomoka; nĩ ũndũ ũcio o mũndũ o mũndũ agĩtoonya itũũra rĩu, na makĩrĩtunyana.
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Nao makĩamũrĩra Jehova itũũra rĩu, na makĩananga kĩndũ o gĩothe kĩrĩa kĩarĩ muoyo kuo na rũhiũ rwa njora, arũme na andũ-a-nja, andũ ethĩ na akũrũ, na ngʼombe, na ngʼondu, na ndigiri.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
Joshua akĩĩra andũ arĩa eerĩ maathiĩte gũthigaana bũrũri ũcio atĩrĩ, “Thiĩi mũtoonye nyũmba ya mũtumia ũrĩa mũmaraya, mũmuumie nja hamwe na andũ ao othe, o ta ũrĩa mwamwĩrire na mwĩhĩtwa.”
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio aanake acio maarĩ athigaani magĩtoonya na makiumia Rahabu na nja, hamwe na ithe na nyina, na ariũ a nyina na andũ ao othe. Magĩkiumia andũ a nyũmba yake othe, makĩmaiga handũ kũu nja ya kambĩ ya Isiraeli.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
Magĩcooka magĩcina itũũra rĩu inene rĩothe, na kĩrĩa gĩothe kĩarĩ thĩinĩ warĩo, no betha na thahabu, na indo cia gĩcango na cia kĩgera, magĩciiga kĩgĩĩna-inĩ kĩa nyũmba ya Jehova.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
No rĩrĩ, Joshua nĩahonokirie Rahabu ũrĩa mũmaraya, hamwe na andũ a nyũmba yake na andũ ao othe, tondũ nĩahithire andũ arĩa Joshua aatũmĩte magathigaane Jeriko nake atũũranagia na andũ a Isiraeli nginya ũmũthĩ.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
Ihinda o ro rĩu, Joshua akĩĩhĩtithia andũ acio na mwĩhĩtwa, akiuga atĩrĩ, “Kũgwatwo nĩ kĩrumi maitho-inĩ ma Jehova-rĩ, nĩ mũndũ ũrĩa ũkaageria gwaka itũũra rĩĩrĩ inene rĩa Jeriko rĩngĩ: “Mũndũ ũrĩa ũgaaka mĩthingi ya itũũra rĩĩrĩ, nĩagakuĩrwo nĩ mũriũ wake wa irigithathi; na akĩrũgamia ihingo cia itũũra rĩĩrĩ, akuĩrwo nĩ mũriũ wake wa kĩhinga-nda.”
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
Nĩ ũndũ ũcio Jehova agĩkorwo arĩ hamwe na Joshua, nayo ngumo yake ĩkĩhunja kũndũ guothe bũrũri ũcio.