< Joshua 6 >
1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
Og Jeriko havde lukket for sig og var tillukket for Israels Børns Ansigt; der kunde ingen gaa ud, ej heller komme ind.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
Og Herren sagde til Josva: Se, i din Haand har jeg givet Jeriko og dens Konge, som ere vældige til Strid.
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Og I skulle gaa omkring Staden, alle Krigsmændene, saa at de gaa rundt om Staden een Gang; saaledes skal du gøre seks Dage.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
Og syv Præster skulle bære syv fuldtonende Basuner foran Arken, og paa den syvende Dag skulle I gaa om Staden syv Gange, og Præsterne skulle blæse i Basunerne.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
Og det skal ske, naar man blæser langsomt i Hornet, naar I høre Basunens Lyd, da skal alt Folket skrige med et stort Skrig; saa skal Stadens Mur falde lige ned, og Folket skal stige op, hver lige frem for sig.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
Saa kaldte Josva, Nuns Søn, ad Præsterne og sagde til dem: Bærer Pagtens Ark, og lader syv Præster bære de syv fuldtonende Basuner foran Herrens Ark.
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
Og han sagde til Folket: Gaar frem og gaar omkring Staden; og hvo som er bevæbnet, gaa frem foran Herrens Ark.
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
Og det skete, der Josva havde sagt dette til Folket, da gik syv Præster frem, som bare de syv fuldtonende Basuner for Herrens Ansigt, og blæste i Basunerne; og Herrens Pagts Ark fulgte efter dem.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
Og hver, som var bevæbnet, gik foran Præsterne, som blæste i Basunerne; og Troppen, som sluttede, gik efter Arken, medens man vedblev at blæse i Basunerne.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
Og Josva bød Folket og sagde: I skulle ikke skrige og ej lade eders Røst høre, og der skal ikke et Ord udgaa af eders Mund, indtil den Dag jeg siger til eder: Skriger! da skulle I skrige.
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
Saa gik Herrens Ark omkring, saa at den gik rundt om Staden een Gang; og de kom i Lejren og bleve om Natten i Lejren.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Og Josva stod tidlig op om Morgenen, og Præsterne bare Herrens Ark.
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
Og de syv Præster, som bare de syv fuldtonende Basuner foran Herrens Ark, gik stedse og blæste i Basunerne; og hver bevæbnet gik for deres Ansigt, og Troppen, som sluttede, gik efter Herrens Ark, medens man vedblev at blæse i Basunerne.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Og de gik omkring Staden paa den anden Dag een Gang, og de vendte tilbage til Lejren; saaledes gjorde de seks Dage.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
Og det skete paa den syvende Dag, da stode de tidlig op, der Morgenrøden brød frem, og de gik omkring Staden syv Gange, efter den samme Vis, kun at de den samme Dag kom syv Gange omkring Staden.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
Og det skete den syvende Gang, da blæste Præsterne i Basunerne, og Josva sagde til Folket: Skriger! thi Herren har givet eder Staden.
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
Og Staden, den og alt det, som er i den, skal være sat i Band for Herren; kun den Skøge Rahab skal leve, hun og alle de, som ere i Huset med hende; thi hun skjulte Budene, som vi udsendte.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
Kun maa I forvare eder for det bandlyste, at I ikke komme under Band og tage af det bandlyste og sætte Israels Lejr i Band og forstyrre den.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Men alt Sølv og Guld og Kobberkar og Jern, det skal være helligt for Herren; det skal komme til Herrens Liggendefæ.
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Og Folket skreg, da de blæste i Basunerne; ja det skete, der Folket hørte Basunernes Lyd, da skreg Folket med et stort Skrig, og Muren faldt lige ned, og Folket steg op i Staden, hver lige frem for sig, og de indtoge Staden.
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Og de ødelagde alt det, som var i Staden, baade Mand og Kvinde, baade ung og gammel, og Øksne og Faar og Asener, med skarpe Sværd.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
Men Josva sagde til de to Mænd, som havde spejdet Landet: Gaar i den Kvindes, den Skøges Hus, og udfører Kvinden derfra og alt det, som hører hende til, som I have svoret hende.
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
Da gik de unge Karle, Spejderne, ind og udførte Rahab og hendes Fader og hendes Moder og hendes Brødre, og alt det, som hørte hende til, og al hendes Slægt udførte de; og de lode dem blive uden for Israels Lejr.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
Men Staden opbrændte de med Ild og alt det, som var i den; alene Sølvet og Guldet og Kobberkarrene og Jernet, det gave de til Herrens Huses Liggendefæ.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
Men Josva lod Rahab, den Skøge, og hendes Faders Hus og alt det, som hørte hende til, leve, og hun boede midt iblandt Israel indtil denne Dag; thi hun skjulte Budene, som Josva havde udsendt til at spejde Jeriko.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
Og paa den samme Tid tog Josva en Ed af dem og sagde: Forbandet være den Mand for Herrens Ansigt, som opstaar og bygger denne Stad Jeriko; naar han lægger dens Grundvold, koste det ham hans førstefødte, og naar han sætter dens Porte, koste det ham hans yngste Søn.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
Saa var Herren med Josva, og hans Rygte var over det ganske Land.