< Joshua 6 >

1 Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
Israel kaminawk zit o pongah, Jeriko vangpui khongkha to kacakah khah o; mi doeh tasa bangah caeh o ai, vangpui thungah doeh akun o ai.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
To naah Angraeng mah Joshua khaeah, Khenah, Na ban ah Jeriko vangpui hoi nawnto siangpahrang doeh, thacak misatuh kaminawk doeh, na ban ah kang paek boeh.
3 Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Vangpui to takui oh, misatuh kaminawk boih hoiah, vangpui to vaito takui oh; to tiah vai tarukto takui oh.
4 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
Qaima sarihto mah Angraeng ih thingkhong hmaa ah tuu takii hoi sak ih mongkah to sin o tih; toe ni sarihto naah, vangpui to vai sarihto takui oh; to naah qaimanawk mah mongkah to ueng o tih.
5 Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
Nihcae mah tuu takii hoi sak ih mongkah kasawkah ueng o moe, mongkah lok to na thaih o naah, kaminawk boih mah tha hoi hang oh; to pacoengah loe vangpui sipae to amtimh tih boeh; to naah kaminawk boih angmacae hmabang ah katoengah caehsak tahang ah, tiah a naa.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
To pongah Nun capa Joshua mah qaimanawk to kawk moe, nihcae khaeah, Angraeng ih thingkhong to apu oh, qaima sarihto mah Angraeng ih thingkhong hmaa ah tuu takii hoi sak ih mongkah sarihto sin o nasoe, tiah a naa.
7 Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
Anih mah kaminawk khaeah, Hmabang ah caeh oh, vangpui to takui oh! Maiphaw maica sin kaminawk Angraeng ih thingkhong hmaa ah caeh oh, tiah naa.
8 Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
Joshua mah kaminawk khaeah lokthuih pacoengah, qaima sarihtonawk loe tuu takii hoi sak ih mongkah sarihto sin o, Angraeng ih thingkhong hmaa ah a caeh o moe, mongkah to ueng o; Angraeng ih thingkhong loe nihcae hnukah bang.
9 Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
Maiphaw sin kaminawk loe, mongkah ueng qaimanawk ih ahnuk ahmaa caeh o; qaimanawk loe mongkah ueng o moe, hmabangah caeh o poe.
10 Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
Joshua mah kaminawk khaeah, Kai mah hangh han kang thuih ih ni pha ai karoek to lok apae o hmah, hraw-ang o hmah; hangh han lok kang thuih o naah hang oh, tiah naa.
11 Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
To pongah Angraeng ih thingkhong hoi vangpui to takui o; vaito takui o pacoengah, angmacae ohhaih ahmuen ah amlaem o moe, to ah atai o.
12 Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Joshua loe khawnbang khawnthaw ah angthawk, qaimanawk mah Angraeng ih thingkhong to aput o.
13 Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
Tuu takii hoi sak ih mongkah sin qaima sarihtonawk loe, Angraeng ih thingkhong hmaa ah caeh o poe moe, mongkah to ueng o; maiphaw sin kaminawk loe Angraeng ih thingkhong hmaa ah caeh o; toe hnukah kaom misatuh kaminawk loe Angraeng ih thingkhong hnukah caeh o, qaimanawk loe mongkah ueng hoiah caeh o poe.
14 Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
Ni hnetto haih naah doeh vangpui to vaito takui o, to pacoengah atai o haih ahmuen ah amlaem o let; to tiah ni sarihto takui o.
15 Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
Ni sarihto naah loe khawnbang khawnthaw ah angthawk o moe, a sak o zong ih baktih toengah, vangpui to vai sarihto takui o; to na ni khue ah vangpui to vai sarihto takui o.
16 Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
Vai sarihto takui o moe, qaimanawk mah mongkah ueng o naah, Joshua mah kaminawk khaeah, Hang oh! Angraeng mah vangpui to ang paek o boeh.
17 Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
Vangpui hoi athung ah kaom hmuennawk boih to paro oh loe, lokkamhaih hoiah Angraeng khaeah paek oh; aicae mah patoeh ih misa khen kami hnik to hawk pongah, tangyat zaw kami Rahab hoi anih ih imthung takoh kaminawk khue to pathlung oh.
18 Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
Toe Sithaw mah la o hmah, tiah thuih ih tangoeng ah kaom hmuen to caeh o taak ah; to tih ai nahaeloe nangcae nuiah kasae pha moeng tih; Israel kaminawk ataihaih ahmuen ah kasae omsak kami hoi raihaih phasak kami ah om moeng tih.
19 Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
Toe phoisa, sui, sum, sum kamlingnawk hoiah sak ih laom sabaenawk loe Angraeng hanah ciimcai o sak loe, Angraeng ih hmuenmae pakuemhaih thungah suem oh, tiah a naa.
20 Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
Qaimanawk mah mongkah to ueng o naah, kaminawk to hangh o; kaminawk mah mongkah uenghaih lok thaih o moe, tha hoi hangh o naah, sipae to amtim rup; to naah kaminawk boih angmacae hmaa ah katoengah vangpui thungah akun o moe, vangpui to a lak o.
21 Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Vangpui thung kaom nongpa, nongpata, nawkta, mitong, maitaw, tuu, laa hrangnawk hoi vangpui thung kaom hmuennawk boih to sumsen hoiah paro pae o boih.
22 Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
Joshua mah tamquta hoi prae khet han patoeh ih kami hnik khaeah, Tangyat zaw kami im ah caeh hoih loe, anih khaeah lokkamhaih na sak hoi baktih toengah, nongpata angmah hoi a imthung ah kaom kaminawk boih to angzo haih ah, tiah a naa.
23 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
To pongah prae khen thendoeng hnik loe caeh hoi moe, Rahab, amno hoi ampa, angmah ih nawkamyanawk hoi a tawnh ih hmuennawk boih angzoh hoi haih; angmah ih imthung takoh kaminawk lak boih pacoengah, Israel kaminawk ataihaih tasa bangah oh o sak.
24 Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
To pacoengah vangpui hoi athung ah kaom hmuennawk to hmai hoiah a thlaek o boih; toe phoisa, sui, sum, sum kamlingnawk hoiah sak ih laom sabaenawk loe, Angraeng ih hmuenmae patunghaih im ah a suek o.
25 Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
Toe Jeriko vangpui khet han patoeh ih kami hnik to a hawk pongah, Joshua mah tangyat zaw Rahab hoi ampa imthung takoh kaminawk boih ih hinghaih to pathlung pae; to nongpata loe vaihni ni khoek to Israel kaminawk khaeah oh.
26 Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
To naah Joshua mah, Hae Jeriko vangpui pathawk moe, sah let kami loe, Angraeng hmaa ah tangoenghaih tong nasoe; anih loe a calu dung ah vangpui ahmuen sak amtong nasoe loe, a capa asoi dung ah sipae khongkhanawk to thungh nasoe, tiah lokkamhaih to a sak.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.
Joshua khaeah Angraeng oh pongah, anih ih ahmin to prae boih ah amthang.

< Joshua 6 >