< Joshua 5 >
1 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Amori ti ìlà-oòrùn Jordani àti gbogbo àwọn ọba Kenaani tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jordani gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Israẹli títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pami, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojúkọ àwọn ọmọ Israẹli.
A gdy wszyscy królowie amoryccy, którzy [mieszkali] po zachodniej stronie Jordanu, i wszyscy królowie Kanaanu, którzy [mieszkali] nad morzem, usłyszeli, że PAN wysuszył wody Jordanu przed synami Izraela, aż się przeprawili, struchlało ich serce i stracili całą odwagę wobec synów Izraela.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kejì.”
W tym czasie PAN powiedział do Jozuego: Zrób sobie ostre noże i ponownie obrzezaj synów Izraela.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà, ní Gibiati-Haralotu.
Jozue zrobił więc sobie ostre noże i obrzezał synów Izraela na pagórku napletków.
4 Wàyí o, ìdí tí Joṣua fi kọ wọ́n nílà nìyìí. Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Ejibiti jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní aginjù ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
A oto powód, dla którego Jozue ich obrzezał: Cały lud, który wyszedł z Egiptu, płci męskiej, wszyscy wojownicy, pomarli na pustyni, w drodze po wyjściu z Egiptu.
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Ejibiti ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú aginjù lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Ejibiti ni wọn kò kọ ní ilà.
Cały lud, który wyszedł, był obrzezany. Lecz cały lud, który urodził się na pustyni, w drodze po wyjściu z Egiptu, nie był obrzezany.
6 Àwọn ará Israẹli rìn ní aginjù fún ogójì ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Ejibiti fi kú, nítorí wọn kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fi fun wa, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin.
Czterdzieści lat bowiem synowie Izraela chodzili po pustyni, aż wymarł cały naród wojowników, którzy wyszli z Egiptu, gdyż nie słuchali głosu PANA. Przysiągł im PAN, że nie pozwoli im zobaczyć ziemi, którą PAN pod przysięgą obiecał ich ojcom, że nam ją da, ziemię opływającą mlekiem i miodem.
7 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Joṣua kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tí ì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.
Ich synów, których wzbudził na ich miejsce, Jozue obrzezał. Byli bowiem nieobrzezani, gdyż ich nie obrzezano w drodze.
8 Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.
A gdy już cały lud został obrzezany, pozostał on na swoim miejscu w obozie aż do wyzdrowienia.
9 Nígbà náà ní Olúwa wí fún Joṣua pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Ejibiti kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gilgali títí ó fi di òní yìí.
Potem PAN powiedział do Jozuego: Dzisiaj zdjąłem z was hańbę Egiptu. Dlatego to miejsce nazywa się Gilgal aż do dziś.
10 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù náà, nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gilgali ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko, àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ọdún àjọ ìrékọjá.
Wtedy synowie Izraela rozbili obóz w Gilgal i obchodzili święto Paschy czternastego dnia tego miesiąca, wieczorem, na równinach Jerycha.
11 Ní ọjọ́ kejì àjọ ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan an ni, wọ́n jẹ nínú àwọn ìre oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.
Nazajutrz po święcie Paschy jedli z plonów tej ziemi, chleby przaśne i prażone ziarno, tego samego dnia.
12 Manna náà sì tan ní ọjọ́ kejì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde, kò sì sí manna kankan mọ́ fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ ìre oko ilẹ̀ Kenaani.
I następnego dnia po tym, jak zaczęli jeść zboża tej ziemi, ustała manna; i synowie Izraela już więcej manny nie mieli, ale jedli tegoroczne plony ziemi Kanaan.
13 Nígbà tí Joṣua súnmọ́ Jeriko, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Joṣua sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀tá a wa?”
A gdy Jozue był w pobliżu Jerycha, podniósł oczy i spojrzał, a oto mąż stał naprzeciw niego z wydobytym mieczem w ręku. Jozue podszedł do niego i zapytał: Czy ty jesteś po naszej stronie, czy po stronie naszych wrogów?
14 “Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Joṣua sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”
A on odpowiedział: Nie, gdyż jako wódz wojska PANA teraz przyszedłem. Wtedy Jozue upadł twarzą do ziemi, oddał pokłon i zapytał: Co mój Pan rozkaże swemu słudze?
15 Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀.
I wódz wojska PANA powiedział do Jozuego: Zdejmij obuwie ze swoich nóg, bo miejsce, na którym stoisz, jest święte. I Jozue tak uczynił.