< Joshua 5 >

1 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Amori ti ìlà-oòrùn Jordani àti gbogbo àwọn ọba Kenaani tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jordani gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Israẹli títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pami, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojúkọ àwọn ọmọ Israẹli.
I stało się, gdy usłyszeli wszyscy królowie Amorejscy, którzy mieszkali za Jordanem ku zachodowi, i wszyscy królowie Chananejscy, którzy mieszkali nad morzem, że wysuszył Pan wody Jordańskie przed syny Izraelskimi, aż się przeprawili, upadło serce ich, tak iż nie został więcej w nich duch przed oblicznością synów Izraelskich.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kejì.”
Onegoż czasu rzekł Pan do Jozuego: Uczyń sobie noże ostre, a znowu obrzeż syny Izraelskie po wtóre.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà, ní Gibiati-Haralotu.
I uczynił sobie Jozue noże ostre i obrzezał syny Izraelskie na pagórku nieobrzezek.
4 Wàyí o, ìdí tí Joṣua fi kọ wọ́n nílà nìyìí. Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Ejibiti jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní aginjù ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
A tać była przyczyna, dla czego je obrzezał Jozue: Wszystek lud, który wyszedł z Egiptu, płci męskiej, wszyscy mężowie wojenni, pomarli byli na puszczy, w drodze, gdy wyszli z Egiptu.
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Ejibiti ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú aginjù lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Ejibiti ni wọn kò kọ ní ilà.
Bo obrzezan był wszystek on lud, co wyszedł; ale wszystek lud, który się zrodził na puszczy, w drodze po wyjściu z Egiptu, nie był obrzezany.
6 Àwọn ará Israẹli rìn ní aginjù fún ogójì ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Ejibiti fi kú, nítorí wọn kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fi fun wa, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin.
(Albowiem przez czterdzieści lat chodzili synowie Izraelscy po puszczy, aż poginął wszystek on naród mężów wojennych, którzy byli wyszli z Egiptu, którzy nie słuchali głosu Pańskiego, którym przysiągł Pan, iż im nie miał okazać ziemi, o którą przysiągł Pan ojcom ich, iż nam ją dać miał, ziemię opływającą mlekiem i miodem.)
7 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Joṣua kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tí ì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.
Ale syny ich, które wystawił na miejsca ich, te obrzezał Jozue, bo byli w nieobrzezce; bo ich nie obrzezano w drodze.
8 Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.
A gdy już wszystek lud był obrzezany, mieszkał na miejscu swem w obozie, aż się wygoili.
9 Nígbà náà ní Olúwa wí fún Joṣua pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Ejibiti kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gilgali títí ó fi di òní yìí.
Potem rzekł Pan do Jozuego: Dzisiajm zdjął pohańbienie Egipskie z was; i nazwano imię miejsca onego Galgal, aż do dnia tego.
10 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù náà, nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gilgali ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko, àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ọdún àjọ ìrékọjá.
Tedy położyli się obozem synowie Izraelscy w Galgal, a obchodzili święto przejścia czternastego dnia miesiąca w wieczór na polach Jerycha.
11 Ní ọjọ́ kejì àjọ ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan an ni, wọ́n jẹ nínú àwọn ìre oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.
I jedli z urodzajów onej ziemi nazajutrz po święcie przejścia chleby przaśne, i kłosy prażone onegoż dnia.
12 Manna náà sì tan ní ọjọ́ kejì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde, kò sì sí manna kankan mọ́ fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ ìre oko ilẹ̀ Kenaani.
I przestała manna nazajutrz, gdy poczęli jeść zboża onej ziemi; i nie mieli więcej synowie Izraelscy manny, ale jedli z urodzajów ziemi Chananejskiej onegoż roku.
13 Nígbà tí Joṣua súnmọ́ Jeriko, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Joṣua sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀tá a wa?”
I stało się, gdy Jozue był u Jerycha, że podniósł oczu swych a ujrzał, a oto mąż stał przeciwko niemu, mając miecz swój dobyty w ręce swej; i przystąpiwszy do niego Jozue, rzekł mu: Z naszychżeś ty, czy z nieprzyjaciół naszych?
14 “Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Joṣua sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”
A on rzekł: Nie; alem Ja hetman wojska Pańskiego, terazem przyszedł. Tedy upadłszy Jozue obliczem swem na ziemię, pokłonił się, i rzekł mu: Cóż Pan mój mówi do sługi swego?
15 Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀.
I rzekł hetman wojska Pańskiego do Jozuego: Zzuj obuwie twoje z nóg twoich, bo miejsce, na którem stoisz, święte jest; i uczynił tak Jozue.

< Joshua 5 >