< Joshua 5 >

1 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Amori ti ìlà-oòrùn Jordani àti gbogbo àwọn ọba Kenaani tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jordani gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Israẹli títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pami, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojúkọ àwọn ọmọ Israẹli.
A LOHE na'lii a pau o ka Amora, ka poe i noho ma ia aoao o Ioredane ma ke komohana, a me na'lii a pau o ko Kanaana, ka poe i noho makai, i hoomaloo o Iehova i na wai o Ioredane, mamua o na mamo a Iseraela, a pau kakou i ka hele ae, maule iho la ko lakou naau, aole hoi i koe ke aho iloko o lakou imua o na mamo a Iseraela.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kejì.”
Ia manawa, olelo mai la o Iehova ia Iosua, E hana oe i mau pahi oi nau, a e okipoepoe hou i na mamo a Iseraela, o ka lua ia.
3 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà, ní Gibiati-Haralotu.
Hana iho la o Iosua i mau pahi oi, a okipoepoe mai la i na mamo a Iseraela, ma ka puu omaka.
4 Wàyí o, ìdí tí Joṣua fi kọ wọ́n nílà nìyìí. Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Ejibiti jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní aginjù ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
No keia mea hoi i okipoepoe ai o Iosua ia lakou; o na kanaka a pau i hele mai, mai Aigupita mai, o ka poe kane i makaukau i ke kaua, pau lakou i ka make ma ka waonahele, ma ke ala a lakou i hele ai mawaho mai o Aigupita.
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Ejibiti ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú aginjù lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Ejibiti ni wọn kò kọ ní ilà.
Ua okipoepoeia no na kanaka a pau i hele mai mawaho; aka, o ka poe i hanau ma ka waonahele, i ka puka ana mai mawaho o Aigupita, aole lakou i okipoepoeia.
6 Àwọn ará Israẹli rìn ní aginjù fún ogójì ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Ejibiti fi kú, nítorí wọn kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fi fun wa, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin.
Hookahi kanaha makahiki i auwana ai na mamo a Iseraela ma ka waonahele, a pau i ka make ka lahuikaua, ka poe i hele mai mai Aigupita mai, i hoolohe ole i ka leo o Iehova. Hoohiki no o Iehova ia lakou, aole e hoike mai ia lakou i ka aina ana i hoohiki ai i ko lakou mau makua, e haawi mai no lakou, he aina e kahe ana o ka waiu a me ka meli.
7 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Joṣua kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tí ì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.
A o ka lakou poe keiki, ana i hoopuka mai ai, oia ka Iosua i okipoepoe iho ai; no ka mea, ua okipoepoe ole ia lakou, aole lakou i okipoepoeia ma ke ala,
8 Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.
A i ka wa i hoopau ai lakou i ke okipoepoe ana i kanaka a pau, alaila, noho iho la lakou ma ko la kou wahi i hoomoana'i, a ola lakou.
9 Nígbà náà ní Olúwa wí fún Joṣua pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Ejibiti kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gilgali títí ó fi di òní yìí.
Olelo mai la o Iehova ia Iosua, I keia la ua olokaa wale aku au, mai o oukou aku, i ka hoino ana o Aigupita. Nolaila ua kapaia ka inoa o ia wahi, o Gilegala, a hiki mai i keia la.
10 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù náà, nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gilgali ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko, àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ọdún àjọ ìrékọjá.
Hoomoana no na mamo a Iseraela ma Gilegala, a malama iho la lakou i ka moliaola, i ka la umikumamaha o ka malama, i ke ahiahi, ma na wahi papu o Ieriko.
11 Ní ọjọ́ kejì àjọ ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan an ni, wọ́n jẹ nínú àwọn ìre oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.
I ka la mahope iho o ka moliaola, ai no lakou i ka ai o ka aina, a ia la no pulehu lakou i ka berena hu ole.
12 Manna náà sì tan ní ọjọ́ kejì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde, kò sì sí manna kankan mọ́ fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ ìre oko ilẹ̀ Kenaani.
Ia la iho, mahope o ka lakou ai ana i ka ai o ka aina, oki iho la ka mane, aole mane hou na na mamo a Iseraela. A ai no lakou i ka ai o ka aina ma Kanaana ia makahiki.
13 Nígbà tí Joṣua súnmọ́ Jeriko, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Joṣua sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀tá a wa?”
Eia hoi kekahi, i ko Iosua noho ana imua o Ieriko, alawa ae la kona maka iluna, nana aku la, aia hoi! ku mai la kekahi kanaka imua ona, me ka pahikaua i unuhiia ma kona lima. Hele aku la o Iosua io na la, i aku la, Ma o makou nei anei oe, ma ko makou enemi paha?
14 “Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Joṣua sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”
I mai la kela, Aole, ua hele mai nei au i alii koa no ko Iehova puali. Moe iho la ko Iosua alo ma ka honua, hoomana aku la, i aku la ia ia, Heaha ka kuu Haku e olelo mai nei i kau kauwa?
15 Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Olelo mai la ke alii koa o ko Iehova puali ia Iosua, E wehe ae oe i kou mau kamaa, mai kou kapnwai aku, no ka mea, he wahi hoano kau e ku nei. A hana no o Iosua pela.

< Joshua 5 >