< Joshua 5 >

1 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Amori ti ìlà-oòrùn Jordani àti gbogbo àwọn ọba Kenaani tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jordani gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Israẹli títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pami, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojúkọ àwọn ọmọ Israẹli.
Ug nahitabo, nga sa nakadungog ang mga hari sa mga Amorehanon, nga didto sa luyo sa Jordan paingon sa kasadpan, ug ang tanang mga hari sa mga Canaanhon nga didto duol sa dagat, nanagpakadungog kong giunsa ni Jehova pagmala ang mga tubig sa Jordan sa atubangan sa mga anak sa Israel, hangtud nga kami nakatabok na, ang ilang mga kasingkasing nangatunaw ug wala na usab kanila ang espiritu, tungod sa mga anak sa Israel.
2 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kejì.”
Niadtong panahona si Jehova miingon kang Josue: Magbuhat ka ug mahait nga mga cuchillo, ug circuncidahon pag-usab ang mga anak sa Israel, sa ikaduha,
3 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà, ní Gibiati-Haralotu.
Ug si Josue nagbuhat alang kaniya ug mga cuchillo nga santik ug gicircuncidahan niya ang mga anak sa Israel, didto sa Gibeatnaaraloth.
4 Wàyí o, ìdí tí Joṣua fi kọ wọ́n nílà nìyìí. Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Ejibiti jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní aginjù ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Mao kini ang hinungdan nga si Josue nagcircuncidar: ang tanang mga tawo nga nanggula gikan sa Egipto, ang mga lalake, ingon man ang mga manggugubat, nangamatay sa dalan sa kamingawan, tapus sila makagula gikan sa Egipto.
5 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Ejibiti ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú aginjù lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Ejibiti ni wọn kò kọ ní ilà.
Kay ang tanang mga tawo nga nanggula pulos gicircuncidahan: apan kadtong tanan nga didto matawo sa ilang pagpanlakaw sa kamingawan, gikan sa Egipto, wala nila circuncidahi.
6 Àwọn ará Israẹli rìn ní aginjù fún ogójì ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Ejibiti fi kú, nítorí wọn kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fi fun wa, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin.
Kay ang mga anak sa Israel mingpanaw sulod sa kap-atan ka tuig sa kamingawan hangtud ang tibook nga nasud bisan ang mga tawo nga manggugubat nga nanggula sa Egipto, nangahurot, kay sila wala magpatalinghug sa tingog ni Jehova kanila si Jehova nanumpa nga sila dili niya pakitaon sa yuta nga gipanumpa ni Jehova sa ilang mga amahan nga iyang ihatag kanato, usa ka yuta nga nagapaagay sa gatas ug dugos.
7 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Joṣua kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tí ì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.
Ug ang ilang mga anak nga iyang gisapnay ilis kanila, sila gicircuncidahan ni Josue: kay sila dili sinircuncidahan, kay sila wala man circuncidahi nila sa dalan.
8 Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.
Ug nahitabo, nga sa diha nga nahuman na circuncidahi ang tibook nasud, nga sila namuyo sa ilang mga puloy-anan sa campo hangtud nga sila nangaayo na.
9 Nígbà náà ní Olúwa wí fún Joṣua pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Ejibiti kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gilgali títí ó fi di òní yìí.
Ug si Jehova namulong kang Josue: Niining adlawa gisalikway ko na ang mga pagtamay sa Egipto kaninyo sa Tungod niini ang ngalan sa dapit ginatawag nga Gilgal; hangtud niining adlawa.
10 Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù náà, nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gilgali ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko, àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ọdún àjọ ìrékọjá.
Ug ang mga anak sa Israel nanagpuyo sa Gilgal, ug sa hapon sa ikapulo ug upat ka adlaw sa maong bulan, nagsaulog sila sa pasko didto sa kapatagan sa Jerico.
11 Ní ọjọ́ kejì àjọ ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan an ni, wọ́n jẹ nínú àwọn ìre oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.
Ug sa pagkaugma human ang pasko, nangaon sila sa abut sa yuta, mga tinapay nga walay levadura ug mga sinanglag nga mga trigo, sa maong adlawa gayud.
12 Manna náà sì tan ní ọjọ́ kejì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde, kò sì sí manna kankan mọ́ fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ ìre oko ilẹ̀ Kenaani.
Ug sa sunod nga adlaw sa nakasugod na sila pagkaon sa abut sa yuta, ang mana mihunong: ug ang mga anak sa Israel wala na ing mana: ug niadtong tuiga nangaon sila sa abut sa yuta sa Canaan.
13 Nígbà tí Joṣua súnmọ́ Jeriko, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Joṣua sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀tá a wa?”
Ug nahitabo, nga sa didto si Josue duol sa Jerico, nga siya miyahat sa iyang mga mata ug mitan-aw, ug ania karon, sa iyang atubangan may usa ka tawo nga nagtindog ug nagbitbit sa iyang kamot ug usa ka espada nga hinuso sa sakob; ug si Josue miduol kaniya, ug miingon kaniya: Kadapig ba ikaw namo kun sa among mga kaaway?
14 “Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Joṣua sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”
Ug siya miingon: Dili; apan ingon nga principe sa panon sa kasundalohan ni Jehova, mianhi ako karon. Ug si Josue mihapa sa yuta ug misimba, ug miingon kaniya: Unsa ba ang isulti sa akong agalon alang sa iyang sulogoon?
15 Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Ug ang principe sa panon sa kasundalohan ni Jehova miingon kang Josue: Kuhaa ang sapin sa imong tiil, kay ang dapit nga imong gitindogan, yuta nga balaan man. Ug si Josue nagtuman.

< Joshua 5 >