< Joshua 4 >

1 Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jordani tan, Olúwa sọ fún Joṣua pé,
Și s-a întâmplat, după ce toți oamenii au terminat de trecut Iordanul, că DOMNUL i-a vorbit lui Iosua, spunând:
2 “Yan ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Luați-vă din popor doisprezece bărbați, un bărbat din fiecare trib,
3 kí o sì pàṣẹ fún wọn pé, ‘Ẹ gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.’”
Și porunciți-le, spunând: Să luați de aici, din mijlocul Iordanului, din locul unde picioarele preoților au stat neclintite, douăsprezece pietre și să le purtați cu voi și să le puneți în locul de găzduire, unde veți găzdui în noaptea aceasta.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pe àwọn ọkùnrin méjìlá tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Atunci Iosua a chemat pe cei doisprezece bărbați, pe care îi pregătise dintre copiii lui Israel, un bărbat din fiecare trib.
5 ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárín odò Jordani. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli,
Și Iosua le-a spus: Treceți înaintea chivotului DOMNULUI Dumnezeul vostru, în mijlocul Iordanului, și ridicați fiecare dintre voi câte o piatră pe umăr, conform numărului triburilor copiilor lui Israel,
6 kí ó sì jẹ́ àmì láàrín yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
Ca aceasta să fie un semn între voi, când va veni timpul și copiii voștri vor întreba pe părinții lor, spunând: Ce înseamnă aceste pietre pentru voi?
7 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jordani kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jordani, a gé omi Jordani kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli láéláé.”
Atunci să le răspundeți: Apele Iordanului au fost despărțite înaintea chivotului legământului DOMNULUI; când a trecut peste Iordan, apele Iordanului au fost despărțite și pietrele acestea vor fi ca amintire copiilor lui Israel, pentru totdeauna.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí Joṣua ti pàṣẹ fún wọn. Wọ́n gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli, bí Olúwa ti sọ fún Joṣua; wọ́n sì rù wọ́n kọjá lọ sí ibùdó, ní ibi tí wọ́n ti gbé wọn kalẹ̀.
Și copiii lui Israel au făcut astfel precum le-a poruncit Iosua și au luat douăsprezece pietre din mijlocul Iordanului, precum i-a vorbit DOMNUL lui Iosua, conform numărului triburilor copiilor lui Israel; și le-au purtat cu ei la locul unde au găzduit și le-au așezat acolo.
9 Joṣua sì to òkúta méjìlá náà sí àárín odò Jordani fún ìrántí ní ọ̀kánkán ibi tí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí dúró sí. Wọ́n sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
Și Iosua a ridicat douăsprezece pietre în mijlocul Iordanului, în locul unde stăteau picioarele preoților care au purtat chivotul legământului; și sunt acolo până în această zi.
10 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí náà dúró ní àárín Jordani títí gbogbo nǹkan tí Olúwa pàṣẹ fún Joṣua fi di ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún Joṣua. Àwọn ènìyàn náà sì yára kọjá,
Fiindcă preoții care au purtat chivotul au stat în mijlocul Iordanului până s-a terminat tot ce i-a poruncit DOMNUL lui Iosua să spună poporului, conform cu tot ce i-a poruncit Moise lui Iosua; și poporul s-a grăbit și a trecut.
11 bí gbogbo wọn sì ti rékọjá tán, ni àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àwọn àlùfáà wá sí òdìkejì. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń wò wọ́n.
Și s-a întâmplat că, după ce tot poporul a terminat de trecut, chivotul DOMNULUI și preoții au trecut în prezența poporului.
12 Àwọn ọkùnrin Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase náà sì rékọjá ní ìhámọ́ra ogun níwájú àwọn ọmọ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún wọn.
Și copiii lui Ruben și copiii lui Gad și jumătatea tribului lui Manase au trecut înarmați înaintea copiilor lui Israel, precum le-a vorbit Moise.
13 Àwọn bí ọ̀kẹ́ méjì tó ti múra fún ogun rékọjá lọ ní iwájú Olúwa sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko láti jagun.
Aproape patruzeci de mii pregătiți pentru război au trecut înaintea DOMNULUI la luptă, spre câmpiile Ierihonului.
14 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa gbé Joṣua ga ní ojú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì bẹ̀rù u rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé e wọn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti bẹ̀rù Mose.
În ziua aceea DOMNUL a mărit pe Iosua în ochii întregului Israel; și s-au temut de el, cum s-au temut de Moise în toate zilele vieții sale.
15 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Iosua, spunând:
16 “Pàṣẹ fún àwọn àlùfáà tí o ń ru àpótí ẹ̀rí, kí wọn kí ó jáde kúrò nínú odò Jordani.”
Poruncește preoților care poartă chivotul mărturiei să iasă afară din Iordan.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ jáde kúrò nínú odò Jordani.”
De aceea Iosua a poruncit preoților, spunând: Ieșiți afară din Iordan.
18 Àwọn àlùfáà náà jáde láti inú odò pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa ni orí wọn. Bí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ ẹ wọn tẹ orí ilẹ̀ gbígbẹ ni omi Jordani náà padà sí ààyè e rẹ̀, o sì kún wọ bèbè bí i ti àtẹ̀yìnwá.
Și s-a întâmplat, când preoții care au purtat chivotul legământului DOMNULUI au ieșit afară din mijlocul Iordanului și tălpile picioarelor preoților au ajuns afară pe uscat, că apele Iordanului s-au întors la locul lor și s-au revărsat peste toate malurile sale, ca înainte.
19 Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìn-ín-ní àwọn ènìyàn náà lọ láti Jordani, wọ́n sì dúró ní Gilgali ní ìlà-oòrùn Jeriko.
Și poporul a ieșit afară din Iordan în a zecea zi a lunii întâi; și au așezat tabăra în Ghilgal, la granița de est a Ierihonului.
20 Joṣua sì to àwọn òkúta méjìlá tí wọ́n mú jáde ní Jordani jọ ní Gilgali.
Și acele douăsprezece pietre, pe care Iosua le-a ridicat la Ghilgal, le-au luat din Iordan.
21 Ó sì sọ fún àwọn ará Israẹli, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kín ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
Și le-a vorbit copiilor lui Israel, spunând: Când copiii voștri vor întreba pe părinții lor în timpul care va veni, zicând: Ce înseamnă pietrele acestea?
22 Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Israẹli rékọjá odò Jordani ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’
Atunci să faceți cunoscut copiilor voștri, spunând: Israel a trecut Iordanul acesta pe uscat.
23 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jordani gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jordani gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.
Fiindcă DOMNUL Dumnezeul vostru a secat apele Iordanului dinaintea voastră, până ați trecut, așa cum a făcut DOMNUL Dumnezeul vostru Mării Roșii, pe care a secat-o dinaintea noastră, până am trecut,
24 Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”
Pentru ca toate popoarele pământului să cunoască mâna DOMNULUI, că este tare; ca să vă temeți de DOMNUL Dumnezeul vostru pentru totdeauna.

< Joshua 4 >