< Joshua 4 >

1 Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jordani tan, Olúwa sọ fún Joṣua pé,
A gdy cały lud zakończył przeprawę przez Jordan, PAN powiedział do Jozuego:
2 “Yan ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Wybierzcie sobie z ludu dwunastu mężczyzn, po jednym z każdego pokolenia.
3 kí o sì pàṣẹ fún wọn pé, ‘Ẹ gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.’”
I rozkażcie im: Weźcie sobie stąd, ze środka Jordanu, z tego miejsca, gdzie nogi kapłanów stały pewnie, dwanaście kamieni, zabierzcie je ze sobą i połóżcie w miejscu, gdzie tej nocy będziecie nocować.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pe àwọn ọkùnrin méjìlá tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Jozue wezwał więc dwunastu mężczyzn, których wybrał spośród synów Izraela, po jednym z każdego pokolenia.
5 ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárín odò Jordani. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli,
I Jozue powiedział do nich: Pójdźcie przed arką PANA, swojego Boga, na środek Jordanu i niech każdy weźmie po jednym kamieniu na swe ramię, według liczby pokoleń synów Izraela;
6 kí ó sì jẹ́ àmì láàrín yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
Aby to było znakiem wśród was, gdy potem wasi synowie zapytają: Co [znaczą] dla was te kamienie?
7 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jordani kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jordani, a gé omi Jordani kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli láéláé.”
Wtedy powiecie im, że wody Jordanu rozdzieliły się przed arką przymierza PANA; gdy przechodziła przez Jordan, rozdzieliły się wody Jordanu; i te kamienie będą pamiątką dla synów Izraela na wieki.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí Joṣua ti pàṣẹ fún wọn. Wọ́n gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli, bí Olúwa ti sọ fún Joṣua; wọ́n sì rù wọ́n kọjá lọ sí ibùdó, ní ibi tí wọ́n ti gbé wọn kalẹ̀.
I synowie Izraela uczynili tak, jak rozkazał Jozue. Wzięli dwanaście kamieni ze środka Jordanu, jak powiedział PAN do Jozuego, według liczby pokoleń synów Izraela, zanieśli je ze sobą na miejsce noclegu i tam je złożyli.
9 Joṣua sì to òkúta méjìlá náà sí àárín odò Jordani fún ìrántí ní ọ̀kánkán ibi tí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí dúró sí. Wọ́n sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
Jozue też postawił dwanaście kamieni na środku Jordanu, w miejscu, gdzie stały nogi kapłanów niosących arkę przymierza. Pozostają tam aż do dziś.
10 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí náà dúró ní àárín Jordani títí gbogbo nǹkan tí Olúwa pàṣẹ fún Joṣua fi di ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún Joṣua. Àwọn ènìyàn náà sì yára kọjá,
Kapłani zaś niosący arkę stali na środku Jordanu, aż wypełniło się to wszystko, co PAN rozkazał Jozuemu powiedzieć ludowi zgodnie ze wszystkim, co Mojżesz nakazał Jozuemu. Lud natomiast spieszył się i przeszedł.
11 bí gbogbo wọn sì ti rékọjá tán, ni àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àwọn àlùfáà wá sí òdìkejì. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń wò wọ́n.
Gdy cały lud przeszedł, przeszli też i arka PANA, i kapłani przed ludem.
12 Àwọn ọkùnrin Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase náà sì rékọjá ní ìhámọ́ra ogun níwájú àwọn ọmọ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún wọn.
Synowie Rubena, synowie Gada i połowa pokolenia Manassesa również przeszli uzbrojeni przed synami Izraela, jak im Mojżesz nakazał.
13 Àwọn bí ọ̀kẹ́ méjì tó ti múra fún ogun rékọjá lọ ní iwájú Olúwa sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko láti jagun.
Około czterdziestu tysięcy uzbrojonych wojowników przeszło przed PANEM do walki na równinach Jerycha.
14 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa gbé Joṣua ga ní ojú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì bẹ̀rù u rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé e wọn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti bẹ̀rù Mose.
W tym dniu PAN wywyższył Jozuego na oczach całego Izraela i bali się go, jak bali się Mojżesza przez wszystkie dni jego życia.
15 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé,
Potem PAN powiedział do Jozuego:
16 “Pàṣẹ fún àwọn àlùfáà tí o ń ru àpótí ẹ̀rí, kí wọn kí ó jáde kúrò nínú odò Jordani.”
Rozkaż kapłanom niosącym arkę świadectwa, aby wyszli z Jordanu.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ jáde kúrò nínú odò Jordani.”
Rozkazał więc Jozue kapłanom: Wyjdźcie z Jordanu.
18 Àwọn àlùfáà náà jáde láti inú odò pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa ni orí wọn. Bí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ ẹ wọn tẹ orí ilẹ̀ gbígbẹ ni omi Jordani náà padà sí ààyè e rẹ̀, o sì kún wọ bèbè bí i ti àtẹ̀yìnwá.
A gdy kapłani niosący arkę przymierza PANA wyszli ze środka Jordanu i stopy ich stanęły na suchej ziemi, wody Jordanu wróciły na swoje miejsce i płynęły jak przedtem, wypełnione po brzegi.
19 Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìn-ín-ní àwọn ènìyàn náà lọ láti Jordani, wọ́n sì dúró ní Gilgali ní ìlà-oòrùn Jeriko.
Lud wyszedł z Jordanu dziesiątego [dnia] pierwszego miesiąca i rozbił obóz w Gilgal, po wschodniej stronie Jerycha.
20 Joṣua sì to àwọn òkúta méjìlá tí wọ́n mú jáde ní Jordani jọ ní Gilgali.
A te dwanaście kamieni, które wyniesiono z Jordanu, Jozue ustawił w Gilgal.
21 Ó sì sọ fún àwọn ará Israẹli, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kín ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
I powiedział do synów Izraela: Gdy w przyszłości wasi synowie zapytają swoich ojców: Co [znaczą] te kamienie?
22 Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Israẹli rékọjá odò Jordani ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’
Wtedy powiecie swoim synom: Izrael przeszedł przez Jordan po suchej ziemi;
23 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jordani gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jordani gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.
PAN Bóg bowiem osuszył wody Jordanu przed wami, aż się przeprawiliście – tak jak PAN, wasz Bóg, uczynił z Morzem Czerwonym, które wysuszył przed nami, aż przeszliśmy;
24 Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”
Aby wszystkie narody ziemi poznały, że ręka PANA jest potężna, i żebyście bali się PANA, swojego Boga, po wszystkie dni.

< Joshua 4 >