< Joshua 4 >

1 Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jordani tan, Olúwa sọ fún Joṣua pé,
A gdy się wszystek lud przeprawił za Jordan, (bo rzekł był Pan do Jozuego, mówiąc:
2 “Yan ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Obierzcie sobie z ludu dwanaście mężów, po jednym mężu z każdego pokolenia.
3 kí o sì pàṣẹ fún wọn pé, ‘Ẹ gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.’”
I rozkażcie im, mówiąc: Weźmijcie sobie stąd z pośrodku Jordanu, z tego miejsca, gdzie stały nogi kapłanów porządnie, dwanaście kamieni, które z sobą wyniósłszy postawicie na stanowisku, gdzie będziecie leżeć przez tę noc.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pe àwọn ọkùnrin méjìlá tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Tedy wezwał Jozue dwanaście mężów, które był wybrał z synów Izraelskich, po jednym mężu z każdego pokolenia.)
5 ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárín odò Jordani. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli,
I rzekł do nich Jozue: Idźcie przed skrzynią Pana, Boga waszego, w pośrodek Jordanu, a weźmij każdy kamień jeden na ramię swoje według liczby pokolenia synów Izraelskich,
6 kí ó sì jẹ́ àmì láàrín yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
Aby to było na znak między wami, gdyby potem pytali synowie wasi mówiąc: Co wam znaczy ten kamień?
7 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jordani kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jordani, a gé omi Jordani kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli láéláé.”
Tedy im powiecie, iż się rozstąpiły wody w Jordanie przed skrzynią przymierza Pańskiego; albowiem gdy szła przez Jordan, rozstąpiły się wody Jordańskie; i będzie ten kamień na pamiątkę synom Izraelskim aż na wieki.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí Joṣua ti pàṣẹ fún wọn. Wọ́n gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli, bí Olúwa ti sọ fún Joṣua; wọ́n sì rù wọ́n kọjá lọ sí ibùdó, ní ibi tí wọ́n ti gbé wọn kalẹ̀.
I uczynili tak synowie Izraelscy, jako rozkazał Jozue, i wzięli dwanaście kamieni z pośród Jordanu, jako mówił Pan do Jozuego, według liczby pokolenia synów Izraelskich, a zanieśli je z sobą aż do stanowiska, i tam je złożyli.
9 Joṣua sì to òkúta méjìlá náà sí àárín odò Jordani fún ìrántí ní ọ̀kánkán ibi tí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí dúró sí. Wọ́n sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
Jozue też wystawił dwanaście kamieni w pośród Jordanu, na miejscu, kędy stały nogi kapłanów, niosących skrzynię przymierza, które tam zostały aż po dziś dzień.
10 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí náà dúró ní àárín Jordani títí gbogbo nǹkan tí Olúwa pàṣẹ fún Joṣua fi di ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún Joṣua. Àwọn ènìyàn náà sì yára kọjá,
A tak kapłani niosący skrzynię stali w pośród Jordanu, aż się wypełniło to wszystko, co był rozkazał Pan Jozuemu mówić do ludu według wszystkiego, co był przykazał Mojżesz Jozuemu. Spieszył się tedy lud i przeszedł Jordan.
11 bí gbogbo wọn sì ti rékọjá tán, ni àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àwọn àlùfáà wá sí òdìkejì. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń wò wọ́n.
I stało się gdy wszystek lud przeszedł, że też przeszła i skrzynia Pańska i kapłani przed oblicznością ludu.
12 Àwọn ọkùnrin Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase náà sì rékọjá ní ìhámọ́ra ogun níwájú àwọn ọmọ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún wọn.
Przeszli też synowie Rubenowi, i synowie Gadowi, z połową pokolenia Manasesowego, zbrojno przed syny Izraelskimi, jako im był powiedział Mojżesz.
13 Àwọn bí ọ̀kẹ́ méjì tó ti múra fún ogun rékọjá lọ ní iwájú Olúwa sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko láti jagun.
Około czterdziestu tysięcy ludu zbrojnego przeszło przed Panem do boju na polu Jerycha.
14 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa gbé Joṣua ga ní ojú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì bẹ̀rù u rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé e wọn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti bẹ̀rù Mose.
Dnia onego wywyższył Pan Jozuego przed oczyma wszystkiego Izraela, i bali się go, jako się bali Mojżesza po wszystkie dni żywota jego.
15 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé,
Potem rzekł Pan do Jozuego, mówiąc:
16 “Pàṣẹ fún àwọn àlùfáà tí o ń ru àpótí ẹ̀rí, kí wọn kí ó jáde kúrò nínú odò Jordani.”
Rozkaż kapłanom, niosącym skrzynię świadectwa, aby wystąpili z Jordanu.
17 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ jáde kúrò nínú odò Jordani.”
I rozkazał Jozue kapłanom, mówiąc: Wystąpcie z Jordanu.
18 Àwọn àlùfáà náà jáde láti inú odò pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa ni orí wọn. Bí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ ẹ wọn tẹ orí ilẹ̀ gbígbẹ ni omi Jordani náà padà sí ààyè e rẹ̀, o sì kún wọ bèbè bí i ti àtẹ̀yìnwá.
I stało się, gdy wystąpili kapłani, niosący skrzynię przymierza Pańskiego, z pośrodku Jordanu, a stanęły stopy nóg kapłanów na suszy, wróciły się wody Jordańskie na miejsce swoje, a płynęły, jako przedtem, we wszystkich brzegach swoich.
19 Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìn-ín-ní àwọn ènìyàn náà lọ láti Jordani, wọ́n sì dúró ní Gilgali ní ìlà-oòrùn Jeriko.
A lud, wyszedłszy z Jordanu dziesiątego dnia miesiąca pierwszego, położyli się obozem w Galgal ku stronie wschodniej Jerycha.
20 Joṣua sì to àwọn òkúta méjìlá tí wọ́n mú jáde ní Jordani jọ ní Gilgali.
A dwanaście onych kamieni, które wynieśli z Jordanu, postawił Jozue w Galgal.
21 Ó sì sọ fún àwọn ará Israẹli, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kín ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
I rzekł do synów Izraelskich, mówiąc: Co znaczy ten kamień?
22 Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Israẹli rékọjá odò Jordani ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’
Tedy oznajmijcie synom waszym, mówiąc: Po suszy przeszedł Izrael ten Jordan;
23 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jordani gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jordani gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.
Albowiem osuszył Pan Bóg wody Jordańskie przed wami, ażeście przeszli, jako uczynił Pan, Bóg wasz, morzu czerwonemu, które wysuszył przed nami, ażeśmy przeszli;
24 Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”
Aby poznali wszyscy narodowie ziemi rękę Pańską, że można jest, żebyście się bali Pana, Boga waszego, po wszystkie dni.

< Joshua 4 >