< Joshua 4 >
1 Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jordani tan, Olúwa sọ fún Joṣua pé,
Lorsque toute la nation eut entièrement traversé le Jourdain, Yahvé parla à Josué et dit:
2 “Yan ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
« Prenez douze hommes parmi le peuple, un homme de chaque tribu,
3 kí o sì pàṣẹ fún wọn pé, ‘Ẹ gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.’”
et donnez-leur cet ordre: « Prenez au milieu du Jourdain, à l'endroit où les pieds des prêtres se sont arrêtés, douze pierres, emportez-les avec vous et posez-les à l'endroit où vous camperez cette nuit ».
4 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pe àwọn ọkùnrin méjìlá tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
Alors Josué appela les douze hommes qu'il avait préparés parmi les enfants d'Israël, un homme de chaque tribu.
5 ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárín odò Jordani. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli,
Josué leur dit: « Traversez devant l'arche de Yahvé votre Dieu jusqu'au milieu du Jourdain, et chacun de vous ramassera une pierre et la mettra sur son épaule, selon le nombre des tribus des enfants d'Israël.
6 kí ó sì jẹ́ àmì láàrín yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
Ce sera un signe parmi vous, et lorsque vos enfants demanderont plus tard: « Que signifient ces pierres? »
7 Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jordani kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jordani, a gé omi Jordani kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli láéláé.”
vous leur répondrez: « Parce que les eaux du Jourdain ont été coupées devant l'arche de l'alliance de Yahvé. Quand elle a traversé le Jourdain, les eaux du Jourdain ont été coupées. Ces pierres serviront de mémorial aux enfants d'Israël pour toujours ».
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí Joṣua ti pàṣẹ fún wọn. Wọ́n gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli, bí Olúwa ti sọ fún Joṣua; wọ́n sì rù wọ́n kọjá lọ sí ibùdó, ní ibi tí wọ́n ti gbé wọn kalẹ̀.
Les enfants d'Israël firent ce que Josué avait ordonné et ils enlevèrent douze pierres du milieu du Jourdain, comme Yahvé l'avait dit à Josué, selon le nombre des tribus des enfants d'Israël. Ils les transportèrent avec eux jusqu'au lieu où ils campaient, et les y déposèrent.
9 Joṣua sì to òkúta méjìlá náà sí àárín odò Jordani fún ìrántí ní ọ̀kánkán ibi tí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí dúró sí. Wọ́n sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
Josué dressa douze pierres au milieu du Jourdain, à l'endroit où se tenaient les pieds des prêtres qui portaient l'arche de l'alliance; elles y sont encore aujourd'hui.
10 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí náà dúró ní àárín Jordani títí gbogbo nǹkan tí Olúwa pàṣẹ fún Joṣua fi di ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún Joṣua. Àwọn ènìyàn náà sì yára kọjá,
Car les prêtres qui portaient l'arche se tinrent au milieu du Jourdain jusqu'à ce que soit achevé tout ce que Yahvé avait ordonné à Josué de dire au peuple, selon tout ce que Moïse avait ordonné à Josué; et le peuple se hâta de passer.
11 bí gbogbo wọn sì ti rékọjá tán, ni àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àwọn àlùfáà wá sí òdìkejì. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń wò wọ́n.
Lorsque tout le peuple eut complètement traversé, l'arche de Yahvé traversa avec les prêtres en présence du peuple.
12 Àwọn ọkùnrin Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase náà sì rékọjá ní ìhámọ́ra ogun níwájú àwọn ọmọ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún wọn.
Les fils de Ruben, les fils de Gad et la demi-tribu de Manassé passèrent armés devant les enfants d'Israël, comme Moïse le leur avait dit.
13 Àwọn bí ọ̀kẹ́ méjì tó ti múra fún ogun rékọjá lọ ní iwájú Olúwa sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko láti jagun.
Environ quarante mille hommes, prêts et armés pour la guerre, passèrent devant l'Éternel pour combattre, dans les plaines de Jéricho.
14 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa gbé Joṣua ga ní ojú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì bẹ̀rù u rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé e wọn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti bẹ̀rù Mose.
Ce jour-là, l'Éternel magnifia Josué aux yeux de tout Israël, et ils le craignirent, comme ils avaient craint Moïse, tous les jours de sa vie.
15 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé,
Yahvé parla à Josué et dit:
16 “Pàṣẹ fún àwọn àlùfáà tí o ń ru àpótí ẹ̀rí, kí wọn kí ó jáde kúrò nínú odò Jordani.”
« Ordonne aux prêtres qui portent l'arche de l'alliance de sortir du Jourdain. »
17 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ jáde kúrò nínú odò Jordani.”
Josué donna cet ordre aux sacrificateurs: « Montez du Jourdain! »
18 Àwọn àlùfáà náà jáde láti inú odò pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa ni orí wọn. Bí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ ẹ wọn tẹ orí ilẹ̀ gbígbẹ ni omi Jordani náà padà sí ààyè e rẹ̀, o sì kún wọ bèbè bí i ti àtẹ̀yìnwá.
Lorsque les prêtres qui portaient l'arche de l'alliance de Yahvé furent sortis du milieu du Jourdain, et que la plante des pieds des prêtres fut levée sur la terre sèche, les eaux du Jourdain retournèrent à leur place et passèrent par-dessus toutes ses rives, comme auparavant.
19 Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìn-ín-ní àwọn ènìyàn náà lọ láti Jordani, wọ́n sì dúró ní Gilgali ní ìlà-oòrùn Jeriko.
Le peuple sortit du Jourdain le dixième jour du premier mois, et il campa à Guilgal, à la frontière orientale de Jéricho.
20 Joṣua sì to àwọn òkúta méjìlá tí wọ́n mú jáde ní Jordani jọ ní Gilgali.
Josué dressa à Gilgal les douze pierres qu'ils avaient prises dans le Jourdain.
21 Ó sì sọ fún àwọn ará Israẹli, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kín ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
Il parla aux enfants d'Israël et dit: « Lorsque vos enfants demanderont un jour à leurs pères: « Que signifient ces pierres? »
22 Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Israẹli rékọjá odò Jordani ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’
Vous le ferez savoir à vos enfants en disant: « Israël a passé ce Jourdain à sec.
23 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jordani gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jordani gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.
Car Yahvé ton Dieu a mis à sec les eaux du Jourdain devant toi jusqu'à ce que tu aies traversé, comme Yahvé ton Dieu l'a fait pour la mer Rouge, qu'il a mise à sec devant nous jusqu'à ce que nous l'ayons traversée,
24 Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”
afin que tous les peuples de la terre sachent que la main de Yahvé est puissante, et que vous craigniez Yahvé votre Dieu pour toujours. »