< Joshua 3 >

1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.
Yǝxua ǝtisi tang sǝⱨǝrdǝ turup, pütkül Israil bilǝn Xittimdin ayrilip Iordan dǝryasiƣa kǝldi; ular dǝryadin ɵtküqǝ xu yǝrdǝ bargaⱨ tikip turdi.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já.
Üq kün toxup, sǝrdarlar qedirgaⱨtin ɵtüp,
3 Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.
hǝlⱪⱪǝ ǝmr ⱪilip: — Silǝr Pǝrwǝrdigar Hudayinglarning ǝⱨdǝ sanduⱪini, yǝni Lawiylarning uni kɵtürüp mangƣinini kɵrgǝn ⱨaman, turƣan ornunglardin ⱪozƣilip, ǝⱨdǝ sanduⱪining kǝynidin ǝgixip menginglar.
4 Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́.”
Lekin uning bilǝn silǝrning ariliⱪinglarda ikki ming gǝz ariliⱪ ⱪalsun; ⱪaysi yol bilǝn mangidiƣininglarni bilixinglar üqün, uningƣa yeⱪinlaxmanglar; qünki silǝr ilgiri muxu yol bilǝn mengip baⱪmiƣansilǝr, — dedi.
5 Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”
Yǝxua hǝlⱪⱪǝ: — Ɵzünglarni pak-muⱪǝddǝs ⱪilinglar, qünki ǝtǝ Pǝrwǝrdigar aranglarda mɵjizǝ-karamǝtlǝrni kɵrsitidu, — dedi.
6 Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.
Andin Yǝxua kaⱨinlarƣa: — Əⱨdǝ sanduⱪini kɵtürüp hǝlⱪning aldida dǝryadin ɵtünglar, dǝp buyruwidi, ular ǝⱨdǝ sanduⱪini elip hǝlⱪning aldida mangdi.
7 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose.
Pǝrwǝrdigar Yǝxuaƣa sɵz ⱪilip: — Ⱨǝmmǝ Israilning Mening Musa bilǝn billǝ bolƣinimdǝk, sening bilǝnmu billǝ bolidiƣanliⱪimni bilixi üqün bügündin etibarǝn seni ularning nǝziridǝ qong ⱪilimǝn.
8 Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà, ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’”
Əmdi sǝn ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürgǝn kaⱨinlarƣa: — Silǝr Iordan dǝryasining süyining boyiƣa yetip kǝlgǝndǝ, Iordan dǝryasi iqidǝ turunglar, — degin, — dedi.
9 Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
Yǝxua Israillarƣa: — Bu yaⱪⱪa kelinglar, Pǝrwǝrdigar Hudayinglarning sɵzini anglanglar, dedi.
10 Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín.
Andin Yǝxua: — Mana, silǝr xu ix arⱪiliⱪ mǝnggülük ⱨayat Tǝngrining aranglarda ikǝnlikini, xundaⱪla Uning silǝrning aldinglardin Ⱨittiylar, Girgaxiylar, Amoriylar, Ⱪanaaniylar, Pǝrizziylar, Ⱨiwiylar, Yǝbusiylarni ⱨǝydiwetidiƣanliⱪini bilisilǝr — pütkül yǝr-zeminning igisining ǝⱨdǝ sanduⱪi silǝrning aldinglarda Iordan dǝryasi iqidin ɵtküzülidu.
11 Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín.
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
ǝmdi Israilning ⱪǝbililiridin on ikki adǝmni tallanglar, ⱨǝrⱪaysi ⱪǝbilidin birdin bolsun;
13 Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”
xundaⱪ boliduki, pütkül yǝr-zeminning Igisi bolƣan Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürgǝn kaⱨinlarning tapini Iordan dǝryasining süyigǝ tǝgkǝndǝ, Iordan dǝryasining süyi, yǝni bax eⱪinidin eⱪip kǝlgǝn sular üzüp taxlinip, dǝrya kɵtürülüp dɵng bolidu, — dedi.
14 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.
Əmdi xundaⱪ boldiki, hǝlⱪ qedirliridin qiⱪip Iordan dǝryasidin ɵtmǝkqi bolƣanda, ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürgǝn kaⱨinlar hǝlⱪning aldida mangdi;
15 Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi,
ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürgüqilǝr Iordan dǝryasiƣa yetip kelip, putliri suƣa tegixi bilǝnla (orma waⱪtida Iordan dǝryasining süyi dǝryaning ikki ⱪirƣiⱪidin texip qiⱪidu),
16 omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko.
yuⱪiri eⱪindiki sular heli yiraⱪtila, Zarǝtanning yenidiki Adǝm xǝⱨirining yenida tohtap, dɵng boldi; Arabaⱨ tüzlǝngliki boyidiki dengizƣa, yǝni «Xor Dengizi»ƣa eⱪip qüxüwatⱪan keyinki eⱪimi üzülüp ⱪaldi; hǝlⱪ bolsa Yeriho xǝⱨirining udulidin [dǝryadin] ɵtüp mangdi.
17 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
Pütkül Israil ⱪuruⱪ yǝrni dǝssǝp, barliⱪ hǝlⱪ Iordan dǝryasidin pütünlǝy ɵtüp bolƣuqilik, Pǝrwǝrdigarning ǝⱨdǝ sanduⱪini kɵtürgǝn kaⱨinlar Iordan dǝryasining otturisida ⱪuruⱪ yǝrdǝ mǝzmut turdi.

< Joshua 3 >