< Joshua 3 >

1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.
Rũciinĩ tene Joshua na andũ othe a Isiraeli makiuma hau Shitimu, magĩthiĩ nginya Jorodani, na matanaringa mũrĩmo ũcio ũngĩ magĩikara hau.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já.
Thuutha wa mĩthenya ĩtatũ-rĩ, anene magĩthiĩ kũndũ guothe gĩikaro-inĩ kĩu,
3 Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.
magĩatha andũ, makĩmeera atĩrĩ: “Rĩrĩa mũrĩona ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova Ngai wanyu, na muone athĩnjĩri-Ngai, o acio Alawii, marĩkuuĩte-rĩ, mumagare muume harĩa mũrĩ na mũrĩrũmĩrĩre.
4 Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́.”
Hĩndĩ ĩyo nĩguo mũrĩmenya njĩra ĩrĩa mũrĩĩgera, nĩgũkorwo mũtirĩ mwagera njĩra ĩyo rĩngĩ. No rĩrĩ, gatagatĩ-inĩ kanyu na ithandũkũ rĩu, nĩhagĩe itĩĩna ta rĩa mĩkono ngiri igĩrĩ; mũtikarĩkuhĩrĩrie.”
5 Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”
Nake Joshua akĩĩra andũ acio atĩrĩ, “Mwĩtheriei, nĩgũkorwo rũciũ Jehova nĩageeka maũndũ ma magegania gatagatĩ-inĩ kanyu.”
6 Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.
Nake Joshua akĩĩra athĩnjĩri-Ngai atĩrĩ, “Oyai ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro mũthiĩ mbere ya andũ aya.” Nĩ ũndũ ũcio makĩrĩoya, magĩthiĩ mbere yao.
7 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose.
Nake Jehova akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ũmũthĩ nĩngwambĩrĩria gũgũtũũgĩria maitho-inĩ ma andũ othe a Isiraeli, nĩguo mamenye atĩ ndĩrĩkoragwo hamwe nawe o ta ũrĩa ndaarĩ hamwe na Musa.
8 Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà, ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’”
Ĩra athĩnjĩri-Ngai arĩa megũkuua ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro atĩrĩ: ‘Mwakinya hũgũrũrũ-inĩ cia Rũũĩ rwa Jorodani, mũthiĩ mũrũgame Jorodani thĩinĩ.’”
9 Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
Nake Joshua akĩĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ, “Ũkai haha mũigue ciugo cia Jehova Ngai wanyu.
10 Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín.
Ũhoro ũyũ nĩguo ũrĩmũmenyithia atĩ Ngai ũrĩa ũrĩ muoyo arĩ hamwe na inyuĩ, na atĩ hatirĩ nganja nĩakamũingatĩra Akaanani, na Ahiti, na Ahivi, na Aperizi, na Agirigashi, na Aamori, na Ajebusi.
11 Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín.
Atĩrĩrĩ, ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro rĩa Mwathani wa thĩ yothe nĩrĩkũringa Rũũĩ rwa Jorodani mbere yanyu.
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Na rĩrĩ, thuurai andũ ikũmi na eerĩ kuuma mĩhĩrĩga-inĩ ya Isiraeli, o mũhĩrĩga mũndũ ũmwe.
13 Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”
Na rĩrĩa athĩnjĩri-Ngai arĩa makuuĩte ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova, o we Mwathani wa thĩ yothe, marĩtoboka thĩinĩ wa Rũũĩ rwa Jorodani-rĩ, maaĩ maruo marĩa maratherera maikũrũkĩte nĩmarĩtinĩka na meyũmbe hĩba.”
14 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.
Nĩ ũndũ ũcio rĩrĩa andũ moimagarire makiuma kambĩ nĩguo maringe Rũũĩ rwa Jorodani, athĩnjĩri-Ngai arĩa maakuuĩte ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro magĩthiĩ mbere yao.
15 Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi,
Na rĩrĩ, nĩgũkorwo Rũũĩ rwa Jorodani nĩrũiyũraga mũno rũgakĩra hũgũrũrũ ciaguo hĩndĩ ya magetha. No rĩrĩa athĩnjĩri-Ngai arĩa maakuuĩte ithandũkũ rĩu maakinyire Rũũĩ rwa Jorodani, namo magũrũ mao magĩtoboka hũgũrũrũ-inĩ cia rũũĩ,
16 omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko.
maaĩ marĩa moimaga mwena wa na igũrũ wa rũũĩ magĩtiga gũtherera maikũrũkĩte; makĩĩyũmba hĩba kũndũ kũraya mũno nginya itũũra-inĩ rĩetagwo Adamu rĩrĩa rĩ gũkuhĩ na Zarethani, namo maaĩ marĩa maathereraga marorete Iria-inĩ rĩa Araba (nĩrĩo Iria rĩa Cumbĩ) magĩtinĩka biũ. Nĩ ũndũ ũcio andũ makĩringa mangʼetheire Jeriko.
17 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
Athĩnjĩri-Ngai arĩa maakuuĩte ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova makĩrũgama mehaandĩte wega kũndũ kũmũ gatagatĩ ka Rũũĩ rwa Jorodani, nao andũ a Isiraeli othe makĩhĩtũka makĩringagĩra thĩ nyũmũ o nginya rĩrĩa rũrĩrĩ rũu ruothe rwarĩkirie kũringa rũũĩ rũu rwa Jorodani.

< Joshua 3 >