< Joshua 3 >
1 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀, Joṣua àti gbogbo àwọn Israẹli sí kúrò ní Ṣittimu, wọ́n sì lọ sí etí odò Jordani, wọ́n sì pa ibùdó síbẹ̀ kí wọn tó kọjá.
Joshua got up early in the morning, and they set out from Shittim. They came to the Jordan, he and all the people of Israel, and they camped there before they crossed over.
2 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta àwọn olórí la àárín ibùdó já.
After three days, the officers went through the middle of the camp;
3 Wọ́n sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Nígbà tí ẹ bá rí àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín, tí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi rù ú, nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sí kúrò ní ipò yín, ẹ̀yin yóò sì máa tẹ̀lé e.
they commanded the people, “When you see the ark of the covenant of Yahweh your God, and the priests from the Levites carrying it, you must leave this place and follow it.
4 Ẹyin yóò lè mọ ọ̀nà tí ẹ ó gbà, torí pé ẹ̀yin kò gba ọ̀nà yìí tẹ́lẹ̀ rí. Ṣùgbọ́n àlàfo gbọdọ̀ wà ní àárín yín àti àpótí náà, tó bí ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́.”
There must be a distance between you and it of about two thousand cubits. Do not come close to it, so that you can see which way to go, since you have not gone this way before.”
5 Joṣua sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ya ara yín sí mímọ́, nítorí ní ọ̀la, Olúwa yóò ṣe ohun ìyanu ní àárín yín.”
Joshua said to the people, “Consecrate yourselves tomorrow, for Yahweh will do wonders among you.”
6 Joṣua sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ̀yin, ẹ gbé àpótí ẹ̀rí náà kí ẹ̀yin kí ó sì máa lọ ṣáájú àwọn ènìyàn.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé e sókè, wọ́n sì ń lọ ní iwájú u wọn.
Then Joshua said to the priests, “Take up the ark of the covenant, and pass in front of the people.” So they picked up the ark of the covenant and went in front of people.
7 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Òní yìí ni Èmi yóò bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ọ ga ní ojú u gbogbo àwọn ará Israẹli, kí wọn lè mọ̀ pé Èmi wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí mo ṣe wà pẹ̀lú Mose.
Yahweh said to Joshua, “This day I will make you a great man in the eyes of all Israel. They will know that as I was with Moses, I will be with you.
8 Sọ fún àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà, ‘Nígbà tí ẹ bá dé etí omi Jordani, ẹ lọ kí ẹ sì dúró nínú odò náà.’”
You will command the priests who carry the ark of the covenant, 'When you have come to the edge of the waters of the Jordan, you must stand still in the Jordan River.'”
9 Joṣua sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ súnmọ́ ibí kí ẹ̀yin kí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín.
Then Joshua said to the people of Israel, “Come here, and listen to the words of Yahweh your God.
10 Èyí ni ẹ̀yin yóò fi mọ̀ pé Ọlọ́run alààyè wà ní àárín yín àti pé dájúdájú yóò lé àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, Hifi, Peresi, Girgaṣi, Amori àti Jebusi jáde níwájú u yín.
By this you will know that the living God is among you and will drive out from before you the Canaanites, the Hittites, the Hivites, the Perizzites, the Girgashites, the Amorites, and the Jebusites.
11 Àpótí májẹ̀mú Olúwa gbogbo ayé ń gòkè lọ sí Jordani ṣáájú u yín.
Look! The ark of the covenant of the Lord of all the earth crosses over ahead of you into the Jordan.
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
Now choose twelve men from the tribes of Israel, one man from each.
13 Bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí Olúwa, Olúwa gbogbo ayé bá ti ẹsẹ̀ bọ odò Jordani, omi tí ń ti òkè sàn wá yóò gé kúrò yóò sì gbá jọ bí òkìtì kan.”
When the soles of the feet of the priests that carry the ark of Yahweh, the Lord of all the earth, touch the waters of the Jordan, the waters of the Jordan will be cut off, and even the waters that flow down from upstream will stop flowing and they will stand in one heap.”
14 Nígbà tí àwọn ènìyàn gbéra láti ibùdó láti kọjá nínú odò Jordani, àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí náà ń lọ níwájú wọn.
So when the people set out to cross over the Jordan, the priests that carried the ark of the covenant went ahead of the people.
15 Odò Jordani sì máa ń wà ní kíkún ní gbogbo ìgbà ìkórè. Ṣùgbọ́n bí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí ti dé odò Jordani tí ẹsẹ̀ wọn sì kan etí omi,
As soon as those who were carrying the ark had come to the Jordan, and the feet of those who carried the chest were dipped in the edge of the water (now the Jordan overflows all its banks throughout the time of the harvest),
16 omi tí ń ti òkè sàn wá dúró. Ó sì gbá jọ bí òkìtì ní òkèèrè, ní ìlú tí a ń pè ní Adamu, tí ó wà ní tòsí Saretani; nígbà tí omi tí ń sàn lọ sínú Òkun aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀) gé kúrò pátápátá. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kọjá sí òdìkejì ní ìdojúkọ Jeriko.
the waters that flowed down from upstream stood up in one heap. The water stopped flowing from a great distance. The waters stopped flowing from Adam, the city that is beside Zarethan, all the way down to the sea of the Negev, the Salt Sea. The people crossed over near Jericho.
17 Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa sì dúró ṣinṣin lórí ilẹ̀ gbígbẹ ní àárín Jordani, nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ń kọjá títí gbogbo orílẹ̀-èdè náà fi rékọjá nínú odò Jordani lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
The priests that carried the ark of the covenant of Yahweh stood on dry ground in the middle of the Jordan until all the people of Israel crossed over on dry ground.