< Joshua 24 >

1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
Yeşu İsrail oymaklarının tümünü Şekem'de topladıktan sonra, İsrail'in ileri gelenlerini, boy başlarını, hâkimlerini, görevlilerini yanına çağırdı. Hepsi gelip Tanrı'nın önünde durdular.
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
Yeşu bütün halka, “İsrail'in Tanrısı RAB şöyle diyor” diye söze başladı, “‘İbrahim'in ve Nahor'un babası Terah ve öbür atalarınız eski çağlarda Fırat Irmağı'nın ötesinde yaşar, başka ilahlara kulluk ederlerdi.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
Ama ben atanız İbrahim'i ırmağın öte yakasından alıp bütün Kenan topraklarında dolaştırdım; soyunu çoğalttım, ona İshak'ı verdim.
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
İshak'a da Yakup ve Esav'ı verdim. Esav'a mülk edinmesi için Seir dağlık bölgesini bağışladım. Yakup'la oğulları ise Mısır'a gittiler.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
Ardından Musa ile Harun'u Mısır'a gönderdim. Orada yaptıklarımla Mısırlılar'ı felakete uğrattım; sonra sizi Mısır'dan çıkardım.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
Evet, atalarınızı Mısır'dan çıkardım; gelip denize dayandılar. Mısırlılar savaş arabalarıyla, atlılarıyla atalarınızı Kamış Denizi'ne dek kovaladılar.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
Atalarınız bana yakarınca, onlarla Mısırlılar'ın arasına karanlık çöktürdüm. Mısırlılar'ı deniz sularıyla örttüm. Mısır'da yaptıklarımı gözlerinizle gördünüz. “‘Uzun zaman çölde yaşadınız.
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
Sonra sizi Şeria Irmağı'nın ötesinde yaşayan Amorlular'ın topraklarına götürdüm. Size karşı savaştıklarında onları elinize teslim ettim. Topraklarını yurt edindiniz. Onları önünüzden yok ettim.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Moav Kralı Sippor oğlu Balak, İsrail'e karşı savaşmaya hazırlandığında, haber gönderip Beor oğlu Balam'ı size lanet etmeye çağırdı.
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
Ama ben Balam'ı dinlemeyi reddettim. O da sizi tekrar tekrar kutsadı; böylece sizi onun elinden kurtardım.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Sonra Şeria Irmağı'nı geçip Eriha'ya geldiniz. Size karşı savaşan Erihalılar'ı, Amor, Periz, Kenan, Hitit, Girgaş, Hiv ve Yevus halklarını elinize teslim ettim.
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
Önden gönderdiğim eşekarısı Amorlu iki kralı önünüzden kovdu. Bu işi kılıcınız ya da yayınız yapmadı.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
Böylece, emek vermediğiniz toprakları, kurmadığınız kentleri size verdim. Buralarda yaşıyor, dikmediğiniz bağlardan, zeytinliklerden yiyorsunuz.’”
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
Yeşu, “Bunun için RAB'den korkun, içtenlik ve bağlılıkla O'na kulluk edin” diye devam etti, “Atalarınızın Fırat Irmağı'nın ötesinde ve Mısır'da kulluk ettikleri ilahları atın, RAB'be kulluk edin.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
İçinizden RAB'be kulluk etmek gelmiyorsa, atalarınızın Fırat Irmağı'nın ötesinde kulluk ettikleri ilahlara mı, yoksa topraklarında yaşadığınız Amorlular'ın ilahlarına mı kulluk edeceksiniz, bugün karar verin. Ben ve ev halkım RAB'be kulluk edeceğiz.”
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
Halk, “RAB'bi bırakıp başka ilahlara kulluk etmek bizden uzak olsun!” diye karşılık verdi,
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
“Çünkü bizi ve atalarımızı Mısır'da kölelikten kurtarıp oradan çıkaran, gözümüzün önünde o büyük mucizeleri yaratan, bütün yolculuğumuz ve uluslar arasından geçişimiz boyunca bizi koruyan Tanrımız RAB'dir.
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
RAB bu ülkede yaşayan bütün ulusları, yani Amorlular'ı önümüzden kovdu. Biz de O'na kulluk edeceğiz. Çünkü Tanrımız O'dur.”
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
Yeşu, “Ama sizler RAB'be kulluk edemeyeceksiniz” dedi, “Çünkü O kutsal bir Tanrı'dır, kıskanç bir Tanrı'dır. Günahlarınızı, suçlarınızı bağışlamayacak.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
RAB'bi bırakıp yabancı ilahlara kulluk ederseniz, RAB daha önce size iyilik etmişken, bu kez size karşı döner, sizi felakete uğratıp yok eder.”
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
Halk, “Hayır! RAB'be kulluk edeceğiz” diye karşılık verdi.
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
O zaman Yeşu halka, “Kulluk etmek üzere RAB'bi seçtiğinize siz kendiniz tanıksınız” dedi. “Evet, biz tanığız” dediler.
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
Yeşu, “Öyleyse şimdi aranızdaki yabancı ilahları atın. Yüreğinizi İsrail'in Tanrısı RAB'be verin” dedi.
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
Halk, “Tanrımız RAB'be kulluk edip O'nun sözünü dinleyeceğiz” diye karşılık verdi.
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
Yeşu o gün Şekem'de halk adına bir antlaşma yaptı. Onlar için kurallar ve ilkeler belirledi.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
Bunları Tanrı'nın Yasa Kitabı'na da geçirdi. Sonra büyük bir taş alıp oraya, RAB'bin Tapınağı'nın yanındaki yabanıl fıstık ağacının altına dikti.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
Ardından bütün halka, “İşte taş bize tanık olsun” dedi, “Çünkü RAB'bin bize söylediği bütün sözleri işitti. Tanrınız'ı inkâr ederseniz bu taş size karşı tanıklık edecek.”
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Bundan sonra Yeşu halkı mülk aldıkları topraklara gönderdi.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
RAB'bin kulu Nun oğlu Yeşu bir süre sonra yüz on yaşında öldü.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
Onu Efrayim'in dağlık bölgesindeki Gaaş Dağı'nın kuzeyine, kendi mülkünün sınırları içinde kalan Timnat-Serah'a gömdüler.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Yeşu yaşadıkça ve Yeşu'dan sonra yaşayan ve RAB'bin İsrail için yaptığı her şeyi bilen ileri gelenler durdukça İsrail halkı RAB'be kulluk etti.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
İsrailliler Mısır'dan çıkarken Yusuf'un kemiklerini de yanlarında getirmişlerdi. Bunları Yakup'un Şekem'deki tarlasına gömdüler. Yakup bu tarlayı Şekem'in babası Hamor'un torunlarından yüz parça gümüşe satın almıştı. Burası Yusuf soyundan gelenlerin mülkü oldu.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
Harun'un oğlu Elazar ölünce, onu Efrayim'in dağlık bölgesinde oğlu Pinehas'a verilen tepeye gömdüler.

< Joshua 24 >