< Joshua 24 >

1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
Tedy zebrał Jozue wszystkie pokolenia Izraelskie do Sychem, i zwołał starszych z Izraela, i przedniejszych z nich, i sędziów ich, i przełożonych ich, i stanęli przed obliczem Bożem.
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
I rzekł Jozue do wszystkiego ludu: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Za rzeką mieszkali ojcowie wasi od dawnych czasów, Tare, ojciec Abrahamów, i ojciec Nachorów, i służyli bogom obcym.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
I wziąłem ojca waszego Abrahama z miejsca, które jest za rzeką, i prowadziłem go przez wszystkę ziemię Chananejską, i rozmnożyłem nasienie jego, dawszy mu Izaaka.
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Dałem też Izaakowi Jakóba i Ezawa, a podałem Ezawowi górę Seir, aby ją posiadł; ale Jakób i synowie jego zaszli do Egiptu.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
I posłałem Mojżesza i Aarona, a trapiłem Egipt; a gdym to uczynił w pośród niego, potemem was wywiódł.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
I wywiodłem ojce wasze z Egiptu, a przyszliście aż do morza, i gonili Egipczanie ojce wasze z wozami i z jezdnymi aż do morza czerwonego.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
Tedy wołali do Pana, a on położył ciemności między wami i między Egipczany, i przywiódł na nie morze, a okryło je; i widziały oczy wasze, com uczynił w Egipcie, i mieszkaliście na puszczy przez długi czas.
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
Potemem przywiódł was do ziemi Amorejczyka, mieszkającego za Jordanem, i walczyli przeciwko wam; alem je podał w rękę waszę, i posiedliście ziemię ich, a wygładziłem je przed wami.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Powstał też Balak, syn Seforów, król Moabski, aby walczył przeciw Izraelowi; a posławszy przyzwał Balaama, syna Beorowego, aby was przeklinał.
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
I nie chciałem słuchać Balaama; przetoż błogosławiąc błogosławił wam, a tak wybawiłem was z rąk jego.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Przeprawiliście się potem przez Jordan, i przyszliście do Jerycha, i walczyli przeciwko wam mężowie z Jerycha, Amorejczyk, i Ferezejczyk, i Chananejczyk, i Hetejczyk, i Gargiezejczyk, i Hewejczyk, i Jebuzejczyk; alem je podał w ręce wasze.
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
I posłałem przed wami sierszenie, którzy je wypędzili przed obliczem waszem, dwu królów Amorejskich, nie mieczem twoim ani łukiem twoim.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
I dałem wam ziemię, w którejście nie robili, i miasta, którycheście nie budowali, w których mieszkacie, a winnic i oliwnic, którycheście nie sadzili, pożywacie.
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
Przetoż teraz bójcie się Pana, a służcie mu w doskonałości i w prawdzie, a znieście bogi, którym służyli ojcowie wasi za rzeką, i w Egipcie, a służcie Panu.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
A jeźli się wam zda źle służyć Panu, obierzcież sobie dziś, komu byście służyli, chociaż bogi, którym służyli ojcowie wasi, co byli za rzeką, chociaż bogi Amorejskie, w których wy ziemi mieszkacie; aleć ja i dom mój będziemy służyli Panu.
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
I odpowiedział lud mówiąc: Nie daj Boże, abyśmy mieli odstąpić Pana, a służyć bogom cudzym:
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
Albowiem Pan, Bóg nasz, on jest, który nas wywiódł, i ojce nasze z ziemi Egipskiej, z domu niewoli, a który uczynił przed oczyma naszemi te znaki wielkie, i strzegł nas we wszystkiej drodze, którąśmy szli, i między wszystkimi narody, przez któreśmy przeszli;
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
I wypędził Pan wszystkie narody, i Amorejczyka mieszkającego w ziemi przed twarzą naszą. A tak my będziemy służyli Panu; bo on jest Bóg nasz.
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
Tedy rzekł Jozue do ludu: Nie możecie wy służyć Panu; bo Bóg święty jest, Bóg zapalczywy jest, nie przepuści złościom waszym, ani grzechom waszym.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
Jeźliż opuścicie Pana, a będziecie służyli bogom cudzym, obróci się, i utrapi was, i zniszczy was, choć wam przedtem dobrze czynił.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
I odpowiedział lud Jozuemu: Nie tak; ale Panu służyć będziemy.
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
Tedy rzekł Jozue do ludu: Świadkami będziecie sami przeciwko, sobie, iżeście sobie obrali Pana, abyście mu służyli; a oni rzekli: Świadkami jesteśmy.
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
I rzekł: Terazże znieście bogi cudze, którzy są w pośrodku was, a nakłońcie serca wasze ku Panu, Bogu Izraelskiemu.
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
I odpowiedział lud Jozuemu: Panu, Bogu naszemu, służyć będziemy, i głosowi jego posłuszni być chcemy.
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
A tak uczynił Jozue przymierze z ludem dnia onego, i przełożył im rozkazanie i sąd w Sychem.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
I napisał Jozue słowa te w księgi Zakonu Bożego; wziął też kamień wielki, i postawił go tam pod dębem, który był u świątnicy Pańskiej.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
Tedy rzekł Jozue do wszystkiego ludu: Oto kamień ten będzie nam świadectwem; albowiem on słyszał wszystkie słowa Pańskie, które mówił z nami i będzie przeciwko wam na świadectwo, byście snać nie skłamali przeciwko Bogu waszemu.
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Zatem rozpuścił Jozue lud, każdego do dziedzictwa swego.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
I stało się potem, że umarł Jozue, syn Nunów, sługa Pański, we stu i w dziesięciu lat.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
I pogrzebali go na granicy dziedzictwa jego w Tamnat Sare, które jest na górze Efraim, ku północy góry Gaas.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
I służył Izrael Panu po wszystkie dni Jozuego, i po wszystkie dni starszych, którzy długo żyli po Jozuem, a którzy wiedzieli o wszystkich sprawach Pańskich, które czynił Izraelowi.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
Kości też Józefowe, które byli przenieśli synowie Izraelscy z Egiptu, pogrzebali w Sychem, na części pola, które był kupił Jakób od synów Hemora, ojca Sychemowego, za sto jagniąt; i były u synów Józefowych w dziedzictwie ich.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
Eleazar także, syn Aaronów, umarł; i pogrzebali go na pagórku Fineesa, syna jego, który mu był dany na górze Efraim.

< Joshua 24 >