< Joshua 24 >

1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
Összegyűjtötte Józsua mind az Izraél törzseit Sekhémbe és hívta Izraél véneit, fejeit, bíráit és tisztviselőit és oda álltak Isten színe elé.
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
És szólt Józsua az egész néphez: Így szól az Örökkévaló, Izraél Istene: túl a folyamon laktak atyáitok ősidőtől fogva, Térach, Ábrahám atyja és Náchór atyja és szolgáltak más isteneket.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
S vettem atyátokat, Ábrahámot a folyamon túlról és engedtem őt járni Kanaán egész országában, megsokasítottam magzatját és adtam neki Izsákot;
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
s adtam Izsáknak Jákóbot és Ézsaut, és adtam Ézsaunak Széir hegyét, hogy elfoglalja, Jákób pedig és fiai lementek Egyiptomba.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
És küldtem Mózest és Áront és sújtottam Egyiptomot a szerint, amint cselekedtem közepette; s azután kivezettelek titeket.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
Kivezettem atyáitokat Egyiptomból és eljutottatok a tengerig, akkor üldözték az egyiptomiak atyáitokat szekérhaddal és lovasokkal a nádas tengerig.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
Kiáltottak az Örökkévalóhoz és vetett homályt közétek és az egyiptomiak közé, hozta reájuk a tengert, úgy hogy elborította és így látták szemeitek, amit cselekedtem Egyiptommal; erre laktatok a pusztában sok ideig.
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
És elhoztalak titeket az emóri országába, aki a Jordánon túl lakott és harcoltak veletek, de kezetekbe adtam őket, elfoglaltátok országukat, s elpusztítottam őket előletek.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Ekkor fölkelt Bálák, Cippór fia, Móáb királya és harcolt Izraél ellen; küldött és hívta Bileámot, Beór fiát, hogy megátkozzon titeket.
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
De nem akartam hallgatni Bileámra; úgy hogy áldva áldott meg titeket s így megmentettelek titeket kezéből.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Átkeltetek a Jordánon és eljutottatok Jeríchóig és harcoltak ellenetek Jeríchó emberei, az emóri, a perizzi, a kánaáni, a chitti, a girgási, a chivvi és a jebúszi; és kezetekbe adtam őket.
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
És küldtem előttetek a darázst és elűzte azokat előletek: az emóri két királyát, nem kardoddal s nem íjaddal.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
Adtam nektek országot, mellyel nem vesződtél és városokat, melyeket nem építettetek és laktok bennök; szőlőket és olajfákat, melyeket nem ültettetek, esztek ti.
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
Most tehát féljétek az Örökkévalót, szolgáljátok őt őszintén és igazán; távolítsátok el az isteneket, melyeket szolgáltak őseitek a folyamon túl és Egyiptomban és szolgáljátok az Örökkévalót.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
Ha pedig rossznak tetszik szemeitekben, szolgálni az Örökkévalót, válasszatok magatoknak ma, kit szolgáltok majd: vajon az isteneket-e, melyeket szolgáltak őseitek a folyamon túl, avagy az emóri isteneit-e, kinek országában laktok; én pedig és házam az Örökkévalót fogjuk szolgálni.
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
Felelt a nép és mondta: Távol legyen tőlünk elhagyni az Örökkévalót, hogy szolgáljunk más isteneket.
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
Mert az Örökkévaló a mi Istenünk – ő az, aki fölvezetett minket és atyáinkat Egyiptom országából, a rabszolgák házából és aki mívelte szemeink előtt e nagy jeleket és megőrzött bennünket az egész úton, melyen jártunk és mind a népek között, melyeknek közepén átvonultunk;
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
és elűzte az Örökkévaló mind a népeket, meg az emórit az ország lakóját előlünk – mi is szolgálni fogjuk az Örökkévalót, mert ő az istenünk.
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
Ekkor szólt Józsua a néphez: Nem szolgálhatjátok majd az Örökkévalót, mert szentséges Isten ő; buzgó Isten ő, nem bocsátja meg elpártolástokat és vétkeiteket.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
Ha elhagyjátok az Örökkévalót és szolgáltok idegen isteneket, akkor elfordul és rosszul bánik veletek és megsemmisít benneteket, minekutána jót tett veletek.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
Szólt a nép Józsuához: Nem, hanem az Örökkévalót fogjuk szolgálni.
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
Erre szólt Józsua a néphez: Tanúk vagytok tenmagatok ellen, hogy ti választottátok magatoknak az Örökkévalót, hogy őt szolgáljátok. – Mondták: Tanúk! –
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
Most tehát távolítsátok el az idegen isteneket, melyek köztetek vannak és hajtsátok szíveteket az Örökkévalóhoz, Izraél Istenéhez.
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
Mondta a nép Józsuának: Az Örökkévalót, a mi Istenünket fogjuk szolgálni és szavára fogunk hallgatni.
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
S kötött Józsua szövetséget a néppel ama napon; és adott neki törvényt és jogot Sekhémben.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
És megírta Józsua e szavakat Isten tanának könyvében; vett egy nagy követ és fölállította ott a tölgyfa alatt, mely az Örökkévaló szentélyénél volt.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
És szólt Józsua az egész néphez: Íme, ez a kő leszen tanú gyanánt ellenünk, mert ő hallotta mind az Örökkévaló szavait, melyeket beszélt velünk, és legyen ellenetek tanú gyanánt, nehogy megtagadjátok Istenteket.
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
És elbocsátotta Józsua a népet, kit-kit birtokába.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Történt e dolgok után, meghalt Józsua, Nún fia, az Örökkévaló szolgája, száztíz éves korában.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
És eltemették őt birtoka határában, Timnat-Szérachban, mely Efraim hegységében van, Gáas hegyétől északra.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
És szolgálta Izraél az Örökkévalót Józsua minden napjaiban és a vének minden napjaiban, akik sokáig éltek Józsua után és a kik tudták az Örökkévaló minden cselekedetét, amelyet mívelt Izraéllel.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
József csontjait pedig, melyeket felhoztak Izraél fiai Egyiptomból, eltemették Sekhémben, azon mező telkén, melyet megvett Jákób Chamór, Sekhém atyja fiaitól száz keszítáért; és jutottak József fiainak birtokul.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
Eleázár, Áron fia is meghalt, és eltemették Pinechász fiának a halmán, melyet adtak neki Efraim hegységében.

< Joshua 24 >