< Joshua 24 >

1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
A LAILA, hoiliili mai la o Iosua i na ohana a pau a Iseraela ma Sekema, a kahea aku la oia i na lunakahiko a Iseraela, a me ko lakou alii, a me ko lakou lunakanawai, a me ka poe luna o lakou; a noho iho la lakou imua o ke alo o ke Akua.
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
Olelo mai la o Iosua i na kanaka a pau, Ke i mai nei o Iehova, ke Akua o Iseraela penei, Ua noho no ko oukou kupuna ma kela kapa o ka muliwai, i ka wa kahiko, o Tera ka makuakane o Aberahama, o ka makuakane hoi o Nahora; a malama no lakou i na'kua e.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
A lawe au i ko oukou kupuna ia Aberahama, mai kela kapa ae o ka muliwai, a alakai au ia ia i na aina a pau o Kanaana nei, a hoonui i kona hua, a haawi no au ia Isaaka nana.
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
A haawi au na Isaaka ia Iakoba a me Esau: a haawi au na Esau i ka mauna o Seira, i wahi e noho ai nona; aka, o Iakoba a me kana mau keiki, hele lakou ilalo i Aigupita.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
Hoouna aku au ia Mose, a me Aarona, a hoomainoino au ia Aigupita, ma ka mea a'u i hana'i mawaena o lakou; a mahope iho, lawe mai au ia oukou mawaho.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
A lawe mai no au i ko oukou poe makua, mai Aigupita mai; a hele mai lakou e hiki i ke kai, a hahai mai ka poe Aigupita mahope o ko oukou poe makua, me na halekaa, a me ko lakou poe hololio, a hiki i ke Kaiula.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
A kahea lakou ia Iehova, alaila, kau oia i ka poeleele mawaena o oukou a me ko Aigupita, hoopopoi mai oia i ke kai, a uhi mai maluna o lakou. Pela no i ike ai ko oukou mau maka i na mea a pau a'u i hana'i i ko Aigupita: a ua noho oukou ma ka waonahele, i na la he nui loa.
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
A ua alakai mai nei au ia oukou i ka aina o ka Amora, ka poe i noho ma kela kapa o Ioredane, a kaua mai lakou ia oukou; aka, haawi no wau ia lakou iloko o ko oukou mau lima, a noho oukou ma ko lakou aina; a luku aku la au ia lakou imua o oukou.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Alaila ku iluna o Balaka, ke keiki a Zipora, o ke alii o Moaba, a kaua mai oia i ka Iseraela, a hoouna aku la oia, a kahea aku la ia Balaama, i ke keiki a Beora e olelo hoino ia oukou.
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
Aka, aole au i makemake e hoolohe ia Balaama; no ia mea, hoomaikai mai oia ia oukou, a hoopakele au ia oukou, mai kona lima aku.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
A hele mai oukou, maluna mai o Ioredane, a hiki i Ieriko; a kaua mai ka poe noho ma Ieriko ia oukou, a me ka Amora, a me ka Pereza, a me ko Kanaana: a me ka Heta, a me ka Giregasa, a me ka Heva, a me ka Iebusa; a haawi au ia lakou i ko oukou mau lima.
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
A hoouna au imua o oukou i na nalohopeeha, a kipaku aku la au ia lakou, mai ko oukou alo aku, i na'lii elua o ka Amora; aole na ka oukou pahikaua, aole no hoi na ka oukou kakaka.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
A haawi au ia oukou i ka aina nona oukou i hooluhi ole ai, a me na kulanakauhale i kukulu ole ia'i e oukou, a ke noho nei oukou malaila; a ke ai nei oukou i kona malawaina, a me na mala oliva a oukou i kanu ole ai.
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
Ano la, e makau oukou ia Iehova, a e malama ia ia, me ka manao maikai, a me ka oiaio; a e haalele oukou i na akua a ko oukou mau makua i malama'i, ma kela kapa aku o ka muliwai, a ma Aigupita; a e malama oukou ia Iehova.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
A ina he mea ino i ko oukou manao ke malama ia Iehova, e koho oukou i keia la i ka oukou mea e malama aku ai; i na'kua paha a ko oukou poe kupuna i malama'i ma kela kapa aku o ka muliwai, i na'kua paha o ka Amora, no lakou no ka aina e noho nei oukou: aka, owau, a me ko ka hale o'u, e malama makou ia Iehova.
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
Alaila, olelo aku la na kanaka, i mai la, Aole loa makou e haalele ia Iehova, a e malama i na akua e;
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
No ka mea, o Iehova, ko kakou Akua, oia no ka mea nana i lawe mai ia kakou, a me ko kakou poe makua mai ka aina o Aigupita mai, mailoko mai hoi o ka hale hooluhi; ka mea nana i hana i na mea nui imua o ko kakou mau maka, a malama mai oia ia kakou ma ke alanui a pau a kakou i hele mai ai, a mawaena o na kanaka a pau ma kahi a kakou i hele ai.
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
A na Iehova no i kipaku aku, mai ko kakou alo aku i na kanaka a pau, i ka Amora, i noho i ka aina; ano la e malama kakou ia Iehova, no ka mea, oia no ko kakou Akua.
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
A olelo mai la o Iosua i na kanaka, Aole hiki ia oukou ke malama ia Iehova, no ka mea, he Akua ihiihi oia, he Akua lili no hoi; aole e kala mai oia i ko oukou hala, a me ko oukou hewa.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
No ka mea, ina e haalele oukou ia Iehova, a e malama i na'kua o, alaila e huli oia a e hoino mai oia ia oukou, a e hoopau oia ia oukou mahope iho o kona lokomaikai ana mai ia oukou.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
Alaila, olelo aku la na kanaka ia Iosua, Aole loa pela, no ka mea, e malama aku no makou ia Iehova.
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
Olelo mai la o Iosua i na kanaka, He poe hoike oukou no oukou iho, ua koho oukou ia Iehova no oukou, e malama aku ia ia. Olelo aku la lakou, He poe hoike no makou.
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
Ano la, e kipaku oukou i na akua e, mai ko oukou alo aku, a e hoopili oukou me ko oukou naau ia Iehova i ke Akua o ka Iseraela.
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
Olelo aku la na kanaka ia Iosua, O Iehova, o ko kakou Akua, o ka makou ia e malama aku ai, a o kona leo ka makou e hoolohe aku ai.
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
A hana iho la o Iosua i berita me na kanaka i kela la, a waiho oia no lakou i ke kanawai a me ke kapu ma Sekema.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
A kakau iho la o Iosua i keia mau olelo maloko o ka buke o ke kanawai o ke Akua, a lawe no hoi oia i pohaku nui, a kukulu iho la i ua pohaku la malaila, ma ka laau e kokoke ana i ka halelewa o Iehova.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
Olelo aku la o Iosua i na kanaka a pau, Eia hoi keia pohaku, oia ko kakou mea hoike; no ka mea, ua lohe ia mea i na olelo a pau a Iehova, ana i kauoha mai ai ia kakou; a he mea hoike no ia no oukou, o hoole oukou i ke Akua.
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
A hookuu aku la o Iosua i ka poe kanaka, i kela kanaka i keia kanaka i kona aina.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Mahope iho o keia mau mea, make iho la o Iosua, ke keiki a Nuna, ke kauwa a Iehova, a o kona mau la a pau, hookahi ia haneri makahiki a me ka umi keu.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
A kanu iho la lakou ia ia ma ke kihi o kona aina, ma Timenasera, ma ka puu o Eperaima, ma ke kukulu akau o ka puu o Gaasa.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
A malama no ka Iseraela ia Iehova i na la a pau o Iosua, a i na la a pau o na lunakahiko, i ola mahope iho o Iosua, ka poe i ike i na mea a pau a Iehova i hana mai ai i ka Iseraela.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
A o na iwi o Iosepa a na mamo a Iseraela i lawe mai ai, mai Aigupita mai, kanu iho la lakou ia mea ma Sekema, i kahi ma ke kula a Iakoba i kuai ai me na keiki a Hamora, ka makua o Sekema, i na moni hookahi haneri; a ili mai no ia no na keiki a Iosepa.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
A make o Eleazara ke keiki a Aarona; a kanu iho la lakou ia ia ma ka puu o Pinehasa o kana keiki, i haawiia mai nona ma ka mauna o Eperaima.

< Joshua 24 >