< Joshua 24 >
1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
Sitten Joosua kokosi kaikki Israelin sukukunnat Sikemiin ja kutsui Israelin vanhimmat, sen päämiehet, tuomarit ja päällysmiehet, ja he asettuivat Jumalan eteen.
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
Ja Joosua sanoi koko kansalle: "Näin sanoo Herra, Israelin Jumala: Tuolla puolella Eufrat-virran asuivat muinoin teidän isänne, myös Terah, Aabrahamin ja Naahorin isä, ja he palvelivat muita jumalia.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
Mutta minä otin teidän isänne Aabrahamin tuolta puolelta virran ja kuljetin häntä kautta koko Kanaanin maan ja tein hänen jälkeläisensä lukuisiksi ja annoin hänelle Iisakin.
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Ja Iisakille minä annoin Jaakobin ja Eesaun. Ja Eesaulle minä annoin Seirin vuoriston omaksi, mutta Jaakob ja hänen poikansa menivät Egyptiin.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
Sitten minä lähetin Mooseksen ja Aaronin ja rankaisin Egyptiä sillä, mitä minä siellä tein, ja sen jälkeen minä vein teidät sieltä pois.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
Ja kun minä vein teidän isänne pois Egyptistä ja te olitte saapuneet meren rannalle, ajoivat egyptiläiset teidän isiänne takaa sotavaunuilla ja ratsumiehillä Kaislamereen saakka.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
Niin he huusivat Herraa, ja hän pani pimeyden teidän ja egyptiläisten välille ja antoi meren tulla heidän ylitsensä, ja se peitti heidät; omin silmin te näitte, mitä minä tein egyptiläisille. Kun te sitten olitte asuneet kauan aikaa erämaassa,
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
toin minä teidät amorilaisten maahan, jotka asuivat tuolla puolella Jordanin, ja he taistelivat teitä vastaan; mutta minä annoin heidät teidän käsiinne, ja te otitte omaksenne heidän maansa, ja minä tuhosin heidät teidän tieltänne.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Silloin nousi Baalak, Sipporin poika, Mooabin kuningas ja taisteli Israelia vastaan; ja hän lähetti kutsumaan Bileamin, Beorin pojan, että hän kiroaisi teidät.
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
Mutta minä en tahtonut kuulla Bileamia, vaan hänen täytyi siunata teidät, ja minä pelastin teidät hänen käsistään.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Ja kun te olitte menneet Jordanin yli ja tulleet Jerikoon, niin Jerikon miehet ja amorilaiset, perissiläiset, kanaanilaiset, heettiläiset, girgasilaiset, hivviläiset ja jebusilaiset taistelivat teitä vastaan, mutta minä annoin heidät teidän käsiinne.
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
Ja minä lähetin herhiläisiä teidän edellänne, ja ne karkoittivat heidät teidän tieltänne, ne kaksi amorilaisten kuningasta; sinä miekallasi ja jousellasi et sitä tehnyt.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
Ja minä annoin teille maan, josta sinä et ollut vaivaa nähnyt, ja kaupunkeja, joita te ette olleet rakentaneet, mutta joihin saitte asettua; viinitarhoista ja öljypuista, joita te ette olleet istuttaneet, te saitte syödä.
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
Niin peljätkää nyt Herraa, palvelkaa häntä nuhteettomasti ja uskollisesti ja poistakaa ne jumalat, joita teidän isänne palvelivat tuolla puolella virran ja Egyptissä, ja palvelkaa Herraa.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
Mutta jos pidätte pahana palvella Herraa, niin valitkaa tänä päivänä, ketä tahdotte palvella, niitäkö jumalia, joita teidän isänne palvelivat tuolla puolella virran, vai amorilaisten jumalia, niiden, joiden maassa te asutte. Mutta minä ja minun perheeni palvelemme Herraa."
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
Silloin kansa vastasi ja sanoi: "Pois se, että me hylkäisimme Herran ja palvelisimme muita jumalia!
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
Sillä Herra on meidän Jumalamme, hän, joka johdatti meidät ja meidän isämme pois Egyptin maasta, orjuuden pesästä, ja joka teki meidän silmiemme edessä suuret tunnusteot ja aina varjeli meitä sillä tiellä, jota me vaelsimme, ja kaikkien niiden kansojen keskellä, joiden kautta me kuljimme.
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
Ja Herra karkoitti meidän tieltämme kaikki ne kansat, myös amorilaiset, jotka asuivat tässä maassa. Sentähden me palvelemme Herraa, sillä hän on meidän Jumalamme."
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
Niin Joosua sanoi kansalle: "Te ette voi palvella Herraa, sillä hän on pyhä Jumala; hän on kiivas Jumala, hän ei anna anteeksi teidän rikoksianne ja syntejänne.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
Jos te hylkäätte Herran ja palvelette vieraita jumalia, niin hän kääntyy pois ja antaa teille käydä pahoin ja tekee lopun teistä, sen sijaan että hän on ennen antanut teille käydä hyvin."
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
Mutta kansa sanoi Joosualle: "Ei niin, vaan me palvelemme Herraa".
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
Silloin Joosua sanoi kansalle: "Te olette itse todistajina itseänne vastaan, että olette valinneet itsellenne Herran palvellaksenne häntä". He vastasivat: "Olemme".
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
Hän sanoi: "Niin poistakaa nyt vieraat jumalat, joita on teidän keskuudessanne, ja taivuttakaa sydämenne Herran, Israelin Jumalan, puoleen".
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
Kansa vastasi Joosualle: "Herraa, meidän Jumalaamme, me palvelemme, ja hänen ääntänsä me kuulemme".
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
Niin Joosua teki sinä päivänä liiton kansan kanssa ja antoi heille Sikemissä käskyt ja oikeudet.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
Ja Joosua kirjoitti nämä puheet Jumalan lain kirjaan, ja hän otti suuren kiven ja pystytti sen sinne, tammen alle, joka oli Herran pyhäkössä.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
Ja Joosua sanoi kaikelle kansalle: "Katso, tämä kivi on oleva todistajana meitä vastaan, sillä se on kuullut kaikki Herran sanat, jotka hän on meille puhunut, ja se on oleva todistajana teitä vastaan, ettette kieltäisi Jumalaanne".
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Sitten Joosua päästi kansan menemään, kunkin perintöosalleen.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Näiden tapausten jälkeen Herran palvelija Joosua, Nuunin poika, kuoli sadan kymmenen vuoden vanhana.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
Ja he hautasivat hänet hänen perintöosansa alueelle, Timnat-Serahiin, joka on Efraimin vuoristossa, pohjoispuolelle Gaas-vuorta.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Ja Israel palveli Herraa Joosuan koko elinajan ja niiden vanhinten koko elinajan, jotka elivät vielä kauan Joosuan jälkeen ja tunsivat kaikki ne teot, jotka Herra oli Israelille tehnyt.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
Ja Joosefin luut, jotka israelilaiset olivat tuoneet Egyptistä, he hautasivat Sikemiin, siihen maapalstaan, jonka Jaakob oli ostanut Hamorin, Sikemin isän, pojilta sadalla kesitalla ja jonka joosefilaiset olivat saaneet perintöosaksensa.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
Ja Eleasar, Aaronin poika, kuoli, ja he hautasivat hänet Gibeaan, hänen poikansa Piinehaan kaupunkiin, joka oli annettu hänelle Efraimin vuoristosta.