< Joshua 24 >

1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
Ja Josua kokosi kaikki Israelin sukukunnat Sikemiin, ja kutsui edes vanhimmat Israelissa, päämiehet, tuomarit ja esimiehet; ja kuin he olivat seisatetut Jumalan eteen,
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
Sanoi Josua kaikelle kansalle: näin sanoo Herra Israelin Jumala: teidän isänne asuivat entiseen aikaan sillä puolella virtaa, Tara, Abrahamin ja Nahorin isä, ja palvelivat muita jumalia.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
Niin otin minä isänne Abrahamin tuolta puolelta virtaa, ja annoin hänen vaeltaa koko Kanaanin maalla, ja enensin hänen siemenensä, ja annoin hänelle Isaakin.
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Ja Isaakille annoin minä Jakobin ja Esaun; ja annoin Esaulle Seirin vuoren asuaksensa. Mutta Jakob ja hänen lapsensa menivät alas Egyptin maalle.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
Ja minä lähetin Moseksen ja Aaronin, ja rankaisin Egyptin, niinkuin minä heidän seassansa tehnyt olen; sitte vein minä teidät ulos.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
Niin vein minä myös teidän isänne Egyptistä ulos, ja te tulitte meren tykö; ja Egyptiläiset ajoivat teidän isiänne takaa vaunuin ja ratsasmiesten kanssa Punaiseen mereen saakka.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
Niin huusivat he Herran tykö, ja hän pani pimeyden teidän ja Egyptiläisten vaiheelle, ja saatti meren heidän päällensä, ja peitti heidät. Ja teidän silmänne näkivät, mitä minä tein Egyptissä; ja te asuitte korvessa kauvan aikaa.
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
Ja minä toin teidät Amorilaisten maahan, jotka asuivat tuolla puolella Jordania; ja kuin he sotivat teitä vastaan, annoin minä heidät teidän käsiinne, että te omistaisitte heidän maansa; ja minä hävitin heitä teidän edestänne.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Niin nousi Balak Zipporin poika, Moabin kuningas, ja soti Israelia vastaan; ja hän lähetti ja antoi kutsua Bileamin Beorin pojan kiroomaan teitä.
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
Mutta en minä tahtonut kuulla Bileamia; ja hän siunaten siunasi teitä, ja minä vapahdin teitä hänen käsistänsä.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
Ja kuin te tulitte Jordanin ylitse ja jouduitte Jerihoon, sotivat Jerihon asuvaiset teitä vastaan, Amorilaiset ja Pheresiläiset ja Kanaanealaiset ja Hetiläiset ja Girgasilaiset ja Heviläiset ja Jebusilaiset; mutta minä annoin heidät teidän käsiinne,
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
Ja lähetin vapsaiset teidän edellänne, ja ne ajoivat heidät ulos teidän edestänne, kaksi Amorilaisten kuningasta, ei sinun miekkas kautta eikä sinun joutses kautta.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
Ja annoin teille maan, jossa ette mitään työtä tehneet, ja kaupungit, joita ette rakentaneet, asuaksenne niissä ja syödäksennne viinapuista ja öljypuista, joita ette istuttaneet.
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
Peljätkäät siis nyt Herraa ja palvelkaat häntä täydellisesti ja uskollisesti, ja hyljätkäät ne jumalat, joita teidän isänne palvelivat tuolla puolella virtaa ja Egyptissä, ja palvelkaat Herraa.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
Jollei teidän kelpaa Herraa palvella, niin valitkaat teillenne tänäpäivänä ketä te palvelette, niitä jumalia, joita teidän isänne palvelivat sillä puolella virtaa, eli Amorilaisten jumalia, joiden maassa te asutte. Mutta minä ja minun huoneeni palvelemme Herraa.
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
Niin vastasi kansa ja sanoi: pois se meistä, että me hylkäisimme Herran ja palvelisimme muita jumalia.
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
Sillä Herra meidän Jumalamme on se, joka johdatti meitä ja meidän isiämme Egyptin maalta orjuuden huoneesta, ja joka teki meidän silmäimme edessä niitä suuria tunnusmerkkejä, ja varjeli meitä kaikella matkalla, jota me vaelsimme, ja kaikkein kansain seassa, joiden lävitse me kävimme.
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
Ja Herra ajoi meidän edestämme ulos kaiken kansan ja Amorilaiset, jotka asuivat maassa: niin me myös palvelemme Herraa, sillä hän on meidän Jumalamme.
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
Ja Josua sanoi kansalle: ette taida palvella Herraa, sillä hän on pyhä Jumala ja hän on kiivas Jumala, joka ei säästä teidän syntejänne.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
Kuin te hylkäätte Herran ja palvelette muukalaisia jumalia, niin hän kääntää hänensä, ja tekee teille pahaa, ja hukuttaa teitä sen jälkeen, kuin hän teille hyvää teki.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
Niin sanoi kansa Josualle: ei suinkaan, vaan me palvelemme Herraa.
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
Ja Josua sanoi kansalle: te olette teillenne todistajat, että te valitsitte teillenne Herran, palvellaksenne häntä. Ja he sanoivat: me olemme todistajat.
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
Niin pankaat nyt teidän tyköänne muukalaiset jumalat pois, jotka teidän seassanne ovat, ja kumartakaat teidän sydämenne Herran Israelin Jumalan tykö.
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
Ja kansa sanoi Josualle: me tahdomme palvella Herraa meidän Jumalaamme, ja olemme hänen äänellensä kuuliaiset.
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
Niin Josua teki sinä päivänä liiton kansan kanssa, ja asetti säädyn ja oikeuden heidän eteensä Sikemissä.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
Ja Josua kirjoitti kaikki nämä sanat Jumalan lakikirjaan, ja otti suuren kiven, ja pystytti sen siinä tammen alla, joka oli Herran pyhässä.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
Ja Josua sanoi kaikelle kansalle: katso, tämä kivi pitää oleman todistus meidän vaiheellamme; sillä hän on kuullut kaikki Herran puheet, jotka hän meidän kanssamme puhunut on, ja pitää oleman teille todistus, ettette teidän Jumalaanne kiellä.
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Ja niin antoi Josua kansan mennä, itsekunkin perintöönsä.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Ja sen jälkeen tapahtui, että Josua Nunin poika, Herran palvelia, kuoli, sadan ja kymmenen ajastaikaisena.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
Ja he hautasivat hänen oman perityn maansa rajoihin, Timnat Serakiin, joka on Ephraimin vuorella, pohjan puolelle Gaasin vuorta.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Ja Israel palveli Herraa kaikkena Josuan elinaikana, niin myös kaikkena vanhimpain elinaikana, jotka kauvan aikaa josuan perästä elivät ja tiesivät kaikki Herran teot, jotka hän Israelille tehnyt oli.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
Ja Josephin luut, jotka Israelin lapset olivat tuoneet Egyptistä, hautasivat he Sikemiin, siihen pellon kappaleeseen, jonka Jakob osti Hemorin Sikemin isän lapsilta sadalla penningillä. Ja se tuli Josephin lasten perinnöksi.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
Niin kuoli myös Eleatsar Aaronin poika, ja he hautasivat hänen Gibeassa, joka oli hänen poikansa Pinehaan oma, joka hänelle Ephraimin vuorella annettu oli.

< Joshua 24 >