< Joshua 24 >
1 Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
Joshua mah Israel acaengnawk to Shekem vangpui ah amkhuengsak boih; kacoehtanawk, zaehoikungnawk, lokcaekkungnawk hoi ukkungnawk to a kawk moe, Angraeng hmaa ah amkhueng o.
2 Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
Joshua mah kaminawk boih khaeah, Israel Angraeng Sithaw mah hae tiah thuih; Canghniah Abraham hoi Nahor ampa Terah hoi nangcae ih amsaenawk loe, vapui yaeh ah khosak o moe, kalah prae kaminawk ih sithawnawk to a bok o.
3 Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
Toe nam pa Abraham to vapui yaeh hoiah ka lak moe, Kanaan prae thung boih ah ka zaeh; anih ih atii to ka pungsak moe, anih hanah Issak to ka paek.
4 àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
Issak hanah Jakob hoi Esau to ka paek; Esau mah qawk ah toep hanah Seir maeto ka paek, toe Jakob hoi a caanawk loe Izip prae ah caeh o tathuk.
5 “‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
To pacoengah Mosi hoi Aaron to ka patoeh; Izip kaminawk mah sak o ih hmuen baktih toengah, Izip prae to raihaih ka paek; to pacoengah nangcae to kang hoih o.
6 Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
Nam panawk to Izip prae thung hoi ka zaeh naah, tuipui to a phak o; to naah Izip kaminawk mah nam panawk to hrang lakok hoiah hrang angthueng kaminawk mah tuipui kathim khoek to patom o.
7 Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
Toe nihcae mah Angraeng khaeah hangh o naah, anih mah nangcae hoi Izip kaminawk salakah vinghaih to phaksak moe, nihcae to tui uemsak boih; Izip prae ah ka sak ih hmuen to na hnuk o boeh; to pacoengah nangcae loe praezaek ah saning kasawkah na oh o.
8 “‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
Jordan vapui yaeh ah kaom, Amor kaminawk ih prae ah kang caeh o haih; nihcae mah ang tuk o naah, nihcae to nangcae ban ah kang paek moe, nihcae ih prae to na lak o; nihcae to nangcae hmaa roe ah kam rosak.
9 Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
Moab siangpahrang, Zippor capa Balak mah angthawk moe, Israel kaminawk tuk naah, nangcae tangoengsak hanah Beor capa Balaam to a kawksak;
10 Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
toe Baalam ih lok to ka tahngai pae ai; anih mah tahamhoihaih ang paek o; to pongah anih ban thung hoiah nangcae to kang pahlong o.
11 “‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
To pacoengah Jordan vapui to nang kaat o moe, Jeriko na phak o naah, Jeriko kaminawk, Amor kaminawk, Periz kaminawk, Kanaan kaminawk, Hit kaminawk, Girgash kaminawk, Hiv kaminawk hoi Jebus kaminawk mah ang tuk o; toe nihcae to nangcae ban ah kang paek.
12 Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
Nangcae loe sumsen hoi kalii to na sin o ai, nangcae hmaa ah khoi to ka patoeh moe, Amor siangpahrang hnetto nangcae hmaa ah kang haek pae.
13 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
To pongah na sak o ai ih lawk hoi na sak o ai ih vangpuinawk to kang paek o moe, athung ah na oh o; nangcae mah na tling o ai ih, misur thaih hoi olive thaih to na caak o, tiah a thuih.
14 “Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
To pongah Angraeng to zii oh loe, loktang hoi oepthohhaih hoiah a tok to sah oh; nam saenawk mah Izip prae hoi vapui yaeh ah bok o ih sithawnawk to pahnawt oh loe, Angraeng ih tok to sah oh.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
Toe Angraeng ih toksak loe hoih ai, tiah na poek o moe, vapui yaeh ah nam panawk mah bok o ih sithawnawk ih tok, to tih ai boeh loe vaihi na oh o haih Amor prae kaminawk mah bok o ih sithawnawk ih tok to na sak o han maw? Vaihniah qoi oh! Toe kai hoi ka imthung takoh loe, Sithaw tok ni ka sak o han, tiah a naa.
16 Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
To naah kaminawk mah, Kalah sithawnawk ih toksak hanah, Angraeng to ka pahnawt o mak ai;
17 Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
aicae Angraeng Sithaw, Anih mah ni aicae hoi aicae ampanawk to misong ah ohhaih, Izip prae thung hoiah zaeh moe, aicae mikhnuk ah kalen parai angmathaihnawk to sak; a caeh o haih ahmuen kruek, prae kaminawk salakah a caeh o naah doeh, anih mah ni ang pakaa.
18 Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
Angraeng mah prae kaminawk to aicae hmaa hoiah haek; hae prae thungah kaom Amor kaminawk doeh a haek; anih loe kaicae ih Sithaw ah oh pongah, Angraeng ih tok ni ka sak o han, tiah a naa o.
19 Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
Joshua mah kaminawk khaeah, Angraeng ih tok na sah o thai mak ai; anih loe ciimcai Sithaw ah oh moe, ut panoek Sithaw ah oh; anih mah na sak o pazae ih zaehaihnawk to tahmen mak ai.
20 Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
Anih loe nangcae nuiah kahoih hmuen to sak, toe Angraeng to na pahnawt o moe, prae kalah sithawnawk ih tok to na sak o taak ving nahaeloe, nangcae to angqoi taak ueloe, nangcae nuiah amrohaih phaksak pacoengah, nangcae to tamit boih tih, tiah a naa.
21 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
Toe kaminawk mah Joshua khaeah, To tih na ai ni! Angraeng ih tok ni ka sak o han, tiah a naa o.
22 Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
To naah Joshua mah kaminawk khaeah, Angraeng toksak han na qoih o boeh pongah, nangmacae roe to hnukung ah na oh o boeh, tiah a naa. Nihcae mah, Kaimacae hae hnukung ah ka oh o boeh, tiah a naa o.
23 Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
To naah Joshua mah, To tih nahaeloe nangcae salakah kaom prae kalah kaminawk ih sithawnawk to vaihi va o boih loe, Israel Angraeng Sithaw bangah na poekhaih palungthin to suem oh, tiah a naa.
24 Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
Kaminawk mah Joshua khaeah, Ka Angraeng Sithaw ih tok to ka sak o moe, a lok ka tahngaih pae o han, tiah a naa o.
25 Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
To pongah to na niah, Joshua mah kaminawk hoi lokmaihaih to sak moe, Shekem vangpui ah nihcae han lokmaihhaih daan hoi toksakhaih atawk to a sak pae.
26 Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
Joshua mah hae ih loknawk hae Angraeng ih kaalok cabu thungah tarik pae; to pacoengah kalen parai thlung to lak moe, Angraeng ih hmuenciim taengah kaom, thing kamtak thing tlim ah a suek.
27 “E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
Kaminawk boih khaeah, Khen oh, hae thlung loe aicae hnukung ah om tih; Angraeng mah aicae khaeah thuih ih loknawk boih hae thlung mah thaih boeh; na Angraeng Sithaw na pahnawt o moeng han ai ah, hae thlung hae nangcae hnukung ah om tih, tiah a naa.
28 Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
To pacoengah Joshua mah kaminawk boih angmacae qawktoep ih ahmuen ah amlaemsak let.
29 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
Hae hmuennawk boih oh pacoengah, Angraeng ih tamna, Nun capa Joshua loe saning cumvai, hato phak naah duek.
30 Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
Anih loe angmah toep ih prae, Gaash mae aluek bangah kaom, Ephraim mae nui ih, Timnath-Serah ahmuen ah aphum o.
31 Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
Israel kaminawk loe Joshua hing thung, Joshua pong saning kasawk kue ah kahing kacoehtanawk hing o nathung, Angraeng mah Israel kaminawk hanah sak pae ih hmuennawk boih panoek kaminawk hing o nathung, Angraeng ih tok to sak o.
32 Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
Israel kaminawk mah Izip prae thung hoi sinh o ih Joseph ih ahuhnawk to, Jakob mah Shekem ampa Hamor ih caanawk khaeah, phoisa cumvaito hoiah qan ih Shekem vangpui taeng ih ahmuen ah aphum o; toe to long ahmuen loe Joseph ih caanawk mah qawk ah toep o ih ahmuen ah oh.
33 Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.
Aaron capa Eleazar doeh duek; anih loe a capa Phinehas khaeah paek ih, Ephraim mae nuiah aphum o.