< Joshua 23 >

1 Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
Și s-a întâmplat, la multe zile după ce DOMNUL a dat odihnă lui Israel, din partea tuturor dușmanilor săi de jur-împrejur, că Iosua era bătrân și înaintat în zile.
2 Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
Și Iosua a chemat pe tot Israelul, pe bătrânii lor și pe căpeteniile lor și pe judecătorii lor și pe ofițerii lor și le-a spus: Eu am îmbătrânit și sunt înaintat în zile.
3 Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
Și ați văzut tot ce a făcut DOMNUL Dumnezeul vostru tuturor națiunilor acestora pentru voi, fiindcă DOMNUL Dumnezeul vostru este cel care a luptat pentru voi.
4 Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Iată, v-am împărțit prin sorț aceste națiuni rămase, ca să fie moștenire pentru triburile voastre, de la Iordan, împreună cu toate națiunile pe care le-am stârpit și până la Marea cea Mare, spre vest.
5 Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
Și DOMNUL Dumnezeul vostru, el însuși le va scoate dinaintea voastră și le va alunga dinaintea voastră; și voi veți stăpâni țara lor, cum v-a promis DOMNUL Dumnezeul vostru.
6 “Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
De aceea fiți foarte curajoși să țineți și să faceți tot ce este scris în cartea legii lui Moise, să nu vă abateți de la ea nici la dreapta, nici la stânga,
7 Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
Ca să nu intrați printre aceste națiuni care au rămas între voi, nici să nu amintiți numele dumnezeilor lor, nici să nu jurați pe ei, nici să nu le serviți și nici să nu vă prosternați înaintea lor,
8 Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
Ci să vă alipiți de DOMNUL Dumnezeul vostru, așa cum ați făcut până în această zi.
9 “Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
Fiindcă DOMNUL a alungat dinaintea voastră națiuni mari și puternice; dar cât despre voi, nimeni nu a putut să vă stea înainte, până în această zi.
10 Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
Un singur om dintre voi va urmări o mie, fiindcă DOMNUL Dumnezeul vostru este cel care luptă pentru voi, așa cum v-a promis.
11 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
De aceea luați seama bine la sufletele voastre, ca să iubiți pe DOMNUL Dumnezeul vostru.
12 “Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
Altfel, dacă veți da înapoi în vreun fel și vă veți alipi de rămășița acestor națiuni, de cele care rămân printre voi, și vă veți căsători cu ele și veți intra la ele și ele la voi,
13 Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
Să știți fără nicio îndoială că DOMNUL Dumnezeul vostru nu va mai alunga aceste națiuni dinaintea voastră și vă vor fi lațuri și curse și bice în coastele voastre și spini în ochii voștri, până veți pieri din această țară bună, pe care v-a dat-o DOMNUL Dumnezeul vostru.
14 “Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
Și, iată, astăzi mă duc pe calea întregului pământ și știți din toată inima voastră și din tot sufletul vostru că nu a eșuat niciun lucru din toate lucrurile bune pe care le-a spus DOMNUL Dumnezeul vostru despre voi. Toate vi s-au întâmplat, un singur cuvânt din ele nu a căzut.
15 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
De aceea se va întâmpla că, așa cum toate lucrurile bune, pe care vi le-a spus DOMNUL Dumnezeul vostru, au venit peste voi, tot așa DOMNUL va face să vină asupra voastră toate lucrurile rele, până vă va nimici de pe acest pământ bun, pe care vi l-a dat DOMNUL Dumnezeul vostru.
16 Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”
Când veți încălca legământul DOMNULUI Dumnezeul vostru, pe care vi l-a poruncit, și veți merge și veți servi altor dumnezei și vă veți pleca înaintea lor, atunci mânia DOMNULUI se va aprinde împotriva voastră și veți pieri repede din această țară bună, pe care v-a dat-o el.

< Joshua 23 >