< Joshua 23 >
1 Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
Lőn pedig sok nappal azután, hogy nyugodalmat adott vala az Úr Izráelnek minden ő körülötte lévő ellenségeitől: megvénhedék Józsué és megidősödék.
2 Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
Előhívá ekkor Józsué az egész Izráelt, annak véneit, fejeit, biráit és felügyelőit, és monda nékik: Én megvénhedtem és megidősödtem.
3 Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
Magatok is láttatok mindent, a mit az Úr, a ti Istenetek mind eme népekkel cselekedett ti előttetek; mivelhogy maga az Úr, a ti Istenetek harczolt érettetek.
4 Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Ímé elosztám néktek sors által a fennmaradt népeket örökségül a ti nemzetségeitek szerint, a Jordántól kezdve, és mindazokat a népeket, a melyeket kipusztítottam, és a nagy tengert is napnyugat felől.
5 Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
Az Úr pedig, a ti Istenetek kiűzi őket a ti orczátok elől, és kiűzi őket ti előletek, hogy örököseivé legyetek az ő földüknek, a mint megmondotta vala néktek az Úr, a ti Istenetek.
6 “Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
Legyetek azért igen erősek, hogy megtartsátok és megcselekedjétek mind azt, a mi meg van írva a Mózes törvényének könyvében; hogy el ne távozzatok attól se jobbkézre, se balkézre;
7 Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
Hogy össze ne elegyedjetek ezekkel a népekkel, azokkal, a melyek fenmaradtak közöttetek; isteneiknek nevét ki se ejtsétek, azokra ne esküdjetek, se ne szolgáljatok nékik, se előttök meg ne hajoljatok;
8 Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
Hanem ragaszkodjatok az Úrhoz, a ti Istenetekhez, a miképen e mai napig cselekedtetek!
9 “Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
Ezért űzött ki az Úr előletek nagy és erős népeket: a mi pedig titeket illet, senki meg nem állhatott ellenetekben mind e napig.
10 Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
Egy férfiú közületek elűz ezeret, mert az Úr, a ti Istenetek az, a ki harczol érettetek, a miképen megmondta vala néktek.
11 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
Azért igen vigyázzatok magatokra, hogy szeressétek az Urat, a ti Isteneteket!
12 “Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
Mert ha elfordulván elfordultok tőle és ragaszkodtok e népek maradékaihoz, a melyek itt maradtak ti közöttetek; és sógorságot köttök ő velök és összeelegyedtek velök és ők veletek:
13 Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
Bizonynyal megtudjátok majd, hogy az Úr, a ti Istenetek ki nem űzi többé e népeket ti előletek; sőt inkább lésznek ti néktek tőrré és hurokká, oldalaitokban ostorrá, szemeitekben pedig tövisekké, míglen kivesztek erről a jó földről, a melyet az Úr, a ti Istenetek adott ti néktek.
14 “Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
Én pedig ímé megyek már a minden földinek útján: Tudjátok meg azért teljes szívetek és teljes lelketek szerint, hogy egy szó sem esett el mindama jó szóból, a melyeket az Úr, a ti Istenetek szólott vala felőletek. Minden betelt rajtatok, egy szó sem esett el azokból!
15 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
De a miképen betelt rajtatok mind az a jó szó, a melyeket az Úr, a ti Istenetek szólott vala felőletek: akképen teljesíti majd rajtatok mind a gonosz szót is az Úr, míglen kipusztít titeket e jó földről, a melyet az Úr, a ti Istenetek adott ti néktek.
16 Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”
Ha általhágjátok az Úrnak, a ti Isteneteknek szövetségét, a melyet parancsolt néktek, és elmentek és szolgáltok idegen isteneknek, és meghajoltok azok előtt: akkor felgerjed ellenetek az Úrnak haragja, és hamar kivesztek e jó földről, a melyet ő adott néktek.