< Joshua 23 >

1 Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
És volt sok idő múlva, miután nyugalmat szerzett az Örökkévaló Izraélnek mind az ellenségeitől köröskörül, Józsua pedig öreg lett, előrehaladt a korban,
2 Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
akkor hívta Józsua egész Izraélt, véneit, fejeit, bíráit és tisztviselőit és szólt hozzájuk: Én öreg lettem, előrehaladtam a korban.
3 Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
Ti láttátok mindazt, amit tett az Örökkévaló, a ti Istentek, mind e népekkel miattatok, mert az Örökkévaló, a ti Istentek az, aki harcolt érettetek.
4 Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Lássátok, birtokul juttattam nektek e megmaradt népeket törzseitek szerint – a Jordántól fogva – és mind a népeket, melyeket kiirtottam, a nagy tengerig napnyugaton.
5 Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
És az Örökkévaló, a ti Istentek – ő el fogja kergetni őket előletek és kiűzni őket előttetek, hogy elfoglaljátok országukat, amint szólt nektek az Örökkévaló, a ti Istentek.
6 “Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
De legyetek erősek nagyon, hogy megőrizzétek és megtegyétek mindazt, ami írva van Mózes tanának könyvében, el nem térvén attól sem jobbra, sem balra;
7 Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
hogy ne jussatok e népek közé, akik itt maradtak veletek, isteneik nevére ne hivatkozzatok és ne tegyetek esküt, ne szolgáljátok őket és ne boruljatok le előttük.
8 Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
Hanem az Örökkévalóhoz, a ti Istentekhez ragaszkodjatok, amint tettétek mind e mai napig.
9 “Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
El is űzött az Örökkévaló előletek nagy és hatalmas népeket és ti – meg nem állott előttetek senki mind e mai napig.
10 Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
Egy ember közületek üldöz ezret, mert az Örökkévaló a ti Istentek – ő az, aki harcol érettetek, amint szólt nektek.
11 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
Őrizkedjetek tehát nagyon lelkeitekért, hogy szeressétek az Örökkévalót, a ti Istenteket.
12 “Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
Mert ha elfordultok és csatlakoztok e népek maradékához, amelyek itt megmaradtak köztetek és összeházasodtok velük, hogy közéjük jussatok, ők meg közétek:
13 Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
tudjátok meg, hogy nem fogja többé az Örökkévaló, a ti Istentek kiűzni előletek e népeket, s lesznek majd nektek tőrré és kelepcévé, ostorrá oldalaitokon és tövisekké szemeitekben, míg el nem vesztek e jó földről, melyet adott nektek az Örökkévaló, a ti Istentek.
14 “Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
S íme, én megyek most az egész földnek utjára – ismerjétek föl egész szívetekkel és egész lelketekkel, hogy nem maradt el egy ige sem mind azon jó igékből, melyeket az Örökkévaló, a ti Istentek szólt felőletek; mind bekövetkeztek számotokra, nem maradt el abból egy sem.
15 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
És lészen, a mint rátok jött mind a jó ige, melyet szólt felőletek az Örökkévaló, a ti Istentek, úgy elhozza rátok az Örökkévaló mind a rossz igét, míg el nem pusztított titeket erről a jó földről, melyet adott nektek az Örökkévaló, a ti Istentek.
16 Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”
Midőn megszegitek az Örökkévaló, a ti Istentek szövetségét, melyet parancsolt nektek, s elmentek és szolgáltok más isteneket és leborultok előttük, akkor majd föllobban az Örökkévaló haragja ellenetek és elvesztek csakhamar azon jó országból, melyet adott nektek.

< Joshua 23 >