< Joshua 22 >
1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Då kallade Josua till sig de Rubeniter och Gaditer, och den halfva slägtena Manasse.
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
Och sade till dem: I hafven hållit allt det Mose Herrans tjenare eder budit hafver, och lydt mine röst i allt det jag hafver budit eder.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
I hafven icke öfvergifvit edra bröder nu i en lång tid, allt intill denna dag; och hafven blifvit vid Herrans edars Guds bud.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Efter nu Herren edar Gud hafver låtit edra bröder komma till ro, såsom han dem sagt hade; så vänder nu om igen, och drager till edra hyddor i edars arfs land, som Mose Herrans tjenare eder gifvit hafver på hinsidon Jordan;
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Allenast tager der vara uppå granneliga, att I gören efter de bud och lag, som Mose Herrans tjenare eder budit hafver; att I älsken Herran edar Gud, och vandren uppå alla hans vägar, och hållen hans bud, och hållen eder intill honom, och tjenen honom af allo hjerta, och af allo själ.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
Så välsignade Josua dem, och lät gå dem; och de gingo till deras hyddor.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Den halfva slägtene Manasse hade Mose gifvit i Basan; den andra hälftene gaf Josua ibland deras bröder på desso sidone Jordan, vestantill. Och då han lät dem gå till deras hyddor, och hade välsignat dem,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
Sade han till dem: I kommen hem igen med stora ägodelar till edra hyddor, med ganska mycken boskap, silfver, guld, koppar, jern och kläder; så skifter nu edra fiendars rof med edra bröder.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
Och så vände de Rubeniter och Gaditer, och den halfva slägten Manasse, om igen, och gingo ifrån Israels barn af Silo, som i Canaans land ligger, att de skulle draga in i Gileads land till deras arfs land, det de till arfs fått hade af Herrans befallning genom Mose.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
Och då de kommo till de högar vid Jordan, som i Canaans land ligga, byggde de samme Rubeniter, Gaditer, och halfva Manasse slägt, der vid Jordan ett stort skönt altare.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
Då Israels barn hörde sägas: Si, Rubens barn, Gads barn, och den halfva slägten Manasse hafva byggt ett altare emot Canaans land, vid Jordans högar, på desso sidone vid Israels barn;
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
Församlade de sig hela menigheten i Silo, att de skulle draga upp till dem, och strida med dem;
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
Och sände till dem in uti Gileads land, Pinehas, Eleazars Prestens son;
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Och med honom tio öfversta Förstar ibland deras fäders hus, af hvarjo Israels slägt en.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Och när de kommo till dem i landet Gilead, talade de med dem, och sade:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Så låter hela Herrans menighet säga eder: Hvi synden I så emot Israels Gud; och vänden eder i dag ifrå Herranom, dermed att I byggen eder ett altare, och fallen ifrå Herranom?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Är oss icke nog med Peors missgerning, af hvilko vi ännu på denna dag icke renade äre; och en plåga kom i Herrans menighet?
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Och I vänden eder i dag bort ifrå Herranom, och ären i dag affällige vordne ifrå Herranom; på det han i dag eller morgon skall vredgas öfver hela Israels menighet.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Tycker eder, att edart arfs land är orent, så kommer hitöfver i det land, som Herren hafver, der Herrans tabernakel är, och tager arf ibland oss; och träder icke ifrå Herranom, och ifrån oss, att I byggen eder ett altare, förutan Herrans vårs Guds altare.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Förbröt icke Achan, Serahs son, sig på det spillgifna; och vreden kom öfver hela Israels menighet, och han umgalt icke sina synd allena?
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Då svarade Rubens barn, och Gads barn, och den halfva slägten Manasse, och sade till de höfvitsmän och Förstar af Israel:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
Herren den starke Gud, Herren den starke Gud vet det, och Israel desslikes; är detta afträdning eller synd emot Herran, så hjelpe han oss intet i dag.
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
Och om vi altaret fördenskull byggt hafve, att vi vilje vända oss ifrå Herranom, offra deruppå bränneoffer och spisoffer, eller göra der tackoffer uppå, så hämnes det Herren;
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
Och om vi icke det mycket heldre för denna sakens skull gjorde, och sade: I dag eller morgon måtte edor barn säga till vår barn: Hvad hafven I göra med Herranom Israels Gud?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Herren hafver satt Jordan till ett landamäre emellan oss och eder; I Rubens och Gads barn, I hafven ingen del med Herranom; och så måtte edor barn komma vår barn ifrå Herrans fruktan.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
Derföre sade vi: Låt oss bygga ett altare, icke till något offer eller bränneoffer;
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
Utan på det att det må vara ett vittnesbörd emellan oss och eder, och våra efterkommande, att vi måge tjena Herranom för honom med vårt bränneoffer, tackoffer och annor offer; och edor barn icke behöfva i dag eller morgon säga till vår barn: I hafven ingen del med Herranom.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
När de nu vordo sägande till oss, eller våra efterkommande i dag eller morgon, så kunna de säga: Ser liknelsen till Herrans altare, hvilket våre fäder gjort hafva; icke till offer eller bränneoffer, utan till ett vittnesbörd emellan oss och eder.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Bort det ifrån oss, att vi skulle träda ifrå Herranom, så att vi i dag skulle vända oss ifrå Herranom, och bygga ett altare till bränneoffer, och till spisoffer, och annor offer, förutan Herrans vårs Guds altare, som står för hans tabernakel.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
Då nu Pinehas Presten, och de öfverste för menighetene, Israels Förstar, som med honom voro, detta hörde, täcktes dem väl Rubens barnas, Gads, och den halfva Manasse slägts ord.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
Och Pinehas, Prestens Eleazars son, sade till Rubens, Gads, och Manasse barn: I dag förstå vi, att Herren är med oss, att I icke hafven syndat emot Herran med denna gerning; nu hafven I frälst Israels barn utu Herrans hand.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Så drog Pinehas, Prestens Eleazars son, och de öfverste, utu Gileads land, ifrå Rubens och Gads barn, åter in uti Canaans land, till Israels barn, och sade dem det igen.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
Då behagade det Israels barnom väl, och lofvade Israels barnas Gud; och sade intet mer, att de ville draga upp emot dem till slags, till att förderfva landet, som Rubens och Gads barn uti bodde.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Och Rubens och Gads barn kallade det altaret, att det skall vara ett vittne emellan oss, och att Herren är Gud.