< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Тада сазва Исус синове Рувимове и синове Гадове и половину племена Манасијиног,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
И рече им: Ви држасте све што вам је заповедио Мојсије слуга Господњи, и слушасте глас мој у свему што сам вам заповедао.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Не остависте браћу своју дуго времена, до овог дана, и добро чувасте заповест Господа Бога свог.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
А сада Господ је Бог ваш смирио браћу вашу, како им је рекао; сада дакле вратите се и идите у шаторе своје у земљу наследства свог, коју вам је дао Мојсије, слуга Господњи, с оне стране Јордана.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Само пазите добро да вршите заповест и закон, што вам је заповедио Мојсије слуга Господњи, да љубите Господа Бога свог и да ходите свим путевима Његовим, и чувате заповести Његове и држите их се, и да Му служите свим срцем својим и свом душом својом.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
И благослови их Исус, и отпусти их да иду у своје шаторе.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
А половини племена Манасијиног беше дао Мојсије наследство у Васану, а другој половини даде Исус с браћом њиховом, с ове стране Јордана, к западу. И отпуштајући их Исус у шаторе њихове благослови их,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
И рече им говорећи: С великим благом враћате се у шаторе своје, са стоком врло бројном; са сребром и златом и међу и гвожђем и оделом врло многим; поделите плен од непријатеља својих с браћом својом.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
И вративши се синови Рувимови и синови Гадови и половина племена Манасијиног одоше од синова Израиљевих из Силома, који је у земљи хананској, идући у земљу галадску, у земљу наследства свог, коју наследише, како беше Господ заповедио преко Мојсија.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
А кад дођоше на међу јорданску у земљи хананској, начинише синови Рувимови и синови Гадови и половина племена Манасијиног олтар онде на Јордану, олтар велик и наочит.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
И чуше синови Израиљеви где се говори: Гле, синови Рувимови и синови Гадови и половина племена Манасијиног начинише олтар према земљи хананској на међи јорданској, покрај синова Израиљевих.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
А кад чуше синови Израиљеви, скупи се сав збор синова Израиљевих у Силом да иду да се бију с њима.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
И послаше синови Израиљеви к синовима Рувимовим и синовима Гадовим половини племена Манасијиног у земљу галадску Финеса сина Елеазара свештеника,
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
И с њим десет кнезова, по једног кнеза од дома отачког од свих племена Израиљевих, а сваки их беше поглавар у дому отаца својих у хиљадама Израиљевим.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
А они дођоше к синовима Рувимовим и синовима Гадовим и половини племена Манасијиног у земљу галадску, и рекоше им говорећи:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Овако вели сав збор Господњи, какав је то грех којим се огрешисте Богу Израиљевом одвративши се данас од Господа, начинивши олтар да се одметнете данас од Господа?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Мало ли нам је греха Фегорова, од ког се још нисмо очистили до данас и с ког дође погибао на збор Господњи,
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Те се данас одвраћате од Господа, и одмећете се данас од Господа, да се сутра разгневи на сав збор Израиљев?
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Ако је земља наследства вашег нечиста, пређите у земљу наследства Господњег, у којој стоји шатор Господњи, и узмите наследство међу нама; само се не одмећите од Господа и не одмећите се од нас градећи себи олтар мимо олтара Господа Бога нашег.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Није ли се Ахан син Зарин огрешио о ствари проклете, те дође гнев на сав збор Израиљев? И он не погибе сам за грех свој.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
А синови Рувимови и синови Гадови и половина племена Манасијиног одговорише и рекоше поглаварима хиљада Израиљевих:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
Господ Бог над боговима, Господ Бог над боговима, Он зна, и Израиљ нека зна. Ако смо ради одметати се и грешити Господу, нека нас не сачува данас.
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
Ако смо начинили олтар да се одвратимо од Господа или да приносимо на њему жртве паљенице или дарове или да приносимо на њему жртве захвалне, Господ нека тражи.
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
Него то учинисмо бојећи се овог: рекосмо: сутра ће рећи синови ваши синовима нашим говорећи: Шта ви имате с Господом Богом Израиљевим?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Међу је поставио Господ између нас и вас, синови Рувимови и Гадови, Јордан; ви немате део у Господу. Синови ваши ће одбити синове наше да се не боје Господа.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
Зато рекосмо: Учинимо тако, и начинимо олтар, не за жртву паљеницу ни за другу жртву,
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
Него да буде сведок међу нама и вама, и међу наслеђем нашим након нас, да бисмо служили Господу пред Њим жртвама својим паљеницама и приносима својим, и жртвама својим захвалним, и да не би рекли кадгод синови ваши синовима нашим: Ви немате део у Господу.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
Јер рекосмо: Ако кад кажу тако нама или натражју нашем, тада ћемо им казати: Видите слику од олтара Господњег коју начинише оци наши не за жртву паљеницу ни за другу жртву, него да је сведочанство међу нама и вама.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Не дај Боже да се одмећемо Господу и да се данас одвраћамо од Господа начинивши олтар за жртву паљеницу, за дар или за принос, мимо олтара Господа Бога нашег, који је пред шатором Његовим.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
А кад чу Финес свештеник и кнезови од збора, поглавари од хиљада Израиљевих који беху с њим, речи које им рекоше синови Рувимови и синови Гадови и синови Манасијини, би им по вољи.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
И рече Финес син Елеазара свештеника синовима Рувимовим и синовима Гадовим и синовима Манасијиним: Данас познасмо да је међу нама Господ кад се не огрешисте Господу тим грехом, и сачувасте синове Израиљеве од гнева Господњег.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
И Финес син Елеазара свештеника и они кнезови вратише се од синова Рувимових и од синова Гадових из земље галадске у земљу хананску к синовима Израиљевим, и јавише им ствар.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
И би по вољи синовима Израиљевим; и хвалише Бога синови Израиљеви, и не говорише више да иду да се бију с њима да потру земљу, у којој живе синови Рувимови и синови Гадови.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
И прозваше синови Рувимови и синови Гадови онај олтар Ед говорећи: Сведок је међу нама да је Господ Бог.

< Joshua 22 >