< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Então Josué chamou os rubenitas, os gaditas e a meia tribo de Manassés,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
e disse-lhes: “Vocês guardaram tudo o que Moisés, servo de Javé, lhes ordenou, e escutaram minha voz em tudo o que eu lhes ordenei.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Vocês não deixaram seus irmãos até hoje, mas cumpriram o dever do mandamento de Javé, vosso Deus.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Agora Yahweh seu Deus deu descanso a seus irmãos, enquanto falava com eles. Agora, pois, voltai e ide para vossas tendas, para a terra de vossa posse, que Moisés, servo de Javé, vos deu além do Jordão.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Somente tome cuidado para cumprir o mandamento e a lei que Moisés, servo de Javé, lhe ordenou, para amar a Javé seu Deus, para andar em todos os seus caminhos, para guardar seus mandamentos, para se apegar a ele e para servi-lo com todo o seu coração e com toda a sua alma”.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
Então Josué os abençoou e os mandou embora; e eles foram para suas tendas.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Agora para a meia tribo de Manassés Moisés havia dado herança em Basã; mas Josué deu à outra metade entre seus irmãos além do Jordão para o oeste. Além disso, quando Josué os enviou para suas tendas, ele os abençoou,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
e falou com eles, dizendo: “Voltem com muita riqueza para suas tendas, com muito gado, com muita prata, com ouro, com bronze, com ferro, e com muita roupa. Dividam o saque de seus inimigos com seus irmãos”.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
Os filhos de Rubem e os filhos de Gad e a meia tribo de Manassés voltaram, e partiram dos filhos de Israel para fora de Shiloh, que está na terra de Canaã, para irem para a terra de Gilead, para a terra de sua posse, que eles possuíam, de acordo com o mandamento de Yahweh por Moisés.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
Quando chegaram à região próxima ao Jordão, que está na terra de Canaã, os filhos de Rúben e os filhos de Gad e a meia tribo de Manassés construíram ali um altar junto ao Jordão, um grande altar para se olhar.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
Os filhos de Israel ouviram isto: “Eis que os filhos de Rúben e os filhos de Gad e a meia tribo de Manassés construíram um altar ao longo da fronteira da terra de Canaã, na região ao redor do Jordão, no lado que pertence aos filhos de Israel”.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
Quando os filhos de Israel ouviram falar disso, toda a congregação dos filhos de Israel se reuniu em Shiloh, para ir contra eles para a guerra.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
Os filhos de Israel enviaram aos filhos de Rúben, e aos filhos de Gad, e à meia tribo de Manassés, para a terra de Gileade, Finéias, filho de Eleazar, o sacerdote.
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Com ele estavam dez príncipes, um príncipe da casa de seus pais para cada uma das tribos de Israel; e cada um deles era chefe da casa de seus pais entre os milhares de Israel.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Eles vieram aos filhos de Rúben, e aos filhos de Gad, e à meia tribo de Manassés, à terra de Gileade, e falaram com eles, dizendo:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
“Toda a congregação de Javé diz: 'Que transgressão é essa que vocês cometeram contra o Deus de Israel, para se afastarem hoje de seguir a Javé, na medida em que vocês mesmos construíram um altar, para se rebelarem hoje contra Javé?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
A iniquidade de Peor é muito pouca para nós, da qual não nos limpamos até hoje, embora tenha vindo uma praga sobre a congregação de Iavé,
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
que hoje vocês devem se afastar de seguir Iavé? Será, já que hoje vocês se rebelam contra Iavé, que amanhã ele estará zangado com toda a congregação de Israel.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Entretanto, se a terra de sua posse for impura, então passe para a terra da posse de Iavé, na qual habita o tabernáculo de Iavé, e tome posse entre nós; mas não se revolte contra Iavé, nem se revolte contra nós, ao construir um altar que não seja o altar de Iavé nosso Deus.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Achan, o filho de Zerah, não cometeu uma transgressão na coisa devota, e a ira caiu sobre toda a congregação de Israel? Aquele homem não pereceu sozinho em sua iniqüidade'”.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Então os filhos de Rubem e os filhos de Gad e a meia tribo de Manassés responderam, e falaram aos chefes dos milhares de Israel,
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
“O Poderoso, Deus, Javé, o Poderoso, Deus, Javé, ele sabe; e Israel saberá”: se foi em rebelião, ou se em ofensa a Iavé (não nos salve hoje),
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
que construímos um altar para nos afastarmos de seguir Iavé; ou se para oferecer holocausto ou oferta de refeição, ou se para oferecer sacrifícios de ofertas de paz, que o próprio Iavé o exija.
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
“Se não tivermos feito isso por preocupação, e por uma razão, dizendo: “A seu tempo seus filhos poderão falar com nossos filhos, dizendo: “O que você tem a ver com Iavé, o Deus de Israel?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Pois Javé fez do Jordão uma fronteira entre nós e vocês, filhos de Rúben e filhos de Gad. Vocês não têm parte em Yahweh”. Assim seus filhos podem fazer com que nossos filhos deixem de temer a Iavé”.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
“Portanto, dissemos: 'Vamos agora nos preparar para construir um altar, não para holocausto, nem para sacrifício;
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
mas será uma testemunha entre nós e você, e entre nossas gerações depois de nós, para que possamos realizar o serviço de Iavé diante dele com nossas ofertas queimadas, com nossos sacrifícios, e com nossas ofertas de paz;' para que seus filhos não digam a nossos filhos no futuro, 'Você não tem parte em Iavé'.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
“Por isso dissemos: “Será, quando nos disserem a nós ou a nossas gerações no futuro, que diremos: “Eis o modelo do altar de Javé, que nossos pais fizeram, não para holocausto, nem para sacrifício; mas é uma testemunha entre nós e vós”.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
“Longe de nós que devemos nos rebelar contra Javé, e hoje nos afastamos de seguir a Javé, para construir um altar para holocausto, para oferta de refeição ou para sacrifício, além do altar de Javé nosso Deus que está diante de seu tabernáculo”!
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
Quando Phinehas, o sacerdote, e os príncipes da congregação, mesmo os chefes dos milhares de Israel que estavam com ele, ouviram as palavras que os filhos de Rubem e os filhos de Gad e os filhos de Manassés falaram, isso os agradou bem.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
Phinehas, filho de Eleazar, o sacerdote, disse aos filhos de Rúben, aos filhos de Gad e aos filhos de Manassés: “Hoje sabemos que Javé está entre nós, porque vocês não cometeram esta transgressão contra Javé. Agora vocês livraram os filhos de Israel das mãos de Iavé”.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Phinehas, filho de Eleazar, o sacerdote, e os príncipes, voltaram dos filhos de Rúben, e dos filhos de Gad, da terra de Gilead, para a terra de Canaã, para os filhos de Israel, e trouxeram-lhes notícias novamente.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
Isto agradou aos filhos de Israel; e os filhos de Israel abençoaram a Deus, e não falaram mais em ir contra eles para a guerra, para destruir a terra em que os filhos de Rúben e os filhos de Gad viviam.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Os filhos de Rúben e os filhos de Gad chamaram o altar de “Uma testemunha entre nós de que Yahweh é Deus”.

< Joshua 22 >