< Joshua 22 >
1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Tedy przyzwał Jozue Rubenitów i Gadytów, i połowę pokolenia Manasesowego,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
I rzekł do nich: Wyście strzegli wszystkiego, co wam rozkazał Mojżesz, sługa Pański, i byliście posłuszni głosowi memu we wszystkiem, com wam rozkazał.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Nie opuściliście braci waszej przez długi czas aż do dnia tego; aleście strzegli pilnie rozkazania Pana, Boga waszego.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
A teraz, ponieważ odpoczynek dał Pan, Bóg wasz, braciom waszym, jako im był obiecał, przetoż teraz wróćcie się, a idźcie do przybytków waszych i do ziemi osiadłości waszej, którą wam dał Mojżesz sługa Pański, przed Jordanem.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Tylko strzeżcie pilnie, abyście zachowali przykazanie, i Zakon, który wam rozkazał Mojżesz, sługa Pański: abyście miłowali Pana Boga waszego, a chodzili wszystkiemi drogami jego, chowając rozkazania jego, dzierżąc się go i służąc mu ze wszystkiego serca waszego, i ze wszystkiej duszy waszej.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
I błogosławił im Jozue, a rozpuścił je; i odeszli do przybytków swoich.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Ale połowie pokolenia Manasesowego dał był Mojżesz osiadłość w Basan, a drugiej połowie jego dał Jozue dział z bracią ich z tej strony Jordanu na zachód słońca; a gdy je rozpuszczał Jozue do przybytku ich, błogosławił im.
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
I rzekł do nich, mówiąc: Z wielkiemi bogactwy wracacie się do przybytków waszych, i z majętnością bardzo wielką, ze srebrem i z złotem, i z miedzią, i z żelazem, i szat bardzo wielą; dzielcież się łupem nieprzyjaciół waszych z bracią swoją.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
Tedy wracając się odeszli synowie Rubenowi, i synowie Gadowi, i połowa pokolenia Manasesowego od synów Izraelskich z Sylo, które jest w ziemi Chananejskiej, aby szli do ziemi Galaad, do ziemi osiadłości swojej, którą dziedzicznie otrzymali według słowa Pańskiego przez Mojżesza.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
I przyszli do granic Jordanu, które były w ziemi Chananejskiej, i zbudowali tam synowie Rubenowi, i synowie Gadowi, i połowa pokolenia Manasesowego ołtarz nad Jordanem, ołtarz wielki na podziw.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
I usłyszeli synowie Izraelscy, iż powiadano: Oto zbudowali synowie Rubenowi, i synowie Gadowi, i połowa pokolenia Manasesowego ołtarz przeciw ziemi Chananejskiej na granicach nad Jordanem, kędy przeszli synowie Izraelscy.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
To gdy usłyszeli synowie Izraelscy, zeszło się wszystko zgromadzenie ich do Sylo, aby się ruszyli przeciwko nim na wojnę.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
I posłali synowie Izraelscy do synów Rubenowych, i do synów Gadowych, i do połowy pokolenia Manasesowego, do ziemi Galaad, Fineesa, syna Eleazara kapłana.
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
A z nim dziesięć książąt, po jednym książęciu z każdego domu ojcowskiego ze wszystkich pokoleń Izraelskich, a każdy książę z tych był przedniejszym w domu ojców swoich, w tysiącach Izraelskich.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Tedy ci przyszli do synów Rubenowych, i do synów Gadowych, i do połowy pokolenia Manasesowego, do ziemi Galaad, i rzekli do nich, mówiąc:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Tak mówi wszystko zgromadzenie Pańskie: Cóż to jest za przestępstwo, któremeście wystąpili przeciwko Bogu Izraelskiemu, żeście się dziś odwrócili od Pana, budując sobie ołtarz, abyście dziś byli przeciwnymi Panu?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Azaż nam mało na złości Fegorowej, od której nie jesteśmy oczyszczeni i po dziś dzień, skąd była pomsta w zgromadzeniu Pańskiem,
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Żeście się dziś odwrócili, żebyście nie szli za Panem? Zaczem stanie się, ponieważeście wy dziś odpornymi Panu, że się on jutro na wszystko zgromadzenie Izraelskie rozgniewa.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
A jeźliż jest nieczysta ziemia osiadłości waszej, przeprowadźcie się do ziemi dziedzictwa Pańskiego, w której przebywa przybytek Pański, i weźmiecie osiadłości w pośrodku nas; tylko Panu nie bądźcie odpornymi, a nie odpadajcie od nas, budując sobie ołtarz oprócz ołtarza Pana, Boga naszego.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Azaż przez Achana, syna Zarego, gdy się dopuścił przestępstwa w rzeczy przeklętej, na wszystko zgromadzenie Izraelskie nie przypadł gniew? a nie on sam jeden umarł dla nieprawości swojej.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Tedy odpowiedzieli synowie Rubenowi, i synowie Gadowi, i połowa pokolenia Manasesowego, a mówili do książąt tysiąców Izraelskich:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
Bóg nad Bogi, Pan, Bóg nad Bogi, Pan, on to wie, i Izrael sam pozna, jeźli się to stało z uporu, albo jeźli z przestępstwa przeciw Panu, niechże nas nie żywi dnia tego.
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
Jeźliżeśmy sobie zbudowali ołtarz, abyśmy się odwrócili od Pana, a jeźliż ku ofiarowaniu na nim całopalenia, i ofiar śniednych, albo ku sprawowaniu na nim ofiar spokojnych, Pan niech to rozezna;
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
Jeźliżeśmy nie raczej obawiając się tej rzeczy, uczynili to, mówiąc: Napotem rzeką synowie wasi synom naszym, mówiąc: Cóż wam do Pana, Boga Izraelskiego?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Oto granicę położył Pan między nami i między wami, synowie Rubenowi i synowie Gadowi, Jordan; nie macie wy działu w Panu, i odwrócą synowie wasi syny nasze od bojaźni Pańskiej.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
Przetośmy rzekli: Uczyńmy tak, a zbudujmy sobie ołtarz, nie dla całopalenia, ani innych ofiar:
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
Ale iżby był świadkiem między nami i między wami, i między potomstwy naszemi po nas, i abyśmy służyli Panu przed obliczem jego w całopaleniach naszych, i w śniednych ofiarach naszych, i w spokojnych ofiarach naszych, a iżby nie rzekli synowie wasi napotem synom naszym: Nie macie cząstki w Panu.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
Nadtośmy rzekli: Gdyby napotem rzekli nam, albo potomstwu naszemu, tedy rzeczemy: Patrzajcie na podobieństwo ołtarza Pańskiego, który uczynili ojcowie nasi, nie dla całopalenia, ani innych ofiar, ale żeby on był świadkiem między nami i między wami.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Boże nas uchowaj, żebyśmy mieli przeciwnymi być Panu, a odstąpić dziś od Pana, zbudowawszy ołtarz dla całopalonych, dla śniednych i dla innych ofiar, oprócz ołtarza Pana, Boga naszego, który jest przed przybytkiem jego.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
A usłyszawszy Finees kapłan, i książęta zgromadzenia, i przełożeni nad tysiącmi Izraelskimi, którzy z nim byli, słowa, które mówili synowie Rubenowi, i synowie Gadowi, i synowie Manasesowi, podobało się im to.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
I rzekł Finees, syn Eleazara kapłana, do synów Rubenowych i do synów Gadowych i do synów Manasesowych: Dzisiajśmy poznali, iż w pośrodku nas jest Pan, iżeście się nie dopuścili przeciw Panu przestępstwa tego, i wyswobodziliście syny Izraelskie z ręki Pańskiej.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
A tak wrócili się Finees, syn Eleazara kapłana, z onymi książęty od synów Rubenowych i do synów Gadowych z ziemi Galaad do ziemi Chananejskiej do synów Izraelskich, i odnieśli im tę rzecz.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
I podobało się to synom Izraelskim; a błogosławili Boga synowie Izraelscy, i nie mówili więcej, żeby mieli iść przeciwko nim na wojnę, i wytracić ziemię, w której synowie Rubenowi i synowie Gadowi mieszkali.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Przezwali tedy synowie Rubenowi i synowie Gadowi ołtarz on Ed, mówiąc: Świadkiem będzie między nami, że Pan jest Bogiem.