< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Ningĩ Joshua agĩĩta andũ a Mũhĩrĩga wa Rubeni, na wa Gadi. na nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
akĩmeera atĩrĩ, “Nĩmwĩkĩte maũndũ marĩa mothe Musa ndungata ya Jehova aamwathire, na nĩmũnjathĩkĩire maũndũ-inĩ mothe marĩa ndĩmwathĩte.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Matukũ macio mothe mathirĩte o nginya ũmũthĩ-rĩ, mũtirĩ mwatiganĩria ariũ a thoguo, no nĩmũrutĩte wĩra ũrĩa Jehova Ngai wanyu aamũheire.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Na rĩrĩ, kuona atĩ Jehova nĩaheete ariũ a thoguo ũhurũko o ta ũrĩa eeranĩire-rĩ, cookai mũthiĩ mĩciĩ kwanyu bũrũri-inĩ ũrĩa Musa ndungata ya Jehova aamũheire mũrĩmo ũũrĩa ũngĩ wa Rũũĩ rwa Jorodani.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
No rĩrĩ, menyerera mũno mũtikanaage kũhingia maathani na watho ũrĩa Musa ndungata ya Jehova aamũheire; akĩmwĩra mwendage Jehova Ngai wanyu, na mũrũmagie njĩra ciake ciothe, na mwathĩkagĩre maathani make, na mũtũũre mwĩgwatanĩtie nake, na mũmũtungatagĩre na ngoro cianyu ciothe na mĩoyo yanyu yothe.”
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
Nake Joshua akĩmarathima, akĩmeera mathiĩ, nao magĩthiĩ, makĩinũka kwao mĩciĩ.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
(Musa nĩaheete nuthu ĩmwe ya mũhĩrĩga wa Manase gĩthaka kũu Bashani, nayo nuthu ĩyo ĩngĩ ya mũhĩrĩga ũcio Joshua akĩmĩhe gĩthaka mwena wa ithũĩro wa Rũũĩ rwa Jorodani hamwe na ariũ a ithe wao.) Rĩrĩa Joshua aameerire mainũke-rĩ, nĩamarathimire,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
akĩmeera atĩrĩ, “Cookai mĩciĩ kwanyu hamwe na ũtonga wanyu mũnene, wa mahiũ maingĩ, na betha, na thahabu, na icango, na igera, na nguo nyingĩ mũno cia kwĩhumba, na mũthiĩ mũgayane indo icio mũtahĩte kuuma kũrĩ thũ cianyu na ariũ a ithe wanyu.”
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
Nĩ ũndũ ũcio mũhĩrĩga wa Rubeni, na wa Gadi, na nuthu ya Manase magĩtiga andũ a Isiraeli Shilo kũu Kaanani nĩguo macooke Gileadi, bũrũri wao kĩũmbe, ũrĩa meegwatĩire naguo o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
Rĩrĩa maakinyire Gelilothu gũkuhĩ na Rũũĩ rwa Jorodani kũu bũrũri wa Kaanani-rĩ, mũhĩrĩga wa Rubeni, na wa Gadi, na nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase nĩmakire kĩgongona kĩnene biũ o kũu hũgũrũrũ-inĩ cia Rũũĩ rwa Jorodani.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
Na rĩrĩa andũ a Isiraeli maaiguire atĩ nĩmakĩte kĩgongona kĩu mũhaka-inĩ wa Kaanani kũu Gelilothu gũkuhĩ na Rũũĩ rwa Jorodani mwena wa andũ a Isiraeli-rĩ,
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
kĩungano gĩothe gĩa Isiraeli gĩkĩũngana Shilo nĩguo gĩkarũe nao.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli magĩtũma Finehasi mũrũ wa Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai athiĩ bũrũri wa Gileadi; athiĩ kũrĩ mũhĩrĩga wa Rubeni, na wa Gadi na nuthu ya Manase.
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
O hamwe nake, magĩtũma atongoria ikũmi o mũtongoria ũmwe akarũgamĩrĩra mũhĩrĩga o mũndũ ũmwe wa Isiraeli, o ũmwe wao nĩwe warĩ mũnene wa nyũmba ya ithe thĩinĩ wa mbarĩ cia andũ a Isiraeli.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Rĩrĩa maathiire Gileadi, magĩthiĩ kũrĩ mũhĩrĩga wa Rubeni, na Gadi, na nuthu ya Manase, makĩmeera atĩrĩ,
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
“Kĩũngano gĩothe kĩa Jehova gĩkũmũũria atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte mwage kwĩhokeka harĩ Ngai wa Isiraeli? Mwahota atĩa kũhutatĩra Jehova mũkeyakĩra kĩgongona nĩguo mũũkĩrĩre Jehova mũmũremere?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Mehia marĩa meekĩirwo Peori matitũiganĩte? Nginya ũmũthĩ ũyũ tũtirĩ twetheria mehia macio, o na gũtuĩka mũthiro nĩwokire igũrũ rĩa kĩrĩndĩ kĩa Jehova!
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Rĩu na inyuĩ nĩ Jehova mũrahutatĩra? “‘Mũngĩremera Jehova ũmũthĩ, rũciũ nake nĩakarakarĩra kĩrĩndĩ gĩothe gĩa Isiraeli.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Angĩkorwo bũrũri ũrĩa mwĩgwatĩire nĩmũthaahu-rĩ, ringai mũũke bũrũri wa Jehova, kũrĩa hema ya Jehova ĩrĩ, mũgayane bũrũri na ithuĩ. No rĩrĩ, mũtikaremere Jehova kana mũtũremere na ũndũ wa kwĩyakĩra kĩgongona kĩanyu inyuĩ ene, o tiga kĩgongona kĩrĩa kĩrĩ kĩa Jehova Ngai witũ.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Rĩrĩa Akani mũrũ wa Zera aagire kwĩhokeka maũndũ-inĩ makoniĩ indo iria ciamũrĩtwo cia kũniinwo-rĩ, githĩ mangʼũrĩ matiakinyĩrĩire kĩrĩndĩ gĩothe gĩa Isiraeli? Mũndũ ũcio to we wiki wakuire nĩ ũndũ wa mehia make.’”
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Hĩndĩ ĩyo andũ a Rubeni, na a Gadi, na a nuthu ya Manase magĩcookeria anene a mbarĩ cia Isiraeli makĩmeera atĩrĩ:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
“Jehova, Ngai, Mwene-Hinya, o we Jehova! Jehova, Ngai, Mwene-Hinya, o we Jehova! Nĩwe ũũĩ! Narĩo Isiraeli nĩrĩmenye! Angĩkorwo ũndũ ũyũ nĩ wa ũremi o na kana kwaga gwathĩkĩra Jehova, mũtigatũtigie muoyo ũmũthĩ.
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
Angĩkorwo nĩtwakĩte kĩgongona giitũ ithuĩ ene nĩguo tũhutatĩre Jehova, na tũrutage maruta ma njino na ma mũtu, o na kana tũkarutagĩra igongona rĩa ũiguano igũrũ rĩakĩo-rĩ, Jehova aroĩyũrĩria gĩtũmi kĩa ũhoro ũcio harĩ ithuĩ.
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
“Aca! Ithuĩ twekire ũguo nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra atĩ mũthenya ũmwe njiaro cianyu ciahota gũkeera ciitũ atĩrĩ, ‘Inyuĩ nĩ ũhoro ũrĩkũ mũrĩ naguo na Jehova Ngai wa Isiraeli?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Jehova nĩekĩrĩte mũhaka wa Rũũĩ rwa Jorodani ũtuĩke wa gũtũhakania ithuĩ na inyuĩ, na andũ aya a Rubeni na Gadi! Gũtirĩ ũndũ mwĩtainwo na Jehova.’ Nĩ ũndũ ũcio njiaro cianyu ciahota gũtũma ciitũ itige gũcooka gwĩtigĩra Jehova.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
“Kĩu nĩkĩo gĩatũmire tuuge atĩrĩ, ‘Nĩtwĩhaarĩrie twĩakĩre kĩgongona, no ti kĩa maruta ma njino o na kana magongona mangĩ.’
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
No rĩrĩ, nĩ gĩtuĩke ũira gatagatĩ gaitũ na inyuĩ na njiarwa iria igooka, atĩ tũrĩhooyagĩra Jehova hema-inĩ yake tũrĩ na maruta maitũ ma njino, na magongona na maruta ma ũiguano. Ningĩ matukũ ma thuutha njiaro cianyu itikeera njiaro ciitũ atĩrĩ, ‘Mũtirĩ na igai harĩ Jehova.’
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
“Na ithuĩ tũkiuga atĩrĩ, ‘Mangĩgaatwĩra ũguo, o na kana meere njiaro ciitũ ũguo-rĩ, nĩtũkamacookeria, tũmeere atĩrĩ: Ta rorai muone mũhianĩre wa kĩgongona kĩa Jehova, kĩrĩa maithe maitũ maakire, gĩtiakirwo nĩ ũndũ wa maruta ma njino na magongona mangĩ, no gĩakirwo nĩguo gĩtuĩke ũira gatagatĩ gaitũ na inyuĩ.’
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
“Kũroaga gũtuĩka ũguo, atĩ no tũremere Jehova tũmũhutatĩre ũmũthĩ na ũndũ wa gwaka kĩgongona kĩngĩ gĩa keerĩ gĩa kũrutĩra maruta ma njino, na maruta ma mũtu na magongona mangĩ, tiga o kĩgongona kĩa Jehova Ngai witũ kĩrĩa gĩakĩtwo hema-inĩ yake.”
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
Rĩrĩa Finehasi, mũthĩnjĩri-Ngai hamwe na atongoria a kĩrĩndĩ, o acio atongoria a mbarĩ cia andũ a Isiraeli maaiguire ũrĩa Rubeni, na Gadi, na Manase moigire-rĩ, magĩkena.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
Nake Finehasi mũrũ wa Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai akĩĩra Rubeni, na Gadi, na Manase atĩrĩ, “Ũmũthĩ nĩtwamenya atĩ Jehova arĩ hamwe na ithuĩ, tondũ mũtihĩtĩirie Jehova ũndũ-inĩ ũyũ. Rĩu nĩmũteithũkĩtie andũ a Isiraeli kuuma guoko-inĩ kwa Jehova.”
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Nake Finehasi mũrũ wa Eleazaru, ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, hamwe na atongoria magĩcooka Kaanani thuutha wa gũcemania na andũ a Rubeni na Gadi kũu Gileadi, nao magĩcookeria andũ a Isiraeli ũhoro.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
Nĩmakenire nĩ kũigua ũhoro ũcio, na makĩgooca Ngai. Na matiigana gũcooka kwaria ũhoro wa kũrũa nao atĩ nĩguo maharaganie bũrũri ũrĩa andũ a Rubeni na Gadi matũũraga.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Nao andũ a Rubeni na Gadi magĩĩta kĩgongona kĩu ũũ: Mũira Gatagatĩ Gaitũ atĩ Jehova nĩwe Ngai.

< Joshua 22 >