< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Alors Josué manda les Rubénites, les Gadites et la demi-Tribu de Manassé,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
et il leur dit: Vous avez observé tout ce que vous a prescrit Moïse, serviteur de l'Éternel, et obéi à ma voix dans tout ce que je vous ai commandé.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Vous n'avez point abandonné vos frères pendant ce long temps jusqu'aujourd'hui, et vous avez observé ce qu'il fallait observer, le commandement de l'Éternel, votre Dieu.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Et maintenant l'Éternel, votre Dieu, a accordé le repos à vos frères, comme Il le leur avait promis; retournez donc et gagnez vos tentes, le pays qui est votre propriété, que vous a concédé Moïse, serviteur de l'Éternel, au delà du Jourdain.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Seulement soyez très vigilants à mettre en pratique le commandement et la Loi que vous a prescrite Moïse, serviteur de l'Éternel, pour aimer l'Éternel, votre Dieu, et pour marcher dans toutes ses voies et garder ses commandements et vous attacher à Lui et Le servir de tout votre cœur et de toute votre âme.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
Et Josué les bénit et les congédia, et ils regagnèrent leurs tentes.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Or Moïse avait doté une moitié de la Tribu de Manassé en Basan, et Josué avait doté l'autre moitié avec leurs frères en deçà du Jourdain à l'occident. Et aussi lorsque Josué leur permit de regagner leurs tentes, il les bénit
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
et leur parla en ces termes: C'est avec de grandes richesses que vous retournez à vos tentes, et avec des bestiaux très nombreux, avec de l'argent et de l'or et de l'airain et du fer et des vêtements en très grande quantité. Partagez le butin de vos ennemis avec vos frères.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
Ainsi s'en retournèrent et partirent les fils de Ruben et les fils de Gad et une moitié de la Tribu de Manassé, d'avec les enfants d'Israël, de Silo dans le pays de Canaan, pour gagner le pays de Galaad, le pays qui était leur propriété, dont ils avaient pris possession sur l'ordre de l'Éternel, transmis par Moïse.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
Et étant arrivés aux districts du Jourdain dans le pays de Canaan, les fils de Ruben et les fils de Gad et la demi-Tribu de Manassé, bâtirent là un autel sur le Jourdain, autel d'une grande apparence.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
Et les enfants d'Israël ouïrent dire: Voilà que les fils de Ruben et les fils de Gad et de la demi-Tribu de Manassé ont bâti l'autel en vue du pays de Canaan, dans les districts du Jourdain en face des enfants d'Israël.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
Et les enfants d'Israël l'ayant appris, toute l'Assemblée des enfants d'Israël se réunit à Silo pour se mettre en campagne contre eux.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
Et les enfants d'Israël députèrent vers les fils de Ruben et les fils de Gad et la demi-Tribu de Manassé au pays de Galaad, Phinées, fils du Prêtre Eléazar,
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
et dix Princes avec lui, un Prince par maison de toutes les Tribus d'Israël, et ils étaient chacun chefs de leurs maisons patriarcales des divisions d'Israël.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Et ils se rendirent auprès des fils de Ruben et des fils de Gad et de la demi-Tribu de Manassé au pays de Galaad, et ils leur parlèrent en ces termes:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Ainsi dit toute l'Assemblée de l'Éternel: Qu'est-ce que ce crime dont vous vous rendez coupables envers le Dieu d'Israël, pour vous détourner aujourd'hui de l'Éternel en vous bâtissant un autel pour vous rebeller aujourd'hui contre l'Éternel?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Est-ce trop peu pour nous que la faute de Pehor dont nous ne sommes pas purifiés jusqu'à ce jour et qui a attiré la plaie sur l'Assemblée de l'Éternel?
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Et vous, vous vous détournez aujourd'hui de l'Éternel! mais si vous vous rebellez aujourd'hui contre l'Éternel, demain Il se courroucera contre toute l'Assemblée d'Israël.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Cependant si le pays qui est votre lot, est impur, passez dans le pays qui est la propriété de l'Éternel où est fixée la Résidence de l'Éternel et prenez possession au milieu de nous; mais ne vous rebellez pas contre l'Éternel, et ne faites pas défection d'avec nous en vous bâtissant un autel en dehors de l'Autel de l'Éternel, notre Dieu.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Hacan, fils de Zérah, ne s'est-il pas rendu coupable de crime en touchant aux choses dévouées? et une vengeance fondit sur toute l'Assemblée d'Israël; et il n'a pas été le seul à périr en suite de sa faute.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Alors les fils de Ruben et les fils de Gad et la demi-Tribu de Manassé répondirent et dirent aux Chefs des divisions d'Israël:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
Dieu, Dieu, l'Éternel, Dieu, Dieu, l'Éternel sait, et Israël doit savoir si c'est par une rébellion, par un crime contre l'Éternel (ne nous donne pas Ton aide en ce jour!)
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
que nous nous sommes bâti un autel, pour nous détourner de l'Éternel; et si c'est pour y offrir des holocaustes et des offrandes, et si c'est pour y faire des sacrifices pacifiques, que l'Éternel nous recherche!
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
et si ce n'est pas par un souci, par une raison que nous l'avons fait en disant: A l'avenir vos fils diront à nos fils: « Qu'avez-vous de commun avec l'Éternel, Dieu d'Israël?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Aussi bien l'Éternel a mis entre nous et vous, fils de Ruben et fils de Gad, pour limite le Jourdain: vous n'avez point part à l'Éternel. » Et ainsi vos fils empêcheront nos fils de craindre l'Éternel.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
C'est pourquoi nous avons dit: Mettons-nous donc à bâtir un autel, non point pour holocaustes et victimes,
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
mais afin qu'il soit un témoin entre nous et vos fils, et nos descendants après nous, que nous pratiquons le culte de l'Éternel devant Lui avec nos holocaustes et nos victimes et nos sacrifices pacifiques, pour que dans l'avenir vos fils ne disent pas à nos fils: « Vous n'avez point part à l'Éternel! »
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
Et nous dîmes: Dans le cas où ils tiendraient ce langage à nous ou à nos descendants dans l'avenir, nous répondrons: Voyez la structure de l'autel de l'Éternel qu'ont fait nos pères, non point pour y offrir des holocaustes et des victimes, mais il est un témoin entre nous et vous.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Loin de nous la pensée de nous rebeller contre l'Éternel, et de nous détourner aujourd'hui de l'Éternel en bâtissant un autel pour holocaustes, offrandes et victimes, en dehors de l'Autel de l'Éternel, notre Dieu, qui est devant sa Résidence!
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
Et lorsque le Prêtre Phinées et les Princes de l'Assemblée et les Chefs des divisions d'Israël qui l'accompagnaient, eurent entendu les paroles que prononcèrent les fils de Ruben et les fils de Gad et les fils de Manassé, ils furent satisfaits.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
Et Phinées, fils du Prêtre Eléazar, dit aux fils de Ruben et aux fils de Gad et aux fils de Manassé: Aujourd'hui nous reconnaissons que l'Éternel est au milieu de nous, puisque vous ne vous êtes pas rendus coupables envers l'Éternel d'un tel crime. Maintenant vous avez sauvé les enfants d'Israël de la main de l'Éternel.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Alors Phinées, fils du Prêtre Eléazar, et les Princes quittant les fils de Ruben et les fils de Gad, revinrent du pays de Galaad dans le pays de Canaan auprès des enfants d'Israël, et ils leur rendirent compte.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
Et les enfants d'Israël furent satisfaits, et les enfants d'Israël bénirent Dieu et ils ne parlèrent plus de marcher contre eux pour ravager le pays qu'habitaient les fils de Ruben et les fils de Gad.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Et les fils de Ruben et les fils de Gad donnèrent à l'autel ce nom: « Car il est témoin entre nous que l'Éternel est Dieu. »

< Joshua 22 >