< Joshua 22 >
1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
In the same tyme Josue clepide men of Ruben, and men of Gad, and half the lynage of Manasses,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
and seide to hem, Ye han do alle thingis whiche Moises, `seruaunt of the Lord, comaundide to you, also ye obeieden to me in alle thingis;
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
nether ye han lefte youre britheren in mych tyme til in to present dai, and ye kepten the comaundement of youre Lord God.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Therfor for youre Lord God yaf reste and pees to youre britheren, as he bihiyte, turne ye ayen, and go ye in to youre tabernaclis, and in to the loond of youre possessioun, which lond Moyses, the `seruaunt of the Lord, yaf to you biyende Jordan;
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
so onely that ye kepe bisili, and fille in werk the comaundement and lawe, `which lawe Moises, the `seruaunt of the Lord, comaundide to you; that ye loue youre Lord God, and go in alle hise weies, and kepe hise heestis, and cleue to hym and serue him in al youre herte, and in al youre soule.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
And Josue blesside hem, and lefte hem, whiche turneden ayen in to her tabernaclis.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Sotheli Moyses hadde youe possessioun in Basan to the half lynage of Manasses; and therfor to the half lynage that lefte Josue yaf part among her othere britheren biyendis Jordan, at the west coost therof. And whanne Josue leet hem go in to her tabernaclis, and hadde blessid hem,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
he seyde to hem, With myche catel and richessis turne ye ayen to youre seetis; with siluer and gold, and bras, and yrun, and myche clothing; departe ye the prey of enemyes with youre britheren.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
And the sones of Ruben, and the sones of Gad, and `half the lynage of Manasses turneden ayen, and yeden fro the sones of Israel fro Silo, which is set in the lond of Canaan, that thei schulden entre in to Galaad, the lond of her possessioun, which thei gaten bi `comaundement of the Lord in the hond of Moises.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
And whanne thei hadden come to the litle hillis of Jordan, in to the lond of Canaan, thei bildiden bisidis Jordan an auter of greetnesse ouer comyn mesure.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
And whanne the sones of Israel hadden herd this, and certeyn messangeris hadden teld to hem, that the sones of Ruben, and of Gad, and the half lynage of Manasses hadden bildid an auter in the lond of Canaan, on the heepis of Jordan, ayens the sones of Israel,
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
alle camen togidir in Silo, that thei schulden stie, and fiyte ayens hem.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
And in the meene tyme thei senten to hem in to the lond of Galaad, Fynees, preest,
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
the sone of Eleazar, and ten princes with hym; of ech lynage o prince.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Whiche camen to the sones of Ruben, and of Gad, and of the half lynage of Manasses, in to the lond of Galaad, and seiden to hem,
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Al the puple of the Lord sendith these thingis; What is this trespassyng? Whi han ye forsake the Lord God of Israel, and han bildid a cursid auter, and han go awei fro the worschiping of hym?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Whether it is litil to you that ye synneden in Belfegor, and the wem of this trespas dwellith in you til in to present dai, and many of the puple felden doun?
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
And to day ye han forsake the Lord, and to morewe, that is, in tyme to comynge, the ire of hym schal be feers ayens al Israel.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
That if ye gessen, that the lond of youre possessioun is vncleene, passe to the lond, `in which the tabernacle of the Lord is, and dwelle ye among vs, oneli that ye go not awei fro the Lord, and fro oure felouschipe, bi an auter bildid outakun the auter of oure Lord God.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Whether not Achar, the sone of Zare, passide the comaundement of the Lord, and his ire felde on al the puple of Israel? And he was o man; and we wolden that he aloone hadde perischid in his trespas.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
And the sones of Ruben, and of Gad, and of half the lynage of Manasses, answeriden to the princes of the message of Israel,
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
The strongeste Lord God hym silf of Israel knowith, and Israel schal vndirstonde togidere; if we bildiden this auter for entent of trespassyng, `that is, of ydolatrye, he kepe not vs, but punysche in present time;
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
and if we diden bi that mynde, that we schulden putte theronne brent sacrifice, and sacrifice, and pesible sacrifices, he seke, and deme;
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
and not more `bi that thouyt and tretyng that we seiden, Youre sones schulen seie `to morew to oure sones, What is to you and to the Lord God of Israel? Ye sones of Ruben,
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
and ye sones of Gad, the Lord hath set a terme, the flood Jordan, bitwixe vs and you; and therfor ye han not part in the Lord; and bi this occasioun youre sones schulen turne awei oure sones fro the drede of the Lord. Therfor we gessiden betere,
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
and seiden, Bilde we an auter to vs, not in to brent sacrifices, nethir to sacrifices to be offrid,
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
but in to witnessyng bitwixe vs and you, and bitwixe oure children and youre generacioun, that we serue the Lord, and that it be of oure riyt to offre brent sacrifices, and sacrifices, and pesible sacrifices; and that youre sones seie not to morewe to oure sones, No part in the Lord is to you.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
And if `youre sones wolen seie this, `oure sones schulen answere hem, Lo! the auter of the Lord, which oure fadris maden, not in to brent sacrifices, nether in to sacrifice, but in to oure and your witnessing euerlastinge.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Fer be this trespas fro vs, that we go awei fro the Lord, and forsake hise steppis, bi an auter bildid to brent sacrifices, and sacrifices, and sacrifices of preisyng to be offrid, outakun the auter of oure `Lord God, which is bildid bifore his tabernacle.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
And whanne these thingis weren herd, Fynees, preest, and the princes of message of Israel, that weren with hym, weren plesyd; and thei resseyueden gladli the wordis of the sones of Ruben, and of Gad, and of the half lynage of Manasses.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
And Finees, preest, the sone of Eleazar, seide to hem, Now we wyten, that the Lord is with you; for ye ben alien fro this trespassyng, and ye han delyuered the sones of Israel fro the hond, `that is, punyschyng, of the Lord.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
And Fynees turnede ayen with the princes fro the sones of Ruben and of Gad, fro the lond of Galaad to the coost of Canaan, to the sones of Israel; and he telde to hem.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
And the word pleside to alle men herynge; and the sones of Israel preisiden God, and seiden, that no more `thei schulden stie ayens hem, and fiyte, and do awei the lond of her possessioun.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
And the sones of Ruben and the sones of Gad clepiden the auter, which thei hadden bildid, Oure Witnessyng, that the Lord hym silf is God.