< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Then, called Joshua—for the Reubenites, and for the Gadites, —and for the half tribe of Manasseh;
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
and said unto them, Ye, have observed all that Moses the servant of Yahweh commanded you, —and have hearkened unto my voice, in all that I commanded you:
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
ye have not forsaken your brethren, these many days, unto this day, —but have kept the charge of the commandment of Yahweh your God.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Now, therefore, that Yahweh your God hath given rest unto your brethren, according as he spake unto them, —now, therefore, turn ye and get you to your homes within the land of your possession, which Moses the servant of Yahweh gave unto you, over the Jordan.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Only, take ye diligent heed, to do the commandment and the law, which Moses the servant of Yahweh commanded you—to love Yahweh your God, and to walk in all his ways, and to keep his commandments, and to cleave unto him, —and to serve him—with all your heart, and with all your soul.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
So Joshua blessed them, —and sent them away, and they took their journey unto their homes.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Now, unto the [one] half tribe of Manesseh, had Moses given a possession in Bashan, and, unto the [other] half, did Joshua give possession with their brethren, over the Jordan, westward, —moreover also, when Joshua sent them away unto their homes, he blessed them,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
and spake unto them, saying—With much wealth, return ye unto your homes, even with very much cattle, with silver and with gold, and with copper and with iron, and with very much raiment, —divide ye the spoil of your enemies with your brethren.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
So the sons of Reuben and the sons of Gad and the half tribe of Manasseh. returned and departed from the sons of Israel, from Shiloh, which was in the land of Canaan, —to go unto the land of Gilead, unto the land of their possession, wherein they had received their possessions, at the bidding of Yahweh by the hand of Moses.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
And, when they came into the circles of the Jordan, which were in the land of Canaan, —then did the sons of Reuben and the sons of Gad and the half tribe of Manasseh build there an altar by the Jordan, an altar of large dimensions,
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
And the sons of Israel heard say, —Lo! the sons of Reuben and the sons of Gad and the half tribe of Manasseh have built an altar in front of the land of Canaan, in the circles of the Jordan, in the region opposite the sons of Israel.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
And, when the sons of Israel heard, all the assembly of the sons of Israel gathered themselves together at Shiloh, to go up against them to war.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
And the sons of Israel sent unto the sons of Reuben and unto the sons of Gad and unto the half tribe of Manasseh, within the land of Gilead, —Phinehas, son of Eleazar the priest;
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
and ten princes with him, one prince of an ancestral house for each of the tribes of Israel, —they being, severally heads of their ancestral houses, among the thousands of Israel.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
So they came in unto the sons of Reuben and unto the sons of Gad and unto the half tribe of Manasseh, within the land of Gilead, —and spake with them, saying:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Thus, say all the assembly of Yahweh—What is this act of treachery which ye have committed against the God of Israel, that ye should turn back, to-day, from following Yahweh, —in that ye have builded you an altar, that ye might rebel, to-day, against Yahweh?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Too little for us, was the iniquity of Peor, from which we have not cleansed ourselves, unto this day, —although the plague came upon the assembly of Yahweh;
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
but that, ye, must turn back to-day from following Yahweh, —though it must needs be that, if, ye, rebel to-day against Yahweh, then, to-morrow, with all the assembly of Israel, will he be wroth?
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Howbeit, if, unclean, be the land of your possession, do ye on your part come over into the land of the possession of Yahweh, where abideth the habitation of Yahweh, and take your possession in our midst, —but, against Yahweh, do not rebel, nor, against us, rebel, by building yourselves an altar apart from the altar of Yahweh our God.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Did not, Achan son of Zerah, commit an act of treachery, with a devoted thing, and, upon all the assembly of Israel, came wrath, —so that not, he—one man alone, died in his iniquity.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Then responded the sons of Reuben and the sons of Gad and the half tribe of Manasseh, —and spake unto the heads of the thousands of Israel:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
El-Elohim-Yahweh, El-Elohim-Yahweh, he knoweth, and, Israel, he, shall know, —if in rebellion, or if in treachery, against Yahweh, do not save us this day:
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
that we should build for ourselves an altar, to turn back from following Yahweh, —or, if that we might cause to go up thereon ascending-sacrifice or meal-offering, or if that we might offer thereon peace-offerings, let Yahweh himself require it;
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
if, indeed, we have not, rather, out of anxiety and of purpose, done this thing, saying, —. In time to come, your sons might speak to our sons, saying, What have ye to do with Yahweh, God of Israel;
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
seeing that, a boundary, hath Yahweh put between us and you, ye sons of Reuben and ye sons of Gad—even the Jordan, ye have no portion in Yahweh, —so might your sons cause our sons, to cease from revering Yahweh.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
We said, therefore, Let us prepare, we pray you, to build us an altar, —not for ascending-offering, nor for sacrifice;
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
but that, a witness, it may be between us and you, and between our generations after us, that we are to do the service of Yahweh, before him, with our ascending-offerings and with our sacrifices, and with our peace-offerings, —that your sons may not say, in time to come, to our sons, Ye have no portion in Yahweh.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
Therefore said we, And it shall be, when they [so] say to us, or to our generations, in time to come, —that we will say—Behold ye the pattern of the altar of Yahweh, which our fathers made, not for ascending-offerings nor for sacrifice, but that, a witness, it might be between us and you.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Far be it from us—that we should rebel against Yahweh, or turn back, to-day, from following Yahweh, by building an altar, for ascending-offering, or meal-offering or for sacrifice, —other than the altar of Yahweh our God, which is before his habitation.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
And, when Phinehas the priest, and the princes of the assembly, even the heads of the thousands of Israel who were with him, heard the words which the sons of Reuben and the sons of Gad and the sons of Manasseh spake, then was it well-pleasing in their eyes.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
And Phinehas son of Eleazar the priest said unto the sons of Reuben and unto the sons of Gad and unto the sons of Manasseh—To-day, we know that, in our midst, is Yahweh, in that ye have not committed, against Yahweh, this act of treachery, —now, have ye rescued the sons of Israel out of the hand of Yahweh.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
So Phinehas son of Eleazar the priest and the princes returned from the sons of Reuben and from the sons of Gad, out of the land of Gilead, unto the land of Canaan, unto the sons of Israel, —and brought them back word.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
And the thing was well-pleasing in the eyes of the sons of Israel, and the sons of Israel blessed God, —and spake not of going up against them, to war, to lay waste the land, wherein the sons of Reuben and the sons of Gad dwelt.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
So the sons of Reuben and the sons of Gad named the altar [a Witness]: A witness, it is between us, That, Yahweh, is God.

< Joshua 22 >