< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Joshua loh Reuben koca, Gad koca neh Manasseh koca hlangvang te koep a khue tih,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
“BOEIPA kah sal Moses lohnangmih n'uen te boeih ngaithuen uh lamtah nang kang uen boeih dongah kai ol he hnatun uh.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Tihnin duela kum te yet na manuca rhoek te na hnoo uh pawt dongah BOEIPA na Pathen kah a kuek olpaek te na vai uh coeng.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Te dongah BOEIPA na Pathen loh amih taengah a thui vanbangla na manuca rhoek te a duem sak coeng. Te dongah mael uh lamtah Jordan rhalvangan ah BOEIPA kah sal Moses loh nangmih m'paek na dap, na lo, na khohut te paan uh laeh.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Tedae BOEIPA kah sal Moses loh nangmih ng'uen olpaek neh olkhueng rhep saii ham, BOEIPA na Pathen lungnah ham neh a longpuei cungkuem ah pongpa ham, a olpaek ngaithuen ham neh a taengah rhep hmaiben ham, amah te na thinko boeih, na hinglu boeih neh thothueng ham te khaw ngaithuen uh,” a ti nah.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
Amih te Joshua loh yoethen a paek tih a tueih daengah amamih kah dap te a paan uh.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
Manasseh koca rhakthuem te Moses loh Bashan ah a phaeng coeng tih rhakthuem te tah Joshua loh khotlak Jordan rhalvangan, rhalvangan ah a pacaboeina neh hmaih a phaeng. Joshua loh amih te amamih kah dap la a tueih vaengah khaw amih te yoethen a paek bal.
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
Te vaengah amih te a thui pah tih, “Na dap te koeva neh a yet la boiva muep a yet nen khaw, cak nen khaw, sui nen khaw, rhohum nen khaw, thicung nen khaw, himbai nen khaw paan uh laeh. Na thunkha kah kutbuem muep aka yet te na manuca neh tael uh thae,” a ti nah.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
A mael uh vaengah Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek, Manasseh koca hlangvang loh Kanaan kho Shiloh kah Israel ca taeng lamloh nong uh tih Moses kut kah BOEIPA ol vanbangla khohut hmuen te buem ham, Gilead kho la cet uh.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
Kanaan kho kah Jordan saa te a pha vaengah Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek, Manasseh koca rhakthuem tah Jordan ah hmueihtuk a suem uh. Te hmueihtuk te a mueimae la sang.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
Tedae Israel ca rhoek loh a yaak uh vaengah Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek neh Manasseh koca rhakthuem loh Kanaan kho kah imdan, Jordan saa, Israel ca rhoek kah khongan ah hmueihtuk a suem uh ke,” a ti uh.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
Israel ca rhoek loh a yaak uh vaengah amih te caempuei neh paan thil ham Shiloh kah Israel ca rhaengpuei loh boeih tingtun uh.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
Te phoeiah Israel ca rhoek loh Gilead kho kah Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek, Manasseh koca rhakthuem taengla khosoih Eleazar capa Phinekha te neh,
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Israel koca imkhui boeih kah a napa, Israel ca thawngkhat imkhui kah a lu la aka om a napa rhoek lamkah khoboei khoboei neh khoboei parha te khaw a tueih uh.
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Te dongah Gilead kho la a kun uh vaengah Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek, Manasseh koca rhakthuem te a voek uh.
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
BOEIPA kah hlangboel boeih taengah ah, “Mebang boekoek aih lam lae Israel Pathen taengah boe na koek uh tih tihnin ah BOEIPA hnuk lamkah na balkhong uh van he? Namamih kah hmueihtuk na suem uh neh tihnin ah BOEIPA te na tloelh uh.
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Peor kathaesainah te mamih ham a rhoeh moenih a? Tihnin kah BOEIPA hlangboel dongah tlohthae aka om he n'caihcil mahpawt a?
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Tihnin ah nangmih loh BOEIPA hnuk lamkah na bal uh nama. Tihnin ah BOEIPA na tloelh thil uh he thangvuen ah Israel rheangpuei pum taengah a thintoek bitni.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Na khohut diklai ni a rhalawt oeh atah BOEIPA kah dungtlungim loh a pai thil BOEIPA kah khohut diklai la ha kat uh lamtah kaimih saa dongkah he bawn uh mai saw. Tedae mamih Pathen BOEIPA kah hmueihtuk lakah namamih ham a tloe hmueihtuk na suem uh neh BOEIPA te tloelh thil uh boeh, kaimih khaw n'tloelh uh boeh.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Yaehtaboeih neh boekoeknah la boe aka koek Zerah capa Akhan moenih a? Anih kathaesainah ah a thinhul loh Israel rhaengpuei boeih a tlak thil vaengah amah bueng hlang a pal moenih ko,” a ti uh.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
Te vaengah Israel thawngkhat kah a lu rhoek te Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek neh Manasseh koca rhakthuem loh a doo uh tih,
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
“Pathen rhoek kah Pathen, pathen rhoek kah BOEIPA Pathen, Yahweh loh a ming, Israel long khaw ming saeh. BOEIPA taengah tloelhnah la om oeh tih boekoeknah la a om atah tihnin ah kaimih he n'hlun uh boeh.
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
BOEIPA hnuk lamloh balkhong ham hmueihtuk ka suem uh khaw, a soah khocang hmueihhlutnah ka nawn uh mai cakhaw, a soah rhoepnah hmueih ka nawn uh mai cakhaw BOEIPA amah loh thuep nawn saeh.
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
Tedae olka dongah mawnnah ham a om pawt dongah ka saii he thui sih. Thangvuen ah nangmih ca rhoek loh kaimih ca rhoek taengah a thui vetih, “Nangmih taeng neh Israel Pathen BOEIPA taengah balae a benbonah,” ti saeh.
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
BOEIPA loh kaimih laklo neh nangmih laklo ah rhi a suem coeng. Reuben koca neh Gad koca, BOEIPA dongah Jordan te nangmih kah khoyo moenih. Te dongah nangmih koca loh BOEIPA aka rhih pawh kaimih ca rhoek te kangkuen sak saeh.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
Te dongah, “Hmueihtuk te sak ham mamih loh saii pawn sih, hmueihhlutnah ham moenih, hmueih ham moenih,” ka ti uh.
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
Te tah kaimih laklo neh nangmih laklo ah, mamih hnukkah mamih cadilcahma laklo ah laipai la om saeh. BOEIPA kah thothuengnah te a mikhmuh ah mamih kah hmueihhlutnah neh, mamih kah hmueih neh, mamih kah rhoepnah neh thothueng sih. Te daengah ni thangvuen ah na ca rhoek loh kaimih ca rhoek taengah, “BOEIPA dongah khoyo te nangmih ham moenih,” a ti uh pawt eh.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
Thangvuen ah kaimih taeng neh n'cadilcahma rhoek taengah a thui uh atah te te ana om mai saeh ka ti uh. Te vaengah, “A pa rhoek loh BOEIPA kah hmueihtuk muei a saii uh te hmueihhlutnah ham pawt tih hmueih ham bal moenih, tedae kaimih laklo neh nangmih laklo kah laipai ni tila hmuh uh,’ ka ti uh bitni.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
BOEIPA te tloelh ham neh tihnin ah BOEIPA hnuk lamloh taengphael ham, a dungtlungim hmaikah mamih Pathen BOEIPA hmueihtuk phoeiah hmueihhlutnah ham, khocang ham neh hmueih ham hmueihtuk suem te kaimih nen tah savisava,” a ti uh.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek neh Manasseh ca rhoek kah a thui uh ol te khosoih Phinekha neh rhaengpuei kah khoboei rhoek, anih taengah aka om Israel ca thawngkhat kah a lu loh a yaak uh vaengah a mik cop uh.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
Te dongah Reuben ca rhoek, Gad ca rhoek, Manasseh ca rhoek te, Khosoih Eleazar capa Phinekha loh, “BOEIPA te boekoeknah la boe na koek pawt tih Israel ca rhoek te BOEIPA kut lamkah na huul uh coeng dongah BOEIPA loh mamih lakli ah om tila tihnin ah m'ming uh,” a ti nah.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Te daengah Gilead kho kah khosoih Eleazar capa Phinekha, Reuben ca rhoek neh Gad ca rhoek lamkah khoboei rhoek te Kanaan kho kah Israel ca rhoek taengla bal uh tih olka te a khuen uh.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
Ol te khaw Israel ca rhoek kah mikhmuh ah a then coeng dongah Israel ca rhoek kah Pathen te a thangthen uh. Te dongah amih taengah caempuei la caeh ham, a khuikah khosa rhoek Reuben ca rhoek neh Gad ca rhoek kah khohmuen phae ham te thui uh voel pawh.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Hmueihtuk te khaw Reuben ca rhoek neh Gad ca rhoek loh, “Kaimih laklo ah aka om BOEIPA Pathen kah laipai ni,”tila a sak uh.

< Joshua 22 >