< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Wtedy naczelnicy wśród ojców Lewitów przyszli do kapłana Eleazara, do Jozuego, syna Nuna, i do naczelników wśród ojców pokoleń synów Izraela.
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
I powiedzieli do nich w Szilo, w ziemi Kanaan: PAN rozkazał przez Mojżesza, abyście nam dali miasta do mieszkania wraz z ich pastwiskami dla naszego bydła.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Synowie Izraela dali więc Lewitom ze swego dziedzictwa zgodnie ze słowem PANA te miasta oraz ich pastwiska.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
Padł los dla rodzin Kehatytów: synowie kapłana Aarona spośród Lewitów otrzymali losem trzynaście miast od pokolenia Judy, od pokolenia Symeona i od pokolenia Beniamina.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
A pozostali synowie Kehata [otrzymali] losem dziesięć miast od rodzin pokolenia Efraima, od pokolenia Dana i od połowy pokolenia Manassesa.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
A synowie Gerszona [otrzymali] losem trzynaście miast od rodzin pokolenia Issachara, od pokolenia Aszera, od pokolenia Neftalego i od połowy pokolenia Manassesa w Baszanie.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
[Także] synowie Merariego według swoich rodzin [otrzymali] dwanaście miast od pokolenia Rubena, od pokolenia Gada i od pokolenia Zebulona.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
Synowie Izraela dali więc Lewitom przez losowanie te miasta i ich pastwiska, jak rozkazał PAN przez Mojżesza.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
Dali z pokolenia synów Judy i z pokolenia synów Symeona następujące miasta wymienione z nazwy.
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
I otrzymali je synowie Aarona, z rodzin Kehatytów, spośród synów Lewiego, gdyż dla nich padł pierwszy los.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
I dano im miasto Arba, ojca Anaka, czyli Hebron, w górach Judy i leżące wokół niego pastwiska;
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Ale pole tego miasta i przyległe do niego wioski dano w posiadanie Kalebowi, synowi Jefunnego.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Synom kapłana Aarona dano miasto schronienia dla zabójcy: Hebron i jego pastwiska, a także Libnę i jej pastwiska;
14 Jattiri, Eṣitemoa,
Jattir i jego pastwiska, Esztemoa i jego pastwiska;
15 Holoni àti Debiri,
Cholon i jego pastwiska, Debir i jego pastwiska;
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
Ain i jego pastwiska, Juttę i jej pastwiska oraz Bet-Szemesz i jego pastwiska: dziewięć miast od tych dwóch pokoleń.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
A od pokolenia Beniamina: Gibeon i jego pastwiska, Gebę i jej pastwiska;
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Anatot i jego pastwiska, Almon i jego pastwiska: cztery miasta.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Wszystkich miast synów Aarona, kapłanów, było trzynaście wraz z ich pastwiskami.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Ale rodzinom synów Kehata, Lewitom, którzy pozostali z synów Kehata, [dano] przez losowanie miasta od pokolenia Efraima.
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
A dano im miasto schronienia dla zabójcy: Sychem i jego pastwiska na górze Efraim, a także Gezer i jego pastwiska;
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kibsaim i jego pastwiska oraz Bet-Choron i jego pastwiska: cztery miasta.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
Także od pokolenia Dana: Elteko i jego pastwiska, Gibbaton i jego pastwiska;
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ajjalon i jego pastwiska, Gat-Rimmon i jego pastwiska: cztery miasta.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
A od połowy pokolenia Manassesa: Tanak i jego pastwiska oraz Gat-Rimmon i jego pastwiska: dwa miasta.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
Wszystkich miast wraz z ich pastwiskami dla pozostałych rodzin synów Kehata [było] dziesięć.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
Synom Gerszona, z rodzin Lewiego, dano od połowy pokolenia Manassesa miasta schronienia dla zabójcy: Golan w Baszanie i jego pastwiska oraz Beeszterę i jej pastwiska: dwa miasta.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
Od pokolenia Issachara Kiszjon i jego pastwiska, Dobrat i jego pastwiska;
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Jarmut i jego pastwiska oraz En-Gannim i jego pastwiska: cztery miasta.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
A od pokolenia Aszera Miszeal i jego pastwiska, Abdon i jego pastwiska;
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Chelkat i jego pastwiska oraz Rechob i jego pastwiska: cztery miasta.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
A od pokolenia Neftalego [dano] miasto schronienia dla zabójcy: Kedesz w Galilei i jego pastwiska, Chammot-Dor i jego pastwiska oraz Kartan i jego pastwiska: trzy miasta.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Wszystkich miast dla Gerszonitów według ich rodzin [było] trzynaście wraz z ich pastwiskami.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
Potem rodzinom synów Merariego, pozostałym Lewitom, [dano] od pokolenia Zebulona: Jokneam i jego pastwiska, Kartę i jej pastwiska;
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Dimnę i jej pastwiska, Nahalal i jego pastwiska: cztery miasta.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
A od pokolenia Rubena Beser i jego pastwiska, Jahaza i jej pastwiska;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kedemot i jego pastwiska, Mefaat i jego pastwiska: cztery miasta.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
Od pokolenia Gada [dano] miasta schronienia dla zabójcy: Ramot w Gileadzie i jego pastwiska, Machanaim i jego pastwiska;
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Cheszbon i jego pastwiska, Jazer i jego pastwiska: razem cztery miasta.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Wszystkich miast przydzielonych losem dla synów Merariego według ich rodzin, którzy jeszcze pozostali z rodzin Lewitów, było dwanaście.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
Wszystkich miast Lewitów pośród dziedzictwa synów Izraela było czterdzieści osiem wraz z ich pastwiskami.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
A każde z tych miast miało dokoła siebie pastwiska; tak [było] z każdym z tych miast.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Dał więc PAN Izraelowi całą ziemię, którą przysiągł dać ich ojcom; i posiedli ją, i mieszkali w niej.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
Dał im PAN także odpoczynek ze wszystkich stron, tak jak przysiągł ich ojcom. Nie ostał się przed nimi nikt spośród wszystkich ich wrogów, wszystkich ich wrogów wydał PAN w ich ręce.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Nie zawiodło [żadne] słowo ze wszystkich dobrych słów, które PAN obiecał domowi Izraela; wszystko się wypełniło.

< Joshua 21 >