< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Przystąpili tedy przedniejsi z ojców Lewitów do Eleazara kapłana, i do Jozuego, syna Nunowego, i do przedniejszych z ojców w pokoleniach synów Izraelskich.
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
I rzekli do nich w Sylo, w ziemi Chananejskiej, mówiąc: Pan rozkazał przez Mojżesza, abyście nam dali miasta ku mieszkaniu z przedmieściami ich dla dobytków naszych.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Przetoż dali synowie Izraelscy Lewitom z dziedzictwa swego według słowa Pańskiego te miasta, i przedmieścia ich.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
Padł tedy los na domy Kaatytów; i dostało się synom Aarona kapłana, Lewitom z pokolenia Judowego i z pokolenia Symeonowego, i z pokolenia Benjaminowego, losem miast trzynaście.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
A drugim synom Kaatowym z domów pokolenia Efraimowego, i z pokolenia Danowego, i z połowy pokolenia Manasesowego, dostało się losem miast dziesięć.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
A synom Gersonowym z domów pokolenia Isascharowego, i z pokolenia Aserowego, i z pokolenia Neftalimowego, i z połowy pokolenia Manasesowego w Basan dostało się losem miast trzynaście.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Także synom Merarego według domów ich, z pokolenia Rubenowego, i z pokolenia Gadowego, i z pokolenia Zabulonowego miast dwanaście.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
Dali tedy synowie Izraelscy Lewitom te miasta, i przedmieścia ich, jako był rozkazał Pan przez Mojżesza, losem.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
A tak dali z pokolenia synów Judowych, i z pokolenia synów Symeonowych te miasta, których tu imiona położone są.
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
I dostały się synom Aaronowym z domów Kaatowych z synów Lewiego; bo im padł los pierwszy.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
I dano im miasto Arba, ojca Enakowego, które jest Hebron na górze Juda, i przedmieścia jego około niego;
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Ale role miasta tego, i wsi jego dano Kalebowi, synowi Jefunowemu w osiadłość jego.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Synom tedy Aarona kapłana dano miasto dla ucieczki mężobójcy, Hebron i przedmieścia jego; także Lobne i przedmieścia jego;
14 Jattiri, Eṣitemoa,
I Jeter, i przedmieścia jego; Estemon, i przedmieścia jego;
15 Holoni àti Debiri,
I Helon, i przedmieścia jego, i Dabir, i przedmieścia jego.
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
I Ain, i przedmieścia jego, i Jeta, i przedmieścia jego; Betsemes i przedmieścia jego; miast dziewięć z tegoż dwojga pokolenia.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
A z pokolenia Benjaminowego Gabaon i przedmieścia jego; Gabae i przedmieścia jego;
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Anatot i przedmieścia jego; i Almon i przedmieścia jego; miasta cztery.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Owa wszystkich miast synów Aaronowych, kapłanów, trzynaście miast i przedmieścia ich.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Ale domom synów Kaatowych, Lewitom, którzy byli zostali z synów Kaatowych, dane były miasta losu ich z pokolenia Efraimowego.
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
A dano im miasto ku ucieczce mężobójcy, Sychem i przedmieścia jego na górze Efraim; i Gazer i przedmieścia jego.
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
I Kibsaim i przedmieścia jego; i Betoron, i przedmieścia jego; miasta cztery.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
Także z pokolenia Danowego Elteko i przedmieścia jego; Gabaton i przedmieścia jego;
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ajalon i przedmieścia jego; Gatrymon i przedmieścia jego; miasta cztery.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
A z połowy pokolenia Manasesowego Tanach i przedmieścia jego; i Gatrymon i przedmieścia jego; dwa miasta.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
Wszystkich miast dziesięć i przedmieścia ich dano domom synów Kaatowych pozostałym.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
Synom zaś Gersonowym z pokolenia Lewiego, od połowy pokolenia Manasesowego, dano miasta dla ucieczki mężobójcy: Golan w Basan i przedmieścia jego, i Bozran i przedmieścia jego; dwa miasta.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
Z pokolenia Isaschar: Kiesyjon i przedmieścia jego; Daberet i przedmieścia jego;
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Jaramot i przedmieścia jego, i Engannim i przedmieścia jego; miasta cztery.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
A z pokolenia Aser: Masaa i przedmieścia jego; Abdon i przedmieścia jego;
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Helkat i przedmieścia jego, Rohob i przedmieścia jego; miasta cztery.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
A z pokolenia Neftalimowego dano miasto dla ucieczki mężobójcy, Kades w Galilei i przedmieścia jego; i Hamotdor i przedmieścia jego, także Kartan i przedmieścia jego; trzy miasta.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Wszystkich miast Gersonitów według domów ich było trzynaście miast i przedmieścia ich.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
Potem domom synów Merarego Lewitom ostatnim, z pokolenia Zabulonowego dano Jeknam i przedmieścia jego; Karta i przedmieścia jego.
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Damna i przedmieścia jego; Nahalol i przedmieścia jego; miasta cztery.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
A z pokolenia Rubenowego Besor i przedmieścia jego; i Jahasa i przedmieścia jego;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kedemot i przedmieścia jego; i Mefaat i przedmieścia jego; miasta cztery.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
Nadto z pokolenia Gadowego dano miasta dla ucieczki mężobójcy, Ramod w Galaad i przedmieścia jego, i Mahanaim i przedmieścia jego;
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Hesebon i przedmieścia jego; Jazer i przedmieścia jego; wszystkich miast cztery.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Wszystkich miast synów Merarego według domów ich, którzy jeszcze byli pozostali z domów Lewitów, przyszło im losem miast dwanaście.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
A tak wszystkich miast Lewitów w pośrodku dziedzictwa synów Izraelskich miast czterdzieści osiem i przedmieścia ich.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
A miały te wszystkie miasta, każde z osobna, przedmieścia około siebie; a tak było około wszystkich onych miast.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Dał tedy Pan Izraelowi wszystkę ziemię, o którą przysiągł, że ją dać miał ojcom ich; i posiedli ją, a mieszkali w niej.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
Dał im też odpoczynek Pan zewsząd w około, tak jako był przysiągł ojcom ich; a nie był nikt, kto by się im oprzeć mógł ze wszystkich nieprzyjaciół ich; wszystkie nieprzyjacioły ich dał Pan w rękę ich.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Nie chybiło żadne słowo ze wszystkich słów dobrych, które obiecał Pan domowi Izraelskiemu; wszystko się wypełniło.

< Joshua 21 >