< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Or les chefs des pères des Lévites vinrent à Eléazar le Sacrificateur, et à Josué, fils de Nun, et aux chefs des pères des Tribus des enfants d'Israël,
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
Et leur parlèrent, à Silo dans le pays de Canaan, en disant: L'Eternel a commandé par le moyen de Moïse qu'on nous donnât des villes pour habiter, et leurs faubourgs pour nos bêtes.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Et ainsi les enfants d'Israël donnèrent de leur héritage aux Lévites, suivant le commandement de l'Eternel, ces villes-ci avec leurs faubourgs.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
Et on tira au sort pour les familles des Kéhathites. Or il échut par sort aux enfants d'Aaron le Sacrificateur qui étaient d'entre les Lévites, treize villes, de la Tribu de Juda, et de la Tribu des Siméonites, et de la Tribu de Benjamin.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
Et il échut par sort au reste des enfants de Kéhath dix villes des familles de la Tribu d'Ephraïm, et de la Tribu de Dan, et de la moitié de la Tribu de Manassé.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
Et les enfants de Guerson eurent par sort treize villes, des familles de la Tribu d'Issacar, et de la Tribu d'Aser, et de la Tribu de Nephthali, et de la demi-Tribu de Manassé en Basan.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Et les enfants de Mérari selon leurs familles, [eurent] douze villes, de la Tribu de Ruben, et de la Tribu de Gad, et de la Tribu de Zabulon.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
Les enfants donc d'Israël donnèrent donc par sort aux Lévites ces villes-là avec leurs faubourgs, selon que l'Eternel l'avait commandé par le moyen de Moïse.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
Ils donnèrent donc de la Tribu des enfants de Juda, et de la Tribu des enfants de Siméon, ces villes, qui vont être nommées par leurs noms.
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
Et elles furent pour ceux des enfants d'Aaron, qui étaient des familles des Kéhathites, enfants de Lévi, car le premier sort fut pour eux.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
On leur donna donc Kirjath-Arbah; [or Arbah était] père de Hanak, [et] Kirjath-Arbah est Hébron, en la montagne de Juda, avec ses faubourgs tout à l'entour.
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Mais quant au territoire de la ville, et à ses villages, on les donna à Caleb, fils de Jéphunné, pour sa possession.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
On donna donc aux enfants d'Aaron le Sacrificateur pour villes de refuge au meurtrier, Hébron, avec ses faubourgs, et Libna, avec ses faubourgs.
14 Jattiri, Eṣitemoa,
Et Jattir, avec ses faubourgs, et Estemoab, avec ses faubourgs,
15 Holoni àti Debiri,
Et Holon, avec ses faubourgs, et Débir, avec ses faubourgs,
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
Et Hajin, avec ses faubourgs, et Jutta, avec ses faubourgs; et Beth-semes, avec ses faubourgs; neuf villes de ces deux Tribus-là.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
Et de la Tribu de Benjamin, Gabaon, avec ses faubourgs, et Guebah, avec ses faubourgs,
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Hanathoth, avec ses faubourgs, et Halmon, avec ses faubourgs; quatre villes.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Toutes les villes des enfants d'Aaron Sacrificateurs, furent treize villes, avec leurs faubourgs.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Or quant aux familles des enfants de Kéhath Lévites, qui étaient le reste des enfants de Kéhath, il y eut dans leur sort des villes de la Tribu d'Ephraïm.
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
On leur donna donc pour villes de refuge au meurtrier, Sichem, avec ses faubourgs, en la montagne d'Ephraïm, et Guézer avec ses faubourgs.
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Et Kibtsajim, avec ses faubourgs, et Beth-horon, avec ses faubourgs; quatre villes.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
Et de la Tribu de Dan, Elteké, avec ses faubourgs; Guibbethon, avec ses faubourgs,
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ajalon, avec ses faubourgs, Gath-rimmon, avec ses faubourgs; quatre villes.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
Et de la demi-Tribu de Manassé, Tahanac, avec ses faubourgs; et Gath-rimmon, avec ses faubourgs, deux villes.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
[Ainsi] dix villes en tout avec leurs faubourgs, furent pour les familles des enfants de Kéhath, qui étaient de reste.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
On donna aussi de la demi-Tribu de Manassé aux enfants de Guerson, qui étaient des familles des Lévites, pour villes de refuge au meurtrier, Golan en Basan, avec ses faubourgs, et Behestera, avec ses faubourgs; deux villes.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
Et de la Tribu d'Issacar, Kisjon, avec ses faubourgs, Dobrath, avec ses faubourgs,
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Jarmuth, avec ses faubourgs, Hengannim, avec ses faubourgs; quatre villes.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
Et de la Tribu d'Aser, Miséal, avec ses faubourgs, Habdon, avec ses faubourgs,
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Helkath, avec ses faubourgs, et Rehob, avec ses faubourgs; quatre villes.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
Et de la Tribu de Nephthali, pour villes de refuge au meurtrier, Kédès en Galilée avec ses faubourgs, Hammoth-Dor, avec ses faubourgs, et Kartan, avec ses faubourgs; trois villes.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Toutes les villes [donc] des Guersonites selon leurs familles, furent treize villes, et leurs faubourgs.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
On donna aussi de la Tribu de Zabulon aux familles des enfants de Mérari, qui étaient les Lévites qui restaient, Jokneham, avec ses faubourgs, Karta, avec ses faubourgs,
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Dimnah, avec ses faubourgs, et Nahalal, avec ses faubourgs; quatre villes.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
Et de la Tribu de Ruben, Betser, avec ses faubourgs, et Jahasa, avec ses faubourgs;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kédémoth, avec ses faubourgs, et Méphahat, avec ses faubourgs; quatre villes.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
Et de la Tribu de Gad, pour villes de refuge au meurtrier, Ramoth en Galaad, avec ses faubourgs, et Mahanajim, avec ses faubourgs,
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Hesbon, avec ses faubourgs, et Jahzer, avec ses faubourgs; en tout quatre villes.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Toutes ces villes-là furent données aux enfants de Mérari, selon leurs familles, qui étaient le reste des familles des Lévites; et leur sort fut de douze villes.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
Toutes les villes des Lévites qui étaient parmi la possession des enfants d'Israël, furent quarante-huit, et leurs faubourgs.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
Chacune de ces villes avait ses faubourgs autour d'elle; il en [devait être] ainsi de toutes ces villes-là.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
L'Eternel donc donna à Israël tout le pays qu'il avait juré de donner à leurs pères; et ils le possédèrent, et y habitèrent.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
Et l'Eternel leur donna un parfait repos tout alentour, selon tout ce qu'il avait juré à leurs pères; et il n'y eut aucun de tous leurs ennemis qui subsistât devant eux; [mais] l'Eternel livra tous leurs ennemis en leurs mains.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Il ne tomba pas un seul mot de toutes les bonnes paroles que l'Eternel avait dites à la maison d'Israël; tout arriva.

< Joshua 21 >