< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Les chefs de familles des Lévites se présentèrent devant le pontife Eléazar, Josué, fils de Noun, et les chefs de familles des tribus d’Israël,
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
à Silo, dans le pays de Canaan, et leur parlèrent ainsi: "L’Eternel a ordonné, par l’organe de Moïse, qu’on nous donnât des villes pour y habiter, ainsi que leurs banlieues pour notre bétail."
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Et les enfants d’Israël, se conformant à l’ordre du Seigneur, donnèrent aux Lévites, sur leurs parts de possession, les villes suivantes avec leurs ban-lieues.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
On tira au sort pour les familles des Kehathites; et d’abord, les Lévites, descendants du pontife Aaron, obtinrent, par la voie du sort, dans les tribus de Juda, de Siméon et de Benjamin, treize villes.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
Le surplus des enfants de Kehath reçut au sort, dans les familles de la tribu d’Ephraïm, dans la tribu de Dan et dans la demi-tribu de Manassé, dix villes.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
Les enfants de Gerson reçurent au sort, dans les familles de la tribu d’Issachar, dans celles d’Aser et de Nephtali, et dans la demi-tribu de Manassé en Basan, treize villes.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Les enfants de Merari, selon leurs familles, eurent de la tribu de Ruben, de celles de Gad et de Zabulon, douze villes.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
Les enfants d’Israël donnèrent ces villes avec leurs banlieues aux Lévites par la voie du sort, comme l’Eternel l’avait prescrit par l’organe de Moïse.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
De la tribu de Juda et de celle de Siméon, l’on donna les villes suivantes, ainsi désignées nominativement,
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
pour appartenir aux descendants d’Aaron, d’entre les familles Kehathites, de la tribu de Lévi, à qui échut le premier lot.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
On leur donna donc la Cité d’Arba (père d’Anok), appelée aussi Hébron, dans la montagne de Juda, avec la banlieue d’alentour.
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Les champs et les bourgades dépendant de la ville, on les avait donnés comme propriété à Caleb, fils de Yefounné.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Mais aux descendants du pontife Aaron l’on donna la ville même de Hébron avec sa banlieue comme ville de refuge pour le meurtrier; plus, Libna avec sa banlieue,
14 Jattiri, Eṣitemoa,
Yattir avec sa banlieue, Echtemoa avec la sienne,
15 Holoni àti Debiri,
Holôn avec sa banlieue, Debir avec la sienne,
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
Ayin avec sa banlieue, Youtta avec sa banlieue et Beth-Chémech avec la sienne: neuf villes, remises par les deux tribus en question.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
Et de la tribu de Benjamin: Gabaon et sa banlieue, Ghéba et la sienne,
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Anatot et sa banlieue, Almôn et la sienne: quatre villes.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Total des villes données aux prêtres descendants d’Aaron: treize villes, avec leurs banlieues.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Quant aux familles lévitiques descendant de Kehath, formant le surplus des Kehathites, elles eurent au sort les villes suivantes de la tribu d’Ephraïm:
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
on leur donna la ville de refuge destinée au meurtrier, Sichem avec sa banlieue, dans la montagne d’Ephraïm; Ghézer, avec sa banlieue;
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kibçaïm avec la sienne, Béthorôn avec la sienne: quatre villes.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
Puis, de la tribu de Dan: Elteké et sa banlieue, Ghibetôn et sa banlieue.
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ayyalôn et la sienne, Gath-Rimmôn et la sienne: quatre villes.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
Et de la demi-tribu de Manassé: Taanakh et sa banlieue, Gath-Rimmôn avec la sienne: deux villes.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
En tout, dix villes avec leurs banlieues, pour le surplus des familles des Kehathites.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
Les familles lévitiques descendant de Gerson reçurent: de la demi-tribu de Manassé, la ville de refuge Golân, dans le Basan, avec sa banlieue, et Beéchtera avec la sienne: deux villes.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
De la tribu d’lssachar: Kichyôn avec sa banlieue, Daberath avec la sienne,
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Yarmout avec sa banlieue, En-Gannim avec la sienne: quatre villes.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
De la tribu d’Aser: Micheal et sa banlieue, Abdôn et la sienne,
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Helkath et sa banlieue, Rehob et la sienne: quatre villes.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
Et de la tribu de Nephtali: la ville de refuge Kédech, en Galilée, avec sa banlieue; Hamot-Dor avec sa banlieue, Kartân avec la sienne: trois villes.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Total des villes des Gersonites, selon leurs familles: treize villes, avec leurs banlieues.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
Enfin, les familles descendant de Merari, formant le surplus des Lévites, reçurent de la tribu de Zabulon: Yokneam et sa banlieue, Karta et sa banlieue;
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Dimna et sa banlieue, Nahalal avec la sienne: quatre villes.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
Et de la tribu de Gad: la ville de refuge Ramoth, en Galaad, avec sa banlieue, Mahanaïm, avec la sienne;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Hesbon, avec sa banlieue; Yazer, avec la sienne: en tout quatre villes.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Telles sont les villes échues aux familles des Merarites, formant le surplus des familles lévitiques; leur lot comportait donc douze villes.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
Toutes les villes appartenant aux Lévites parmi les possessions des Israélites se montaient ainsi à quarante-huit villes, indépendamment de leurs banlieues.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
Chacune de ces villes comprenait la banlieue qui lui sert de zone: règle uniforme pour toutes les villes en question.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Ainsi l’Eternel donna aux Israélites tout le pays qu’il avait promis par serment à leurs ancêtres; ils en prirent possession et s’y établirent.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
II les fit jouir d’une sécurité entière, comme il l’avait juré à leurs ancêtres; de tous leurs ennemis, pas un n’avait tenu devant eux: tous, Dieu les avait mis en leur pouvoir.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Aucune ne fit défaut de toutes les faveurs que l’Eternel avait promises à la maison d’Israël: toutes s’accomplirent.

< Joshua 21 >