< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
And the princes of meynees of Leuy neiyiden to Eleazar, preest, and to Josue, sone of Nun, and to the duykis of kynredis, bi alle the lynagis of the sones of Israel;
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
and the Leuytis spaken to hem in Sylo, of the lond of Canaan, and seiden, The Lord comaundide bi the honde of Moises, that citees schulden be youun to vs to dwelle ynne, and the subarbis of tho to werk beestis to be fed.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And the sones of Israel yauen `of her possessiouns, bi comaundement of the Lord, citees and the subarbis of tho.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
And the lot yede out in to the meynee of Caath, of the sones of Aaron, preest, of the lynages of Juda, and of Symeon, and of Beniamyn, threttene citees;
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
and to the othere of the sones of Caath, that is, to dekenes that weren left, of the lynagis of Effraym, and of Dan, and of the half lynage of Manasse, ten citees.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
Sotheli lot yede out to the sones of Gerson, that thei schulden take of the lynagis of Isachar, and of Aser, and of Neptalym, and of the half lynage of Manasses `in Basan, threttene citees in noumbre;
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
and to the sones of Merari, bi her meynees, of the lynagis of Ruben, and of Gad, and of Zabulon, twelue citees.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
And the sones of Israel yauen to dekenes cytees, and the subarbis `of tho, as the Lord comaundide bi the hond of Moises; and alle yauen bi lot.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
Of the lynagis of the sones of Juda, and of Symeon, Josue yaf citees;
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
to the sones of Aaron, bi the meynees of Caath, of the kyn of Leuy, of whiche citees these ben the names; for the firste lot yede out to hem;
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
Cariatharbe, of the fadir of Enach, which is clepid Ebron, in the hil of Juda, and the subarbis therof bi cumpas;
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
sotheli he hadde youe the feeldis and townes therof to Caleph, sone of Jephone, to haue in possessioun.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Therfor Josue yaf to the sones of Aaron, preest, Ebron, a citee of refuyt, and the subarbis `of it, and Lebnam with hise subarbis,
14 Jattiri, Eṣitemoa,
and Jether, and Yschymon,
15 Holoni àti Debiri,
and Elon, and Dabir, and Ayn, and Lethan,
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
and Bethsames, with her subarbis; nyne citees, of twei lynagis, as it is seid.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
Sotheli of the lynage of the sones of Beniamyn, he yaf Gabaon, and Gabee, and Anatoth, and Almon, with her subarbis;
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
`foure citees.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Alle the citees togidere of the sones of Aaron, preest, weren threttene, with her subarbis.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Forsothe to `the othere, bi the meynees of the sones of Caath, of the kyn of Leuy, this possessioun was youun;
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
of the lynage of Effraym, the citee of refuyt, Sichen, with hise subarbis, in the hil of Effraym, and Gazer,
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Sebsam, and Bethoron, with her subarbis;
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
`foure citees; also of the lynage of Dan, Helthece, and Gebethon, and Haialon,
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Gethremmon, with her subarbis;
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
`foure citees; sotheli of the half lynage of Manasses, Thanach, and Gethremon, with her subarbis; `twei citees.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
Alle the citees ten, and the subarbis `of tho weren youun to the sones of Caath, of the lowere degree.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
Also to the sones of Gerson, of the kyn of Leuy, Josue yaf of the half lynage of Manasses, citees of refuyt, Gaulon in Basan, and Bosra, with her subarbis, `twei citees.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
Forsothe of the lynage of Isachar, he yaf Cesion, and Daberath,
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Jerimoth, and Engannym, with her subarbis; `foure citees.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
Of the lynage of Aser, he yaf Masal, and Abdon,
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Elecath, and Roob, with her subarbis; `foure citees.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
Also of the lynage of Neptalym, `he yaf the citee of refuyt, Cedes in Galile, and Amodor, and Carthan, with her subarbis; `thre citees.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Alle the citees of the meynees of Gerson weren threttene, with her subarbis.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
Sotheli to the sones of Merary, dekenes of the lowere degree, bi her meynees, was youun Getheran, of the linage of Zabulon, and Charcha, and Demna, and Nalol;
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
`foure citees, with her subarbis.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
And of the lynage of Gad, he yaf the citee of refuyt, Ramoth in Galaad, and Manaym, and Esebon, and Jaser; `foure citees, with her subarbis.
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
And of the lynage of Ruben, biyende Jordan, ayens Jerico, he yaf `the citee of refuyt, Bosor in the wildirnesse of Mysor, and Jazer, and Jecson, and Maspha; `foure citees, with her subarbis.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Alle the citees of Merary, bi her meynees and kynredis, weren twelue.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
And so alle the citees of Leuytis, in the myddis of possessioun of the sones of Israel, weren eiyte and fourti, with her subarbis;
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
and alle citees weren departid by meynees.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
And the Lord yaf to Israel al the lond which he swoor hym silf to yyue to the fadris `of hem, and thei hadden it in possessioun, and dwelliden therynne.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
And pees was youun of hym in to alle naciouns `by cumpas; and noon of enemyes was hardi to withstonde hem, but alle weren dryuen in to the lordschip `of hem.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Forsothe nether o word, which he bihiyte him silf to yyue to hem, was voide, but alle wordis weren fillid in werkis.

< Joshua 21 >