< Joshua 21 >
1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
And they approached [the] leaders of [the] fathers of the Levites to Eleazar the priest and to Joshua [the] son of Nun and to [the] leaders of [the] fathers of the tribes of [the] people of Israel.
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
And they spoke to them at Shiloh in [the] land of Canaan saying Yahweh he commanded by [the] hand of Moses to give to us cities to dwell in and pasture lands their for livestock our.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And they gave [the] people of Israel to the Levites some of inheritance their to [the] mouth of Yahweh the cities these and pasture lands their.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
And it came out the lot of [the] clans of the Kohathite[s] and it belonged to [the] descendants of Aaron the priest of the Levites from [the] tribe of Judah and from [the] tribe of the Simeonite[s] and from [the] tribe of Benjamin by the lot cities thir-teen.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
And [belonged] to [the] descendants of Kohath which remained from [the] clans of [the] tribe of Ephraim and from [the] tribe of Dan and from [the] half of [the] tribe of Manasseh by the lot cities ten.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
And [belonged] to [the] descendants of Gershon from [the] clans of [the] tribe of Issachar and from [the] tribe of Asher and from [the] tribe of Naphtali and from [the] half of [the] tribe of Manasseh in Bashan by the lot cities thir-teen.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
[and belonged] to [the] descendants of Merari to clans their from [the] tribe of Reuben and from [the] tribe of Gad and from [the] tribe of Zebulun cities two [plus] ten.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
And they gave [the] people of Israel to the Levites the cities these and pasture lands their just as he had commanded Yahweh by [the] hand of Moses by the lot.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
And they gave from [the] tribe of [the] descendants of Judah and from [the] tribe of [the] descendants of Simeon the cities these which he called them by name.
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
And it belonged to [the] descendants of Aaron one of [the] clans of the Kohathite[s] from [the] descendants of Levi for to them it belonged the lot first.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
And they gave to them Kiriath Arba [the] father of Anak that [is] Hebron in [the] hill country of Judah and pasture lands its around it.
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
And [the] field[s] of the city and villages its they gave to Caleb [the] son of Jephunneh possession his.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
And to [the] descendants of - Aaron the priest they gave [the] city of refuge of the killer Hebron and pasture lands its and Libnah and pasture lands its.
And Jattir and pasture lands its and Eshtemoa and pasture lands its.
And Holon and pasture lands its and Debir and pasture lands its.
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
And Ain and pasture lands its and Juttah and pasture lands its Beth Shemesh and pasture lands its cities nine from with [the] two the tribes these.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
And from [the] tribe of Benjamin Gibeon and pasture lands its Geba and pasture lands its.
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Anathoth and pasture lands its and Almon and pasture lands its cities four.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
All [the] cities of [the] descendants of Aaron the priests [were] thir-teen cities and pasture lands their.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
And to [the] clans of [the] descendants of Kohath the Levites who remained of [the] descendants of Kohath and it was [the] cities of lot their from [the] tribe of Ephraim.
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
And they gave to them [the] city of refuge of the killer Shechem and pasture lands its in [the] hill country of Ephraim and Gezer and pasture lands its.
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
And Kibzaim and pasture lands its and Beth Horon and pasture lands its cities four.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
And from [the] tribe of Dan Eltekeh and pasture lands its Gibbethon and pasture lands its.
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Aijalon and pasture lands its Gath Rimmon and pasture lands its cities four.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
And from [the] half of [the] tribe of Manasseh Taanach and pasture lands its and Gath Rimmon and pasture lands its cities two.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
All [the] cities ten and pasture lands their [belonged] to [the] clans of [the] descendants of Kohath which remained.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
And to [the] descendants of Gershon from [the] clans of the Levites from [the] half of [the] tribe of Manasseh [the] city of refuge of the killer (Golan *Q(K)*) in Bashan and pasture lands its and Beeshtarah and pasture lands its cities two.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
And from [the] tribe of Issachar Kishion and pasture lands its Daberath and pasture lands its.
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Jarmuth and pasture lands its En Gannim and pasture lands its cities four.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
And from [the] tribe of Asher Mishal and pasture lands its Abdon and pasture lands its.
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Helkath and pasture lands its and Rehob and pasture lands its cities four.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
And from [the] tribe of Naphtali [the] city of - refuge of the killer Kedesh in Galilee and pasture lands its and Hammoth Dor and pasture lands its and Kartan and pasture lands its cities three.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
All [the] cities of the Gershonite[s] to clans their [were] thir-teen citi[es] and pasture lands their.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
And to [the] clans of [the] descendants of Merari the Levites which remained from with [the] tribe of Zebulun Jokneam and pasture lands its Kartah and pasture lands its.
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Dimnah and pasture lands its Nahalal and pasture lands its cities four.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
(And from [the] tribe of Reuben Bezer and pasture lands its and Jahaz and pasture lands its. *R*)
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
(Kedemoth and pasture lands its and Mephaath and pasture lands its cities four. *R*)
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
And from [the] tribe of Gad [the] city of refuge of the killer Ramoth in Gilead and pasture lands its and Mahanaim and pasture lands its.
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Heshbon and pasture lands its Jazer and pasture lands its all [the] cities [were] four.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
All the cities of [the] descendants of Merari to clans their which remained of [the] clans of the Levites and it was lot their cities two [plus] ten.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
All [the] cities of the Levites in [the] midst of [the] possession of [the] people of Israel [were] cities forty and eight and pasture lands their.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
They were the cities these a city a city and pasture lands its around it thus for all the cities these.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
And he gave Yahweh to Israel all the land which he had sworn to give to ancestors their and they took possession of it and they dwelt in it.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
And he gave rest Yahweh to them from round about according to all that he had sworn to ancestors their and not he stood anyone in faces their from all enemies their all enemies their he gave Yahweh in hand their.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Not it fell a word from every word good which he had spoken Yahweh to [the] house of Israel everything it came.