< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Then came near the heads of the divisions of the Levites unto Elazar the priest, and unto Joshua the son of Nun, and unto the heads of the divisions of the tribes of the children of Israel;
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
And they spoke unto them at Shiloh, in the land of Canaan, saying, The Lord commanded by the hand of Moses to give unto us cities to dwell in, with the open spaces thereof for our cattle.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And the children of Israel gave unto the Levites from their inheritance, at the order of the Lord, these cities and their open spaces.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
And the lot came out for the families of the Kehathites: and the children of Aaron the priest, who were of the Levites, obtained from the tribe of Judah, and from the tribe of Simeon, and from the tribe of Benjamin, by lot, thirteen cities.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
And the rest of the children of Kehath obtained from the families of the tribe of Ephraim, and from the tribe of Dan, and from the half tribe of Menasseh, by lot, ten cities.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
And the children of Gershon obtained from the families of the tribe of Issachar, and from the tribe of Asher, and from the tribe of Naphtali, and from the half tribe of Menasseh in Bashan, by lot, thirteen cities.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
The children of Merari after their families obtained from the tribe of Reuben, and from the tribe of Gad, and from the tribe of Zebulun, twelve cities.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
And the children of Israel gave unto the Levites these cities with their open spaces, as the Lord had commanded by the hand of Moses, by lot.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
And they gave from the tribe of the children of Judah, and from the tribe of the children of Simeon, these cities which are called by name.
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
And the children of Aaron, of the families of the Kehathites, of the children of Levi, obtained them; —for they had the first lot.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
And they gave unto them Kiryath-arba', [the father of 'Anak, ] which is Hebron, in the mountain of Judah, with the open spaces thereof round about it;
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
But the fields of the city, and its villages, they gave to Caleb the son of Yephunneh for his possession.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
And to the children of Aaron the priest they gave the city of refuge for the manslayer, Hebron with its open spaces, and Libnah with its open spaces,
14 Jattiri, Eṣitemoa,
And Yattir with its open spaces, and Eshtemoa' with its open spaces.
15 Holoni àti Debiri,
And Cholon with its open spaces, and Debir with its open spaces,
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
And 'Ayin with its open spaces, and Yuttah with its open spaces, and Beth-shemesh with its open spaces: nine cities from those two tribes.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
And from the tribe of Benjamin, Gib'on with its open spaces, Geba' with its open spaces,
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
'Anathoth with its open spaces, and 'Almon with its open spaces: four cities.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
All the cities of the children of Aaron, the priests, were thirteen cities with their open spaces.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
And the families of the children of Kehath, the Levites, who remained of the children of Kehath, obtained the cities of their lot from the tribe of Ephraim.
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
And they gave to them the city of refuge for the manslayer, Shechem with its open spaces in the mountain of Ephraim, and Gezer with its open spaces,
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
And Kibzayim with its open spaces, and Beth-choron with its open spaces: four cities.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
And from the tribe of Dan, Elteke with its open spaces, Gibbethon with its open spaces,
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ayalon with its open spaces, Gath-rimmon with its open spaces: four cities.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
And from the half tribe of Menasseh, Ta'nach with its open spaces, and Gath-rimmon with its open spaces: two cities.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
All the cities were ten with their open spaces for the families of the children of Kehath that remained.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
And unto the children of Gershon, of the families of the Levites, [they gave] from the other half tribe of Menasseh the city of refuge for the manslayer, Golan in Bashan with its open spaces, and Be'eshterah with its open spaces: two cities.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
And from the tribe of Issachar, Kishyon with its open spaces, Daberath with its open spaces,
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Yarmuth with its open spaces, 'En-gannim with its open spaces: four cities.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
And from the tribe of Asher, Mishal with its open spaces, Abdon with its open spaces.
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Chelkath with its open spaces, and Rechob with its open spaces: four cities.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
And from the tribe of Naphtali, the city of refuge for the manslayer, Kedesh in Galilee with its open spaces, and Chammothdor with its open spaces, and Karthan with its open spaces: three cities.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
All the cities of the Gershunites according to their families were thirteen cities with their open spaces.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
And unto the families of the children of Merari, the remainder of the Levites, [they gave] from the tribe of Zebulun, Yokne'am with its open spaces, and Karthah with its open spaces,
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Dimnah with its open spaces, Nahalal with its open spaces: four cities.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
And from the tribe of Gad, the city of refuge for the manslayer, Ramoth in Gil'ad with its open spaces, and Machanayim with its open spaces,
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Cheshbon with its open spaces, Ya'zer with its open spaces: four cities in all.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
All the cities for the children of Merari after their families, they who were remaining of the families of the Levites, even their lot was twelve cities.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
All the cities of the Levites in the midst of the possession of the children of Israel were forty and eight cities with their open spaces.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
These cities were every one with their open spaces round about them: thus it was with all these cities.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
And the Lord gave unto Israel all the land which he had sworn to give unto their fathers; and they possessed it, and dwelt therein.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
And the Lord gave them rest round about, all just as he had sworn unto their fathers: and there stood not up before them a man of all their enemies; all their enemies the Lord delivered into their hand.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
There failed not aught of all the good thing which the Lord had spoken unto the house of Israel: it all came to pass.

< Joshua 21 >