< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
And the leaders of the families of Levi approached Eleazar, the priest, and Joshua, the son of Nun, and the rulers of the extended families of each of the tribes of the sons of Israel.
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
And they spoke to them at Shiloh, in the land of Canaan, and they said, “The Lord instructed, by the hand of Moses, that cities should be given to us as habitations, with their suburbs to nourish our cattle.”
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And so the sons of Israel gave cities and their suburbs from their possessions, in accord with the order of the Lord.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
And the lot went out for the family of Kohath, of the sons of Aaron, the priest, from the tribes of Judah and Simeon and Benjamin: thirteen cities.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
And to the remainder of the sons of Kohath, that is, to the Levites who were left over, there went, from the tribes of Ephraim and Dan, and from the one half tribe of Manasseh, ten cities.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
And next the lot went out to the sons of Gershon, so that they would receive, from the tribes of Issachar and Asher and Naphtali, and from the one half tribe of Manasseh at Bashan: the number of thirteen cities.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
And to the sons of Merari, by their families, from the tribes of Reuben and Gad and Zebulun, there went twelve cities.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
And so the sons of Israel gave cities and their suburbs to the Levites, just as the Lord instructed by the hand of Moses, distributing to each by lot.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
From the tribes of the sons of Judah and Simeon, Joshua gave cities, whose names are these:
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
to the sons of Aaron, of the families of Kohath of the stock of Levi, (for the first lot went out for them, )
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
the city of Arba, the father of Anak, which is called Hebron, on the mountain of Judah, and its surrounding suburbs.
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Yet truly, the fields and its villages he had given to Caleb, the son of Jephunneh, as a possession.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Therefore, he gave to the sons of Aaron the priest, Hebron as a city of refuge, as well as its suburbs, and Libnah, with its suburbs,
14 Jattiri, Eṣitemoa,
and Jattir, and Eshtemoa,
15 Holoni àti Debiri,
and Holon, and Debir,
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
and Ain, and Juttah, and Beth-shemesh, with their suburbs: nine cities from two tribes, just as has been said.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
Then, from the tribe of the sons of Benjamin, he gave Gibeon, and Geba,
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Anathoth, and Almon, with their suburbs: four cities.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
All the cities together of the sons of Aaron, the priest, were thirteen, with their suburbs.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Yet truly, the remainder of the families of the sons of Kohath, of the stock of Levi, were given this possession:
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
from the tribe of Ephraim, Shechem, one of the cities of refuge, with its suburbs, on mount Ephraim, and Gezer,
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Kibzaim, and Beth-horon, with their suburbs, four cities;
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
and from the tribe of Dan, Elteke and Gibbethon,
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Aijalon and Gath-Rimmon, with their suburbs, four cities;
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
then, from the one half tribe of Manasseh, Taanach and Gath-Rimmon, with their suburbs, two cities.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
All the cities were ten, with their suburbs; these were given to the sons of Kohath, of the lesser degree.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
Likewise, to the sons of Gershon, of the stock of Levi, from the one half tribe of Manasseh, went Golan in Bashan, one of the cities of refuge, and Bosra, with their suburbs, two cities;
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
also, from the tribe of Issachar, Kishion, and Daberath,
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Jarmuth, and Engannim, with their suburbs, four cities;
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
then, from the tribe of Asher, Mishal and Abdon,
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Helkath and Rehob, with their suburbs, four cities;
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
likewise, from the tribe of Naphtali, Kedesh in Galilee, one of the cities of refuge, and Hammoth-Dor, and Kartan, with their suburbs, three cities.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
All the cities of the families of Gershon were thirteen, with their suburbs.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
Then, to the sons of Merari, Levites of the lesser degree, by their families, were given, from the tribe of Zebulun, Jokneam and Kartah,
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
and Dimnah and Nahalal, four cities with their suburbs;
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
from the tribe of Reuben, beyond the Jordan, opposite Jericho, Bezer in the wilderness, one of the cities of refuge, Misor and Jazer, and Jethson and Mephaath, four cities with their suburbs;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
from the tribe of Gad, Ramoth of Gilead, one of the cities of refuge, and Mahanaim and Heshbon and Jazer, four cities with their suburbs.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
All the cities of the sons of Merari, by their families and extended families, were twelve.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
And so all the cities of the Levites, in the midst of the possession of the sons of Israel, were forty-eight,
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
with their suburbs, each distributed by families.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
And the Lord God gave to Israel all the land that he had sworn he would deliver to their fathers. And they possessed it, and they lived in it.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
And he gave them peace with all the surrounding nations. And none of their enemies dared to stand against them; instead, they were brought under their sovereignty.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Indeed, not so much as one word that he had promised to provide for them was left empty; instead, everything was fulfilled.

< Joshua 21 >